Olaiya Igwe: Kò sí nnkan tó ṣe Ebun Oloyede, àlááfíà ló wà - Sokoti Alagbede

Olaiya Igwe

Oríṣun àwòrán, @olaiya_igwe01

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Gbajugbaja oṣere tiata Yoruba, Adewale Abdulrasak Sokoti, ti ọpọ eeyan mọ si Sokoti Alagbede ti sọ pe ko ohunkohun to ṣe Ebun Oloyede ti ọpọ mọ si Olaiya Igwe.

Sokoti lo sọ ọrọ naa ninu ifọrọwerọ kan pẹlu BBC Yoruba lori iroyin ti awọn eeyan kan n gbe kiri pe Olaiya Igwe ti jade laye.

O ni oun ati Olaiya ṣi foju ganni ara wọn laarin iṣẹju diẹ ki akọroyion BBC to kan si oun, alaafia si ni Olaiya wa.

Sokoti sọ pe "Ẹ ma ka awọn to n sọ pe Olaiya ti ku si o, ko si nnkankan to ṣe Igwe."

"Mo n fi da yin loju pe Olaiya ko ku, alaafia lo wa, emi pẹlu rẹ ṣi sọrọ ni iṣẹju marun un sẹyin."

Olaiya Igwe

Oríṣun àwòrán, NaijaExpress.com

O tẹsiwaju pe "Mi o mọ nnkan to maa n ṣe awọn eeyan wa to jẹ pe ti wọn ba ti gbọ iroyin bayii, wọn kii fidi rẹ mulẹ ki wọn to maa pin irufẹ iroyin bẹẹ kiri."

Àkọlé fídíò, Esabod, Sunday Igboho: Kò burú bí Igboho ṣe wà lẹ́wọ̀n báyìí,ọ̀rọ̀ rẹ̀ dàbí i ti aláboyún

Ṣaaju ni iroyin kan ti kọkọ gbode lọjọ Aje pe Olaiya Igwe ti jade laye nile iwosan ijọba apapọ to wa niluu Ibadan, UCH.

Iroyin naa ni Olaiya n ṣaisan kidirin, eyii to mu ẹmi rẹ lọ

Ebun Oloyede jẹ ọkan gboogi lara awọn oṣere tiata Yoruba ti irawọ wọn tan kaakiri orilẹ-ede Naijiria ati kaakiri agabye.

Lara awọn tiata ti Olaiya ti ṣe to milẹ titi ni Iru Esin, Ololade Mr Money, ati bẹẹ bẹẹ lọ.