Coronavirus in Nigeria: Abẹ́rẹ́ àjẹsára, Covid 19 ti balẹ̀ bàgẹ̀ sí orílẹ̀èdè Naijiria

Coronavirus

Oríṣun àwòrán, Twitter

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 4

Abẹrẹ ajẹsara covid 19 lati dẹkun itankalẹ arun Coronavirus ti de si orilẹede Naijiria.

Ilu Abuja ni ọkọ afurufu to gbẹ abẹrẹ ajẹsara naa balẹ si, awọn eleto ilera si wa nibẹ lati ri wipe gbogbo rẹ lọ daradara.

Nibayii, Ijọba ti ni awọn elto ilera ni yoo kọkọ gba abẹrẹ ajẹsara naa.

Ti awọn oloṣelu yoo si bẹrẹ si ni gba lati Ọjọ Ajẹ, ọṣẹ too n bọ.

O ti le ni ẹgbẹrun eniyan ti aarun Coronavirus ti mu ẹmi wọn lọ lorilẹede Naijiria.

Wo alakalẹ lati pin abẹrẹ ajẹsara Covid-19

Ni bayii ti ijọba apapọ ti n reti abẹrẹ ajẹsara Covid-19 ni Naijiria, ọpọ eeyan lo ti n woye bi wọn ṣe le ri abẹrẹ naa gba, ati ibi ti wọ ti le gbaa.

Ṣaaju ni minista eto ilera, Ọlọruninbẹ Mamora ti kọkọ kede pe awọn oṣiṣẹ eto ilera to n ṣetọju awọn to ti lugbadi arun na ni yoo kọkọ gba abẹrẹ ọhun.

vaccine

Ẹwẹ, ileeṣẹ ijọba apapọ to n ri si eto ilera alakọbẹrẹ, iyẹn National Primary Health Care Development Agency, NPHCDA, ti kede bi awọn ṣe le gba abẹrẹ naa.

Ninu atẹjade ti wọn fi lede loju opo Twitter wọn, NPHCDA ni awọn eeyan le lọ fi orukọ silẹ lati gba abẹrẹ naa lori ikanni www.nphcda.gov.ng.

Bawo ni ẹ ṣe le fi orukọ silẹ fun abẹrẹ naa?

Ti ẹ ba ti de ori ikanni nphcda.gov.ng, ẹ lọ si abala ti ẹ ti le fi orukọ silẹ fun abẹrẹ naa ni igun apap ọtun.

Skip X post
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post

Ẹ o ri awọn imọran kan nibẹ pẹlu awọn nọmba ẹrọ ibaraẹnisọrọ ti ẹ le pe nipa abẹrẹ ọhun.

Àkọlé fídíò, Francis Olusola Alao: Wọ́n ti ti ọ̀rọ̀ òṣèlú bọ ọ̀rs Sunday Igboho, ṣùgbọ́n..- Oba Olugbọn

Lẹyin naa ni ẹ o ri fọọmu iforukọsilẹ abẹrẹ ajẹsara ọhun.

Lara awọn awọn ohun ti wọn yoo bere ninu fọọmu naa ni orukọ yin, ẹrọ ibaraẹnisọrọ, email, nọmba ile ti ẹ n gbe, ọjọ ibi yin, ibi ti ẹ ti fẹ gba abẹrẹ naa atawọn ohun miran to ṣe pataki nipa yin.

Ti ẹ ba ti tẹ awọn alaye yin sinu fọọmu naa tan, ki ẹ fi ranṣẹ si ajọ NPHCDA.

Ti ẹ ba ti ṣe eyii tan, NPHCDA yoo fun yin ni nọmba idanimọ kan gẹgẹ bii nọmba abẹrẹ ajẹsara yin.

Ẹ wo àwọn tí yóò kọ́kọ́ gba abẹ́rẹ́ àjẹsárá Covid-19 to bá dé sí Naijiria...

Abẹrẹ ajẹsara

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Ijọba orilẹede Naijiria ti fi lede awọn ti yoo kọkọ ni anfaani lati gba abẹrẹ ajẹsara ti yoo koju aarun Coronavirus ni Naijiria.

