Eid-el-Kabir: Tinubu rọ àwọn mùsùlùmí láti tẹ̀lé ìlànà Allah bí wọ́n ṣé ń yayọ̀ ọdún

Bola Tinubu ati Muhammadu Busari

Oríṣun àwòrán, others

Eekan ẹgbẹ oṣelu APC, Asiwaju Bola Tinubu ti rọ awọn musulumi lati fi ara wọn jin, ki wọn si maa tẹle Ilana Allah bi wọn ṣe n ṣọdun Ileya.

Tinubu tun rọ àwọn musulumi lati maa gbagbe awọn alaini bi wọn ti n ṣe ọdun Sallah.

Aṣiwaju ni awọn musulumi ko gbọdọ gbagbe pe ohun ti ọdun Ileya wa fun ni lati ṣeranwọ fawọn ti ko rọwọ họri.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Tinubu sọrọ yii ninu atẹjade to fi sita lati ọwọ oludamọran rẹ lori eto iroyin, Tunde Rahman.

Tinubu sọ ninu atẹjade ọhun pe awọn iṣoro to n koju Naijiria nilo kawọn eeyan tubọ maa tẹle ofin Allah.

Aṣiwaju ni nipa bẹẹ ni orilẹ-ede Naijiria fi le bori awọn ipenija to n koju rẹ.

Tinubu tun rọ awọn musulumi lati rántí Aarẹ Muhammadu Buhari, awọn gomina at'awọn olori mii ninu adura bi wọn ṣe n ṣe ayẹyẹ ọdun Sallah.

Aṣiwaju ni awọn olori Naijiria nilo adura ki wọn le wa ojutuu s'awọn ìṣòro tó n ba orilẹ-ede yìí finra.

Gomina ipinlẹ Eko nigba kan ri ni bayii ni tonile talejo fi le jẹ anfaani orilẹ-ede Naijiria.

"Nitori naa, ninu ayẹyẹ ọdún Ileya yii, a gbọdọ wa oju Allah ki a sì gbé ounjẹ fawọn otosi.

A tun fi asiko yii gbadura fawọn ọmogun wa ati gbogbo awọn ẹṣọ eleto abo to n koju awọn janduku lojoojumọ.

A tun gbadura fun iṣọkan orilẹede Naijiria lasiko yii.

Mo ki gbogbo awọn musulumi ati gbogbo ọmọ Naijiria ku ọdun Ileya," Tinubu lo sọ bẹẹ.