Sunday Igboho: Páropáro ní iléẹjọ́ dá, tí wọn sì fi àgádágodo ti ẹnu ọ̀nà

Yatọ si ikede to waye lọjọ Aje pe igbẹjọ awọn eeyan ti DSS ko nile Sunday Igboho yoo waye lọjọ Isẹgun, tii se ọjọ ọdun Ileya, amọ ọrọ ko ri bẹẹ mọ.
Nigba ti BBC Yoruba kan sile ẹjọ giga ijọba apapọ to wa nilu Abuja, lati mọ boya lootọ nile ẹjọ naa yoo joko lati gbọ ẹjọ naa, a ri pe paro paro ni ibẹ da.
Koda, a ko ri awọn agbẹjọro, ọlọpaa tabi awọn eeyan kankan to yọju sile ẹjọ naa lati wa mọ ohun ti yoo sẹlẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ṣé lóòtọ́ ni ìjọba Naijiria ti fi pampẹ̀ òfin mú Sunday Igboho?
- "Á dá ohun àlùmọ́ọ́nì wa jọ láti gbèjà Sunday Igboho nílé ẹjọ́"
- Ẹ rántí Buhari àtàwọn gómìnà nínú àdúrà bí ẹ ti ń ṣọdún Iléyá - Tinubu
- Ààrẹ Ògbóni sọ òkò ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ sí Gani Adams torí bó ṣe tàbùkù Ọba Ogboni tó ṣe ìwọ́de Yorùbá Nation
- Ẹ̀yin ọmọ Nàíjíríà, mó rí ìlàkàkà yín, ẹ ṣe sùúrù nítórí ìyá yìí yóò dópìn - Ààrẹ Buhari
- Àwọn agbébọn ti pa ọlọ́pàá mẹ́tàlá ní Zamfara- Gomina Zamfara
- Ilé ẹjọ Májísírèètì Yaba nípinlẹ Eko ti gba béèlì àwọn olùwọde Yoruba Nations 49 tí wọn wa ní àhámọ
- Ohun márùn ún tó mú ìgbé ayé le fọ́mọ Nàìjíríà lójoojúmọ́
Koda, agadagodo ni wọn fi ti ẹnu ọna abawọle ile ẹjọ naa, ti gbogbo ọọfisi to wa nibẹ si wa ni titipa.
Bẹẹ ba gbagbe, Adajọ Yomi Aliyu ti kede saaju fun BBC Yoruba pe oun yoo yọju sile ẹjọ naa lonii, boya adajọ joko lati gbọ ẹjọ naa abi bẹkọ.

Adajọ fi igbẹjọ awọn afurasi ti DSS ko nile Sunday Igboho si ọjọ ọdun Ileya

Oríṣun àwòrán, DSS
Agbẹjọro fun awọn eeyan mejila ti DSS ko nile Sunday Igboho Yomi Aliyu, ti ni igbẹjọ yoo bẹrẹ lori ẹjọ ti wọn pe tako ajọ DSS nile ẹjọ ni ọjọ Isẹgun ọla.
Bẹẹ ba gbegbe, ọla ọjọ Isẹgun ni ọjọ ọdun Ileya, ti ijọba si ti kede pe isinmi ọlọjọ fun awọn ọmọ Naijiria lati gbadun ọdun naa.
Ireti si wa pe awọn osisẹ ile ẹjọ, awọn agbẹjọro atawọn adajọ gan yoo wa lẹnu isinmi fun ọdun Ileya naa.
- Ó tó gẹ́, Sunday Igboho fẹ́ gbé ìjọba lọ ilé ẹjọ́ bí wọn kò bá tú àwọn èèyàn rẹ̀ sílẹ̀
- "DSS tó kọlu ilé Sunday Igboho dàbí pé wọ́n gbé ‘Map’ ilé náà lọ́wọ́ ni"
- Ìkọlù DSS sílé Sunday Igboho tàpá sófin, ìwà ìjọba ológun ni - Falana
- Sunday Igboho ń ṣọ̀fọ̀ ọ̀kan lára àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ tí DSS pa
- Sunday Igboho ń dáró èèyàn kejì tí DSS pa nílé rẹ̀
- DSS kò mú mi lọ́dọ̀ Guru Maharaji, èmi rèé n‘Ibadan, ẹ sinmi àhesọ ọ̀rọ̀ - Sunday Igboho
Nigba to n fidi ọrọ naa mulẹ fun BBC Yoruba, Agbẹjọro Aliyu ni lootọ ni ijọba fi ọjọ igbẹjọ si ọjọ ọdun ileya.
"Iru rẹ ko sẹlẹ ri, a ko wa mọ ohun to le mu ki adajọ ni oun fẹ gbọ ẹjọ naa lọjọ ọdun, to si mọ pe isinmi wa, gbogbo awọn afurasi yii si ni wọn fẹ ko lọ sile ẹjọ.