Ninu atẹjade ti wọn fi lede pẹlu ajọṣepọ Ajọ eto Ilera Lagbaye, WHO ati Ajọ UNICEF ni wọn ti gbe alakalẹ naa jade.

Ijọba ni awọn ti yoo kọkọ ni anfaani si abẹrẹ ajẹsara niiṣe pẹlu bi o ṣe pọn dandan si fun awọn eniyan, ti awọn onimọ nipa eto ilera si lewaju wọn.

Ijọba ni awọn ti bẹrẹ si ni kọ awọn eleto ilera bi wọn yoo ṣe bẹrẹ si ni pin awọn abẹrẹ ajẹsara naa.

Bakan naa ni awọn ẹrọ amohuntutu ti wọn nilo ti wa ni pese kaakiri awọn ojuko ti wọn yoo lo.

Àkọlé fídíò, Coronavirus after one year in Nigeria: Níbo ni ọ̀rọ̀ Covid 19 dé dúró ní Nàìjíríà?

Eyi ni igba akọkọ ti orilẹede Naijiria yoo ma gba abẹrẹ ajẹsara Coronavirus to to miliọnu mẹrin fun awọn araalu lati koju aarun naa.

Amọ orilẹede Naijiria ni orileede kẹta lẹyin Ghana ati Cote d'lvoire ti yoo gba abẹrẹ ajẹsara naa ni ẹkun iwọ oorun ilẹ Afrika.

Ọjọ́ Ìṣẹ́gun ní abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19 tó tó 4 milionu yóò bàlẹ̀ sí Nàìjíríà

Orilẹede Naijiria yoo gba abẹrẹ ajẹsara covid -19 wọle si orilẹede yii bẹrẹ lati Ọjọ Keji, Oṣu Kẹta, ọdun 2021.

Akọwe ijọba orilẹ-ede Naijiria, Boss Mustapha lo kede bẹẹ ninu atẹjade ti wọn fi lede.

Mustapha ni Ajọ to n risi eto ẹkọ lagbaye, UNICEF ni yoo gba abẹrẹ ajẹsara naa wọle lati ileeṣẹ COVAX.

''Abẹrẹ ajẹsara wa kuro ni India ni Ọjọ Kini, Oṣu Kẹta, ọdun 2021 ni alẹ, ti yoo si de ilu Abuja ni ọjọ kẹji ni nkan bi aago mọkanla, ni iyalẹta.

'' A n reti bii miliọnu mẹrin abẹrẹ ajẹsara lati ileeṣẹ COVAX ''

Àkọlé fídíò, Badagry Historical Wells: Omi inú kànga Wawú ló ń kó ọpọlọ àwọn ẹrú lọ

''Kini Osu kẹrin to pe, a n rẹti bii abẹrẹ ajẹsara bii miliọnu ọgọta, ti yoo si ju bẹẹ lọ ki ọdun to pari.''

O damiloju pe oogun abẹrẹ ajẹsara naa yoo wa lati ileeṣẹ apoogun AstraZeneca, eleyii to dara lati gbe pamọ di igba ti wọn ba n fun awọn eniyan''

Covax

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Bakan naa ni ileeṣẹ to n risi ọrọ oogun ati ounjẹ lorilẹede Naijiria, NAFDAC ti buwọlu abẹrẹ ajẹsara AstraZeneca pe o dara lati lo ni orilẹede Naijiria.

Amọ akọwe ijọba Naijiria naa fikun un pe awọn ilana to de aarun Coronavirus naa yoo si wa ni ṣẹpẹ lẹyin abẹrẹ ajẹsara naa.

Johnson ^ Johnson Covid-19 vaccine

Oríṣun àwòrán, EPA

Àkọlé àwòrán, Aarẹ orilẹede South Africa, Cyril Ramophosa ti gba abẹrẹ ajẹsara.

Bakan naa lo ni ida ogoji Naijiria ni awọn yoo fun ni abẹrẹ ajẹsara ni ọdun 2021, ti ida ọgbọn yoo gba ti wọn ni ọdun 2022.

Àkọlé fídíò, Mother tongue day 2021, Akomolede, YSAN: A ti parí iṣẹ́ lórí èdè ìperí Meta-Language Yorùb