Sunday Igboho: Rògbòdìyàn yóò bẹ́ sílẹ̀ láàrin Naijiria àti Benin tí wọ́n bá fi Igboho sílẹ̀ báyìí- Malik Olusegun Falola
Ọkan lara awọn agbẹjọro ajijagbara Yoruba Nation, Sunday Ighboho, ti sọ pe wọn n daabo bo ajijagbara naa ni bo ṣe wa ninu ẹwọn lasiko yii.
Agbẹjọro naa, Malik Olusegun Falola sọ fun awọn akọroyin pe ijọba Benin mọọmọ fi Igboho si ahamọ ni, ki awuyewuye to n waye lori ọrọ rẹ le dinku.
Falola, to jẹ olukọ nipa imọ ofin ni fasiti kan lorilẹ-ede Benin Republic ṣalaye pe ofin ajọ ECOWAS ko fun ijọba Naijiria lanfaani lati gbe Igboho wa si Naijiria lati wa jẹjọ.
- Mo nífẹ̀ẹ́ rẹ "baby" bóo ṣe jẹ́ kí ọkùnrin míì gbẹ́nu sí ìdí, ọyàn rẹ nílé Ẹlẹ́gbọ̀n-ọ́n àgbà BB Naija - Ọkọ Tega
- Olórí ọ̀dọ́ ẹgbẹ́ PDP sọ àbùkù ọ̀rọ̀ sí Ààrẹ Buhari àti SGF, ẹ̀wọ̀n jàntò ló rí he!
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá Naijiria ti yọ Abba Kyari nípò nítórí ẹ̀sùń tí US fi kàn án
- Àwọn jàndùkú kọlu Amuludun FM n'Ibadan, wọ́n ba ọ̀kẹ́ àìmoye dúkìá jẹ́
- Ọta ìbọn ba ẹnìkan nígbà tí àwọn òṣìṣẹ́ aṣọ́bodè àti ará ìlú kọjú ìjà síra wọn ní Yewa nípìnlẹ̀ Ogun
- Àwọn àgùnbánirọ̀ 25 lùgbàdì àrún Coronavirus ní ìpàgọ̀ NYSC
- Ta a ni ọ̀rẹ́ tóòtọ́, Ọba Buhari Oloto tó kú tó mú Ebenezer Obey wà nínú ìbànújẹ́?
O ni "Ofin agbaye ati ofin ajọ ECOWAS ko fun Buhari laaye ko sọ pe ki wọn gbe Sunday Igboho wa si Naijiria lati wa jẹjọ."
Falola ni ijọba Naijiria le bere pe ki ijọba Benin gbe ẹni to ba jale tabi pa eeyan wa si Naijiria, ṣugbọn kii ṣe bii ẹni ti ko ṣẹ labẹ ofin bii Igboho.
Agbẹjọro naa sọ siwaju si pe ẹni to ba n wa aabo lori ọrọ to jọ mọ ọrọ oṣelu yoo ri abo naa gba lọwọ ijọba Benin Republic.
O fi kun pe ajijagbara naa tun le maa gbe inu ilu naa gẹgẹ bii ẹni to lọ fi ori rẹ pamọ lai si wahala kankan.
Ni ti awọn to n funrere pe ki wọn tu Igboho silẹ, Falola sọ pe o ṣeeṣe ki igbesẹ bẹẹ da wahala silẹ laarin orilẹ-ede Naijiria ati Benin Republic.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, wọn le ṣekupa Igboho ti wọn ba tu silẹ lọwọ yii pe ko maa lọ.
O ni "Ti awọn kan ba ni ki wọn fi Sunday silẹ bayii ko le ni ominira, ẹni naa fẹ ṣekupa ni."
"To ba jẹ ilu oyinbo ni, wọn le fi silẹ ko maa lọ nitori abo to peye wa nibẹ, amọ ko si abo to peye nibi."
"To ba n lọ laarin ilu ti wọn ba yinbọn fun nkọ? Tabi ki wọn lọ sile rẹ lati lọ yinbọn nibẹ."
Falola ni bo tilẹ jẹ pe ẹwọn ni Sunday Igboho wa, ko yẹ ki wọn fi irufẹ ọwọ ti ba fi mu awọn ọdaran mu.
- 'Hàá, irú ikú tí ọmọ mí kú kò tọ́ síi, aláànú mí ní'
- Àfìgbà tóò dúró ká jọ gbé orin tuntun wa pẹ̀lú Alhaji Mustapha Abiola jáde - Ẹnìkejì Tope Ajogbajesu
- Kí ni àwọn ẹ̀sun tuntun tí ìjọba ìpínlẹ̀ Kaduna tún gbé dìde tako Ibrahim El-zakzaky?
- Ikú Tope AjogbaJesu, ohun tí a mọ̀ nípa ohun tó ṣokùnfà ikú rẹ̀ nìyí
- 'Lábẹ́ òfin àjọ ECOWAS, kó ṣééṣe kí Benin Republic jọ́wọ́ Sunday Igboho fún Nàìjíríà'





















