Divorce case: Ọkùnrin kan sọ fún iléẹjọ́ láti tú ìgbéyàwó rẹ̀ ká, torí ìyàwó rẹ̀ máa ń gbá a létí

Oríṣun àwòrán, AFP
Ọkunrin kan to jẹ oṣiṣẹ ijọba, Ọgbẹni Oyeniyi Oyedepo sọ fun ileẹjọ agbegbe to wa ni Mapo niluu Ibadan pe ki wọn tu igbeyawo ọdun mẹrinla laarin oun ati iyawo oun ka.
Idi abajọ ni pe Ọgbẹni Oyedepo ṣalaye fun ileẹjọ pe niṣe ni iyawo oun, Iyabo ma n digbaju ru oun nigba kugba toun ba ti ba awọn ọmọ mẹrin ti Eledua fi jinki awọn wi.
''Iyabo ti da igbeyawo ru pata pata, alaigbọran obinrin ni, bẹẹ ni ko si bọwọ fun mi rara,'' Oyedepo lo sọ bẹẹ.
- Sunday Igboho gbọdọ̀ gbàṣẹ ìdáàbòbò láti iléẹjọ́ tí kò ní jẹ́ kí ọlapáá mú un- amòfin Ozekhome
- Mo kọ̀ láti gbọ̀jẹ̀gẹ́ tàbí bẹ̀rù ẹnikẹ́ni nítorí ìjà òmìnira ìran Yorùbá- Igboho
- Àwọn jàndùkú ajínigbé fẹ́ẹ̀ lù wá pa nínú igbó, ọ̀rọ̀ rèé lẹ́nu àwọn àkẹ́kọ̀ọ́ ìlú Kagara
- Mo kọ̀ láti gbọ̀jẹ̀gẹ́ tàbí bẹ̀rù ẹnikẹ́ni nítorí ìjà òmìnira ìran Yorùbá- Igboho
- Bí èèrà lásán bá rin Sunday Igboho, ẹ rugi oyin - Oodua Youth Caolition
- Wo àwọn ìlú tó jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti èèwọ̀ ni kí ènìyàn kú níbẹ̀
- Wọ́n ní ọkọ̀ bàálù NAF tó mú ẹ̀mí ọmọ mi lọ l'Abuja ti lo ọdún 49 láyé - Bàbá Flight Sergent Olasunkanmi
Iyawo rẹ naa to jẹ oniṣowo ni faramọ wi pe ki ileẹjọ tu igbeyawo awọn ka.
Iyabo ni onidọti n ọkọ oun, kii tun ara ṣe lẹyin to ba tọju awọn ẹranko to n sin tan ninu ile.
''Otitọ ni mo gba eti ẹ ṣugbọn nitori o lu mi, o si ni ki n kuro nile oun ni mo fi ṣe bẹẹ,'' Iyabo ṣalaye.
Iyabo fikun ọrọ rẹ pe Oyedepo tun n ṣe ṣina, nitori naa oun ko ni ifẹ rẹ mọ.
Aarẹ ileẹjọ ọhun, Oloye Ademola Odunade woye pe igbeyawo naa si le duro tawọn mejeeji ba ni suuru.
Aarẹ Odunade ranṣẹ pe awọn ẹbi ọkọ ati iyawo lati da si ọrọ naa.
Ileẹjọ ti sun igbẹjọ naa siwaju di ọjọ kẹrindinlogun, oṣu kẹrin, ọdun 2021 yii.
- Àwọn Olùkọ́ Yorùbá ní ìlú Ondo fọkọyọ lórí ètò Akọ́mọlédè àti Àṣà lórí BBC Yorùbá
- Wọ ohun tí a mọ̀ nípa gbajúgbajù olórin ọmọ Naijiria, Dr Frabz tí wọ́n yìnbọn pa ?
- Ọjọ́ Ìṣẹ́gun ní abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19 tó tó 4 milionu yóò bàlẹ̀ sí Nàìjíríà
- Sunday Igboho gbọdọ̀ gbàṣẹ ìdáàbòbò láti iléẹjọ́ tí kò ní jẹ́ kí ọlọ́páá mú un- Amòfin Ozekhome
















