Oniduromi: Taní Wolí rẹ̀? ẹ wò mí bí mo ṣe lọ ''minister'', tí Woli Joshua Iginla fí ọkọ̀ ńla ta mí lọ́rẹ - Adeyinka Alaseyori

Oríṣun àwòrán, Facebook/Joshua Iginla Ministries
Evangelist Yinka Alaṣeyori ti fi idunnu rẹ han lori bi Woli rẹ, Josua Iginla ṣe fi ọkọ bọgini ta a lọrẹ.
Alaṣeyori naa lo lọ kọrin ni ile ijọsin wọn to wa ni ilku Abuja ti wọn pe ni Champions International, lorilẹede Naijiria.
Alaṣẹyọri lasiko to n fi idunnu rẹ han bẹrẹ ibeere wi pe tani Woli rẹ, nibo ni ile ijọsin rẹ, to si gbadura fun woli rẹ naa.
- Ẹ jọ̀wọ́ ẹ jẹ́ kí àláfíà jọba lórí orin "Oniduro Mi", ìyá ni Tope Alabi jẹ́ sí mi - Adeyinka Alaṣeyori
- Alaseyori kọ́ ló ni orin "Oniduro Mi", àmọ́ ìdí tí mi ò ṣe bá a jà pé ó jí orin mi kọ nìyìí - Tolu Adelegan
- Wòlíì Genesis fèsì lórí ọ̀rọ̀ Tope Alabi nípa orin 'Oniduromi'
- Ẹ ṣeun, ẹ kú àdúrótì mi! Ẹ wo ọ̀rọ̀ tí Tope Alabi padà sọ nípa awuyewuye tó wáyé lóri orin Oniduro Mi
''E wo ni ki a lọ minister, ki a gba honourarium to lamilaaka, ki wọn tun fi ọkọ bọgini, mọto ẹlẹṣẹ mẹrin ta wa lọọrẹ.?''
Bakan naa lo bẹrẹ si ni kọ orin lati fi idunnu rẹ han pe aanu ni oun ri gba.
Alaṣeyori ni igba akọkọ ni yii ti oun yoo ri Woli Joshua Iginla, ti oun si lọ si ile ijọsin rẹ.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Joshua Iginla Ministries
O ni ko sọ wi pe ki oun polongo ore to ṣe fun oun, amọ lati fi idunnu oun han ni oun ṣe gbe si ori ẹr ayelujara wi pe aanu ni oun ri gba.
Ko pẹ ti olorin ẹmi ,Yinka Alaseyori di ilumọka lẹyin ti gbas gbos waye ni aarin rẹ ati olorin ẹmi, Tope Alabi to sọrọ orin rẹ, Oniduromi, to si ni pe ko tọ ki o pe Ọlọrun ni "Oniduro Mi".
- Mo nífẹ̀ẹ́ rẹ "baby" bóo ṣe jẹ́ kí ọkùnrin míì gbẹ́nu sí ìdí, ọyàn rẹ nílé Ẹlẹ́gbọ̀n-ọ́n àgbà BB Naija - Ọkọ Tega
- Olórí ọ̀dọ́ ẹgbẹ́ PDP sọ àbùkù ọ̀rọ̀ sí Ààrẹ Buhari àti SGF, ẹ̀wọ̀n jàntò ló rí he!
- Wo ǹkan tí a mọ̀ nípa akẹ́kọ̀ọ́ fásitì FUTA tó kú àti ìdí tí àwọn akẹ̀kọ̀ọ́ fi faraya
- Njẹ́ o mọ̀ pé bíi ọdún 700 sẹ́yìn ni wọ́n ti ń bọ Osun-Osogbo? Mọ̀ síi nípa ìtàn ojúbọ̀ nàá
- Ta ni Tunji Disu ti wọ́n kéde láti rọ́pò Abba Kyari?
- Ẹ wó bí akẹ́kọ̀ọ́ ìmọ̀ ìṣègùn ṣe rí òkú ọ̀rẹ́ rẹ̀ nínú kílásìí...
- Dáa padà! Àwa kìí ṣe ẹgbẹ́ kan náà pẹ̀lú APC tó dojú Nàìjíríà kodò -PDP sí Jega
Amọ awọn ọmọ Naijiria faraya, ti wọn si sọrọ kubakugbe si Tope Alabi wi pe ko tọ si lati tabuku.
Lẹyin naa ni Adeyinka Alaseyori kọkọ ṣebi ẹni ti ko fẹ mẹnu ba ọrọ yii rara lati igba to ti ṣẹlẹ, amọ ni ibi ti o ti n ṣe isin orin iyin lati ṣaami ayẹyẹ ọjọ ibi rẹ lo ti bẹ gbogbo awọn eeyan lori ọrọ yii.
Lo ba tun fi adura bọ ẹnu fun gbogbo awọn to n ṣe iṣẹ to jẹ ọna to tọ pe: "gbogbo ẹyin tẹ n ṣe iṣẹ ọna to tọ to n mu ounjẹ wa sori tabili yin, ẹ o maa lowo sii ni".














