AjogbaJesu Twins: Ọgbẹ́ inú, Ulcer ló pa Tope, ọ̀kan lárá àwọn ìbejì AjogbaJesu - Amágbálẹ́gbẹ́ rẹ̀

Oríṣun àwòrán, Ajogbajesu instagram
Tọpẹ, ọkan lara awọn ibeji Ajogbajesu ti jade laye. Akọrin ẹmi naa jade laye lọjọ Ẹti nilu Ibadan
Gẹgẹbi ọkan lara awọn amugbalẹgbẹ rẹ ṣe sọ fun BBC News Yoruba, ọgbẹ inu, iyẹn Ulcer lo ṣokunfa iku rẹ.
Gẹgẹ bi alaye ti amugbalẹgbẹ rẹ naa ṣe fun BBC News Yoruba, o ti to ọjọ melokan bayii ti akọrin naa ti n ba aisan ọgbẹnu inu Ulcer faa.
- Àfìgbà tóò dúró ká jọ gbé orin tuntun wa pẹ̀lú Alhaji Mustapha Abiola jáde - Ẹnìkejì Tope Ajogbajesu
- Kí ni àwọn ẹ̀sun tuntun tí ìjọba ìpínlẹ̀ Kaduna tún gbé dìde tako Ibrahim El-zakzaky?
- 'Ẹ yọ Ọgá Ọlọ́pàá Abba Kyari tí US fẹ̀sùn kàn lórí ọ̀rọ̀ Hushpuppi kúrò nípò kíá!'
- 'Lábẹ́ òfin àjọ ECOWAS, kó ṣééṣe kí Benin Republic jọ́wọ́ Sunday Igboho fún Nàìjíríà'
- 'Ẹgbẹ́ APC ẹ funra, "Oríyọmí" lásán ni Akeredolu fí na Jegede mọ́lẹ̀ ní iléẹjó tó gajù lọ'
- Èyí ni bí wọ́n ṣe pa akẹ́kọ̀ọ́ Poly Ibadan tí wọ́n sì sọ òkú rẹ̀ sí orí àkìtàn
- ÌṢé lóòtọ̀ ni gbajúgbajà òṣèré, Racheal Oniga ti jáde láyé?
O ni nigba ti awọn amugbalẹgbẹ rẹ kan de ile rẹ ni owurọ ọjọ Ẹti, ọgbọn ọjọ oṣu keje ọdun 2021 ni wọn baa lori ibusun to wa ti gbogbo ara rẹ ti le. Eyi lo mu ki ẹnikeji rẹ, iyẹn Kehinde o paṣẹ ki wọn tete maa gbe lọ si ileewosan.
"Nigba ti wọn fi de ileewosan Ọyọmesi nilu Ibadan ni wọn rii pe ko si ẹjẹ lara wọn mọ. Nitori ọgbẹ inu ti wọn ni, o ti wọ aga ara wọn gan, nibẹ ni wọn dakẹ si ni owurọ yii"
Aisan ọgbẹ inu yii lawọn dokita ni o ti wọ agọ ara akọrin ẹmi naa eleyi ti ko si jẹ ko si ẹjẹ pupọ lara rẹ mọ.
Ọmọ mẹta ati iyawo ni akọrin naa fi silẹ saye lọ.
Tope AjogbaJesu jáde láyé!

Oríṣun àwòrán, other
Ọkan lara awọn ibeji AjogbaJesu, ti orukọ rẹ n jẹ Tọpẹ ti jade laye.
Tọpẹ AjogbaJesu gẹgẹ bi ọpọ ṣe mọọ jẹ ọkan lara awọn akọrin meji ninu ẹgbẹ orin AjogbaJesu Twins.
Orin Kristẹni ni wọn yan laayo lasiko ti irawọn wọn jade pẹlu ọwọ 'tungba'ti wọn fi nkọrin ẹmi tiwọn.
Ọkan lara awọn to sun mọ olorin naa sọ pe owurọ ọjọ Ẹti lo jade laye.














