University of Calabar: Ẹ wó bí akẹ́kọ̀ọ́ ìmọ̀ ìṣègùn ṣe rí òkú ọ̀rẹ́ rẹ̀ nínú kílásìí...

Oríṣun àwòrán, Enya Egbe
Arakunrin Enya Egbe ti sọ iriri rẹ pẹlu bi o ṣe sa kuro ni kilaasi ti wọn ti n kọ nipa ẹya ara eniyan lẹyin to ri oku ti wọn fun un lati lo fun iṣẹ amurele.
Arakunrin, ẹni ọdun mẹrindingbọn sọ ohun ti oju rẹ ri ni ọdun meje ṣẹyin ni fasiti Calabar nibi ti awọn akẹkọọ nimọ iṣegun ti pejọ lati ṣiṣẹ pẹlu oku mẹta ti wọn fun wọn lati ṣiṣẹ le lori.
Amọ, iyalẹnu lo jẹ fun un nigba ti o ri pe oku ti wọn fun oun lati ṣiṣẹ le lori jẹ oku ọrẹ oun timọ timọ fun ọdun meje, Divine ti wọn si ti n wa.
- Wo àmí ẹ̀yẹ tí Abba Kyari tí gba gẹ́gẹ́ bí ògbóǹtagìrì ọlọ́pàá kí wọ́n tó fi ẹ̀sùn ìwà àjẹbánu kàn án
- Kéére óò! Ọ̀gá àgbà ọlọ́pàá tí yan igbákejì Kọmiṣọnna ọlọ́pàá,Tunji Disu ní olórí ikọ̀ àmúsẹ̀yá àwọn Ọlọpaa
- Olaiya Igwe ò kú o, àyè ló wà
- Kí ni yóò ṣẹlẹ̀ sí gbajúmò ọlọ́pàá, Abba Kyari tí wọ́n kó pọ̀ mọ́ "rógà" pẹ̀lú Hushpuppi?
- Àwọn dókítà da iṣẹ́ sílẹ̀ káàkiri Naijiria, ilé ìwòsàn dá páròpáro!
- Micheal kó sí gbaga ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn pé ó lu ọlọ́kadà pa ní Abeokuta
O ni awọn jọ ma n lọ si ile igbafẹ ni alẹ ni, to si sọ wi pe oju ibọn meji ni oun ri ni igba aya rẹ.
Ọkan lara awọn akẹkọọ ti wọn tẹle sare jade ni Oyifo Ana, ti o si ba nibi ti o ti n sun ẹkun.
''Ọpọlọpọ awọn oku ti a ma n lo ni ileewe lati fi kọ ẹkọ ni iho ibọn wa nibẹ, to si ṣeeṣẹ ki awọn eniyan naa ma hu iwa ọdaran.''
''Mo ti lẹ ti ri awọn ọlọpaa ti wọn n gbe oku awọn eniyan wa si ileewe wa nitori o ni ile igbokusi.''

Oríṣun àwòrán, AFP
Lẹyin iṣẹlẹ naa ni Egbe wa ranṣẹ si ẹbi awọn ọrẹ rẹ Divine lati wa gbe oku rẹ ti wọn ti n wa tipẹ tipẹ.
Iroyin nipe awọn obi Divine ti n wa lati agọ ọlọpaa kan si omiran lẹyin ti ọlọpaa mu oun ati awọn ọrẹ rẹ ti wọn lọ gbafẹ.
Awọn obi Divine pada gba oku naa,ti wọn si ṣewadii ọlọpaa ti o ṣekupa a, ti wọn si yọ niiṣẹ.
Iṣẹlẹ naa mi Egbe titi, to fi mu u padanu ọdun kan lẹnu ẹkọ rẹ, ti ko si le e ba awọn ara rẹ jade fasiti nigba kan naa.
Ọdun to kọja kaakiri orilẹede Naijiria ni awọn ọdọ bọ sita lati ṣe ifẹhọnuhan Endsars tako bi awọn ọlọpaa ṣe n pa awọn ọdọ Naijiria ati bi wọn ṣe n fi iya jẹ wọn lọna aitọ.
- Wo iná olójú mẹ́rìndínlógún, arugbá àtàwọn ohun míì tí yóò wáyé l'Ọdún Osun Osogbo 2021
- Olaiya Igwe ò kú o, àyè ló wà
- Àwọn ọmọ Sunday Igboho mẹ́jọ̀ nínú méjìlá níkan ní DSS gbé wá sí iléẹ̀jọ́ - Agbẹjọrò
- Oyedepo tún ti fèsì sí áwọn tó bẹnu àtẹ́ lu ìgbésẹ̀ tó gbé lórí àwọn Pásítọ̀ rẹ̀
- Kí ni yóò ṣẹlẹ̀ sí gbajúmò ọlọ́pàá, Abba Kyari tí wọ́n kó pọ̀ mọ́ "rógà" pẹ̀lú Hushpuppi?
- Àwọn dókítà da iṣẹ́ sílẹ̀ káàkiri Naijiria, ilé ìwòsàn dá páròpáro!
- Ìgbìmọ̀ ẹlẹ́nu mẹ́rin ti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ lórí ọ̀rọ̀ ìwádìí Abba Kyari àti Ramoni Igbalode

Oríṣun àwòrán, AFP