Oríṣun àwòrán, DSS
Amọ ibeere ni pe awọn wo gan lo fẹ ko awọn afurasi yii de ile ẹjọ.? Awọn ọlọpaa ti yoo ko wọn lọ gan yoo se ọdun nile.
Amọ, a ko tii mọ iru ara ti wọn fẹ da, awa yoo de ile ẹjọ lọla, bi adajọ joko, bi ko joko, awa yoo wa nibẹ.
Awa la pe ijọba apapọ lẹjọ lati tako bi wọn se ti awọn eeyan naa mọle lọna ti ko ba ofin mu, ti wọn ko si jẹ ki awa agbẹjọro wọn ri wọn."
Aliyu ni ohun to tiẹ wa n kọ awọn lominu ni ọrọ obinrin kan soso to wa laarin wọn, o ni wọn ko gba laaye lati paarọ asọ rẹ.
"Pata kan soso to wọ si idi ni ọjọ ti wọn mu, naa lo si wa ni idi rẹ, wọn ko jẹ ko paarọ pata tabi asọ."
Aliyu wa fikun pe ohun ti awọn n beere nile ẹjọ ni pe ki adajọ pasẹ pe ki awọn DSS fi oju awọn eeyan mejeejila naa han sita fun wa.
A fẹ fi oju wa ri wọn lati mọ boya awọn mejeejila si wa laye tabi wọn ti ku, a fẹ mọ."
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- "Seyi Makinde, yé dá ìjọba ṣe, wá nǹkan ṣe lórí ọ̀rọ̀ ààbò tó mẹ́hẹ́"
- Ojú àwọn arìnrìnàjò rí màbo lójú ọ̀nà Márosẹ̀ Ibadan sí Eko torí ọdún Ileya
- Wo ǹkan mẹ́ẹ̀dògún tó yẹ kí o mọ̀ nípa olówó ayé Obi Cubana
- Adójútini ni Bíṣọ́bù Kukah lórí ọ̀rọ̀ tó sọ nípa Buhari l'Ámẹ́ríkà - iléeṣẹ́ Áàrẹ
- Ọkọ Lizzy Anjorin fí ẹ̀bùn ọkọ̀ N20m fi ta lọ́rẹ
- Buhari kò jẹ́ kí Yoruba àtàwọn ẹ̀yà míràn gbérí ní Naijiria - Ẹgbẹ́ Yoruba VOR
- "Mo fi nǹkan ọkùnrin mi sínú àgádádogo fún ọ̀sẹ̀ méjì fún ìbálòpọ̀, wàhálà bá de"
- Àwọn egungun ẹ̀yìn mi lágbo tíátà ní Adebimpe Oyebade fi ọ̀nà ẹ̀bùrú gbà mọ́ mi lọ́wọ́ - Yomi Fabiyi
- Wo àwòrán bí ìrìnàjò Hajj ṣe n lọ ní Mecca lásìkò Covid-19
- Mo tún ibojì Funmi Martins ṣe torí ojú ń tì mí nípa ipò ìtìjú tó wà - Ashabi Olorisha



















