Osun Osogbo festival: Wo iná olójú mẹ́rìndínlógún, arugbá àtàwọn ohun míì tí yóò wáyé l'Ọdún Osun Osogbo 2021

Oríṣun àwòrán, Negrohood
Yoruba ni ọdọọdún là ń rí awusa, ọdọọdún là ń rí orogbo, kii yẹ bí ọdún Osun Osogbo, kárí ilé kárí oko sì ni ìròyìn rẹ máa ń kan ká.
Ayẹyẹ ọdún Osun Osogbo tí ọdun yìí tún ti gberasọ tohun ti iyi to máa ń mú dání.
Wiwẹ ìlú mọ lọ kọ́kọ́ fi ṣide tí ọdun yìí, èyí tí wọn ń pè ní "Ìwọpopo" tí wọn máa fi ń bẹ̀rẹ̀ bíbọ yemoja odò Oṣun lọdọọdún.
- Oyedepo tún ti fèsì sí áwọn tó bẹnu àtẹ́ lu ìgbésẹ̀ tó gbé lórí àwọn Pásítọ̀ rẹ̀
- Kí ni yóò ṣẹlẹ̀ sí gbajúmò ọlọ́pàá, Abba Kyari tí wọ́n kó pọ̀ mọ́ "rógà" pẹ̀lú Hushpuppi?
- Olaiya Igwe ò kú o, àyè ló wà
- Àwọn dókítà da iṣẹ́ sílẹ̀ káàkiri Naijiria, ilé ìwòsàn dá páròpáro!
- Àwọn ọmọ Sunday Igboho mẹ́jọ̀ nínú méjìlá níkan ní DSS gbé wá sí iléẹ̀jọ́ - Agbẹjọrò
Ataoja ti ilu Osogbo, Kabiyesi Ọba Jimoh, Oyè Tunji (Olaonipekun Laaroye II) lo dárí àwọn ìgbìmò Ìwọpopo, àwọn Oloye, àwọn olùjọsìn, aṣojú ijọba àtàwọn olùgbé ìlú Osogbo nínú ìlànà ṣíṣe wiwẹ ìlú mọ gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe rìn ja àwọn pooro àti ona kan ni ilu ja ni ìsòrí ìsòrí, lomode àti lagba láti lọ ṣe Kabiyesi Ataoja to joko si aarin gbùngbùn ìlú.
Pẹlu ọpọ ìjọ àti ilu, gbogbo ìlú lọ ń hó fún idunu fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ wákàtí gẹgẹ bí àwọn aráàlú ṣe tú jáde kẹti kẹti láti side ayẹyẹ ọdún ńlá yìí laarin gbogbo ọdún ní ilè Yoruba.
Àwọn ètò míì tó ti wà níkalẹ tí yóò wáyé nìbi ayẹyẹ ọdún Oṣun Osogbo tí ọdun yìí ni:
- Titan "iná olójú mẹ́rìndínlógún" to tí lo eedegbeta ọdún laye èyí tí yóò wáyé ní Ọjọbọ ọjọ́ Kàrún oṣù kẹjọ.
- Iboriade - eyi ni akojopo àti àfihàn gbogbo adé àwọn Ọba Ataoja Osogbo tó ti je lateyin wa fún ṣíṣe àdúrà èyí tí yóò wáyé lọ́jọ́ Kẹ̀sán oṣù kẹjọ.
Pabanbari asekagba ọdún náà èyí tí wọn safihan rẹ lórí ayélujára fún gbogbo agbaye yoo waye ni ọjọ kẹtàlá oṣù kẹjọ, ohun si ni ọjọ bí ó odò Oṣun èyí tí Arugba Oṣun yóò lọ rúbọ ní Odò isembaye ti Oṣun Osogbo.
- Ìgbìmọ̀ ẹlẹ́nu mẹ́rin ti bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ lórí ọ̀rọ̀ ìwádìí Abba Kyari àti Ramoni Igbalode
- Micheal kó sí gbaga ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn pé ó lu ọlọ́kadà pa ní Abeokuta
- Ọta ìbọn ba ẹnìkan nígbà tí àwọn òṣìṣẹ́ aṣọ́bodè àti ará ìlú kọjú ìjà síra wọn ní Yewa nípìnlẹ̀ Ogun
- Àwọn àgùnbánirọ̀ 25 lùgbàdì àrún Coronavirus ní ìpàgọ̀ NYSC
- N kò mọ̀ pé àsìkò yìí ni máa dágbéré fún Rachel Oniga- Jide Kosoko












