What is food poisoning: Wo ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa májèlé oúnjẹ àti bí o ṣe lè dẹ́kun rẹ̀

Oríṣun àwòrán, All Nigerian Foods
Ọpọ eeyan lo ti maa n gbọ nipa majele ounjẹ (food poisining), ti ko mọ ohun to tumọ si.
Lọpọ igba ni awọn eeyan tilẹ ti dero ile iwosan, ti awọn dokita yoo si sọ pe majele ounjẹ ni wọn ni ṣugbọn ti wọn ko mọ ohun to ṣokunfa rẹ.
Awọn miran tilẹ lero pe ohun to tumọ si ni pe ki wọn fi majele sinu ounjẹ fun eeyan lati jẹ.
- Àjọ̀dún odò Ẹ̀rìn, omi tí wọn kò gbọdọ̀ pa ẹja abàmì inú rẹ̀ wáyé nílùú Erinjiyan
- Awujale Ijebu Ode, Ọba Adetona wọ́gilé àjọ̀dún Ojude Oba tọdún yìí
- Ẹ wo ibi ọ̀rọ̀ dé dúró lórí àwọn afurasí tó lọ́wọ́ nínú ikú Tolulope Arotile
- Buhari fẹ́ dá Naijiria padà sí ọdún 1984, ṣùgbọ́n a kò ní gbà fun- Femi Falana
Ṣugbọn ki ni wọn n pe ni "Food poisoning" gan?
Dokita kan, to jẹ onimọ nipa itọju idile ni ile iwosan ijọba apapọ to wa niluu Owo, FMC, Olaniyi Ojo Johnson ṣalaye fun BBC ohun ti wọn n pe majele ounnjẹ.
Gẹgẹ bii ohun to sọ, awọn kokoro aifojuri kan lo maa n ṣokunfa majele ounjẹ.
O ni "Awọn kokoro ti a ko foju ri le wo inu ounjẹ tabi omi, ti yoo si maa bi si ninu irufẹ omi tabi ounjẹ bẹẹ."

Oríṣun àwòrán, Chioma Jeremiah
"Awọn kokoro naa maa n tọ awọn oje kan sinu ounjẹ, yala wọn ti ṣe ounjẹ naa ni tabi wọn ko gbe kana daadaa ko le pa awọn kokoro naa, ẹni bẹẹ le maa fi ami ailera han."
Olaniyi ni awọn ami naa maa n fara laarin wakati mẹfa pere, ailera naa si le da ge ẹmi eeyan kuru.
Iru ami wo ni ẹni to ba ni majele ounjẹ yoo ri?
Dokita Olaniyi sọ pe awọn ami to wọnpọ ju ni ki eeyan maa bi tabi ki wọn maa ṣe igbọnsẹ gbuuru.
O ni omi inu ara ni irufẹ ẹni bẹe yoo maa ya danu, ti omi inu ara eeyan ba si ti tan, iku ko jina si irufẹ ẹni bẹẹ.
O ṣalaye pe "Awọn nnkan wa ti wọn n pe ni 'electrolyte'ninu agọ ara, to ba ti jo danu ti wọn ko si tete daa pada, iku de niyẹn."
- A ti bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ẹ̀sùn tí Igboho, Akintoye àti Ilana Omo Oodua gbé wa síwájú wa- ICC
- Ọmọ Naijiria 350 ni ẹ̀mí wọn sọnù nínù ìjàmbá ọkọ̀ ojú omi lọ́dún 2020
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ ọkùnrin tó gbé ọ̀kadà iléesẹ́ sá lọ lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta tó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́
- Ó kéré tán, ajínigbé ti pa èèyàn 222 láàrìn oṣù mẹ́ta ní Kaduna- Gomina El Rufai
Ọna abayọ
Bo tilẹ jẹ pe Olaniyi sọ pe awọn ọmọde ati agbalaba lo wa ninu ewu to pọ ju lọwọ majele ounjẹ, o fi kun pe ti irufẹ ẹni bẹẹ ba le tete mu "ORS" ti wọn n pe ni "somi dagbo," irufẹ ẹni bẹẹ ni ireti.
Ẹwẹ, Olaniyi gba awọn eeyan nimọran lati maa gbe ounjẹ gbona daadaa ki wọn to jẹ.
Ki wọn si tun dẹkun ati maa mu omi ti ko mọ geere.
Ṣugbọn o ni ọna abayọ kankan ṣoṣo to daju ni pe ki eeyan tete kọri si ile iwosan to ba ti ri irufẹ apẹrẹ bẹẹ.
- Emmanuel kó sí gbaga ólọ́pàá lórí ẹ̀sùn pé ó lu ìyàwó rẹ̀ pa nítórí ó kọ ìbálòpọ̀
- Wọ́n ní Ìyá Esabod yẹn ma ń ṣépè, fi òṣèré wọ́lẹ̀, mò ń retí èsì yín sí ọ̀rọ̀ tí mo fi síta yìí - Mr Portable
- Kò sọ́jà mọ́! A ti ti Ọjà Ladipo pa nítorí rògbòdìyàn tó bẹ́ sílẹ̀ níbẹ̀ - `ijọba ìpínlẹ̀ Eko
- Ẹ̀ṣọ́ ìyàwó Gómìnà Ekiti Bisi Fayemi bọ́ sọ́wọ́ ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn ìfipábánilòpọ̀ l'Abuja
- Àfinra! Ẹ wá máa lọ ilé ẹ̀yin akẹ́kọ̀ọ́ títí di ọjọ́ wájú, a ti ti ìbugbé ilé ẹkọ́ pa torí Covid-19 - Fásitì Unilag

















