Eid-el-Kabir: Tinubu rọ àwọn mùsùlùmí láti tẹ̀lé ìlànà Allah bí wọ́n ṣé ń yayọ̀ ọdún

Oríṣun àwòrán, others
Eekan ẹgbẹ oṣelu APC, Asiwaju Bola Tinubu ti rọ awọn musulumi lati fi ara wọn jin, ki wọn si maa tẹle Ilana Allah bi wọn ṣe n ṣọdun Ileya.
Tinubu tun rọ àwọn musulumi lati maa gbagbe awọn alaini bi wọn ti n ṣe ọdun Sallah.
Aṣiwaju ni awọn musulumi ko gbọdọ gbagbe pe ohun ti ọdun Ileya wa fun ni lati ṣeranwọ fawọn ti ko rọwọ họri.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ṣé lóòtọ́ ni ìjọba Naijiria ti fi pampẹ̀ òfin mú Sunday Igboho?
- "Á dá ohun àlùmọ́ọ́nì wa jọ láti gbèjà Sunday Igboho nílé ẹjọ́"
- Ààrẹ Ògbóni sọ òkò ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ sí Gani Adams torí bó ṣe tàbùkù Ọba Ogboni tó ṣe ìwọ́de Yorùbá Nation
- Ẹ̀yin ọmọ Nàíjíríà, mó rí ìlàkàkà yín, ẹ ṣe sùúrù nítórí ìyá yìí yóò dópìn - Ààrẹ Buhari
- Àwọn agbébọn ti pa ọlọ́pàá mẹ́tàlá ní Zamfara- Gomina Zamfara
- Ilé ẹjọ Májísírèètì Yaba nípinlẹ Eko ti gba béèlì àwọn olùwọde Yoruba Nations 49 tí wọn wa ní àhámọ
- Ohun márùn ún tó mú ìgbé ayé le fọ́mọ Nàìjíríà lójoojúmọ́
Tinubu sọrọ yii ninu atẹjade to fi sita lati ọwọ oludamọran rẹ lori eto iroyin, Tunde Rahman.
Tinubu sọ ninu atẹjade ọhun pe awọn iṣoro to n koju Naijiria nilo kawọn eeyan tubọ maa tẹle ofin Allah.
Aṣiwaju ni nipa bẹẹ ni orilẹ-ede Naijiria fi le bori awọn ipenija to n koju rẹ.
Tinubu tun rọ awọn musulumi lati rántí Aarẹ Muhammadu Buhari, awọn gomina at'awọn olori mii ninu adura bi wọn ṣe n ṣe ayẹyẹ ọdun Sallah.
Aṣiwaju ni awọn olori Naijiria nilo adura ki wọn le wa ojutuu s'awọn ìṣòro tó n ba orilẹ-ede yìí finra.
Gomina ipinlẹ Eko nigba kan ri ni bayii ni tonile talejo fi le jẹ anfaani orilẹ-ede Naijiria.
"Nitori naa, ninu ayẹyẹ ọdún Ileya yii, a gbọdọ wa oju Allah ki a sì gbé ounjẹ fawọn otosi.
A tun fi asiko yii gbadura fawọn ọmogun wa ati gbogbo awọn ẹṣọ eleto abo to n koju awọn janduku lojoojumọ.
A tun gbadura fun iṣọkan orilẹede Naijiria lasiko yii.
Mo ki gbogbo awọn musulumi ati gbogbo ọmọ Naijiria ku ọdun Ileya," Tinubu lo sọ bẹẹ.
















