Akomolede Ondo: Àwọn Olùkọ́ Yorùbá ní ìlú Ondo fọkọyọ lórí ètò Akọ́mọlédè àti Àṣà lórí BBC Yorùbá

Awọn olukọ ede Yoruba ni ilu Ondo ni ipinlẹ Ondo ni guusu Naijiria ni wọn kọ awọn koko ti a n gbeyẹwo lasiko yii.
Awọn olukọ to dantọ yii kọ wa ni awọn ẹkọ kọọkan ni eyi ti o gbe aṣa, ede ati igabgbọ Yoruba sita sii.
Eto Akomolede ati Aṣa lori BBC Yoruba jẹ eto ti a ti n kọni lẹkọ nipa Yoruba eyi ti BBC n ṣe pẹlu apapọ ẹgbẹ Akọmọlede ati Aṣa
Iwi Egungun jẹ koko ti olukọ Olalekan Ojelade to wa lati ileẹkọ Orisunbare Number Community High School ni Bankẹmọ ni Ondo lo kọ ọ.
Asiko ati Iba Iṣẹlẹ ni koko ti Alagba Okunlọla J.A kọ wa.
Lati ileẹkọ Community High School ni Asewele-korede ni agbegbe Odigbo-Ọrẹ ni ẹkun Ondo ni olukọ to kọ koko yii.
Olukọ yii mẹnuba awọn ọrọ ti a n sọ nipa iṣẹlẹ ati asiko ti iṣẹlẹ n ṣẹlẹ nigba naa.
Iwe litireṣọ apilẹkọ Aja lo lẹru láti ọwọ ogbontarigi onkọwe ni, Oladejọ Okediji.
Arabinrin Kikelomo Ogunboye lo kọ wa nipa ẹda itan, ẹkọ inu iwe naa, awon ibudo itan ati itan inu iwe naa ni ṣoki.

Ileẹkọ St Monica Girl's Grammar School, ni ipinlẹ Ondo.
Olukọ wa fi ara balẹ yannana ohun gbogbo to ṣẹlẹ nibẹ ati ipa ti Tafa, Lapade, ati awọn ẹda itan miran ko ninu ifọrọyaworan to nii ṣe pẹlu ohun to n ṣẹlẹ ni Naijiria.
Aranmọ Fawẹẹli ni koko girama ti a gbe yẹwo.
Alagba Oyewọle Isaac, lati ileẹkọ Awaye Comprehensive Grammar School, Ilẹ̀ Oluji ni ipinlẹ Ondo.
- Kí ló mú kí géńdé Olorun fi àfọ́kù ìgò gé ǹkan ọmọkùnrin rẹ̀ ní Kano?
- Akẹ́kọ̀ọ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlá mú ìbọn ìléwọ́ lọ ilé ìwé láti yìín lu olùkọ́ tó ní kó gé irun orí rẹ̀
- Ọwọ́ pálábá Abubakar, mọ́káliíkì ségi níbi tó ti fẹ́ jí ọkọ̀ gbé l'Abuja
- "Èèyàn mọ́kànlá ni a yìnbọn pa níbi ìdigunjalè Offa"
- Ṣé lóòtó ni ilé-iṣẹ́ ológun gbé hẹlikópítà ìjagun lọ si Orlu ní ìpínlẹ̀ Imo?
Olukọ wa mẹnuba awọn iro agbaranmọ ati iro afaranmọ,.
Bakan naa lo sọ nipa awọn ọna ijẹyọpọ fawẹẹli ati bi aranmọ ṣe n waye ninu gbolohun ede Yoruba.
Iwa Omoluwabi ni a gbe yẹwo ni kilaasi yii.
Arabinrin Adenikẹ Okun lo kọ wa ni koko naa lati ileẹkọ St Andrews Anglican Grammar School ni ipinlẹ Ondo.
- Àwọn obìnrin mánigbàgbé tó ti kópa nínú sáà ìjọba tiwantiwa láti ọdún 1999
- Ẹ̀yin ọmọ Yoruba, ẹ dáàbò bo ara yín lọ́wọ́ àwọn jàǹdùkú tó ń kọlù yín - Sunday Igboho
- Ìjọba ti ileẹ̀kọ́ pà lẹ́yìn tí àwọn jàndùkú ṣèkọlù sí Osogbo, ìpínlẹ̀ Osun
- Ọ̀gá àgbà ilé-iṣẹ́ aṣọ́bodè (Customs) tẹ́lẹ̀ tó kú tí wọ́n fẹ̀sùn kíkó ẹgbẹ̀lẹ́gbẹ̀ bílíọ̀nù jẹ kan
Olukọ to yaranti yii sọrọ nipa awọn iwa ọmọluabi bii otitọ inu, ifẹ, ibọwọfagba, itẹriba, ifọwọsopọ ati bẹẹ bẹẹ lọ.
O mẹnuba awọn iwa ti kii ṣe ti ọmọluwabi bii irọ pipa, ole jija, rikiṣi ṣiṣe, imọtara ẹni nikan, ọtẹ ṣiṣẹ atawọn nkan imii.
Olukọ wa sọ awọn anfani nini iwa ọmọluwabi pelu iṣẹ aṣetilewa fun awa akẹkọọ.
Arabinrin Adeyemi Taiwo lati ileẹkọ C.A.C. Grammar school Ọ̀kà, Ondo West.
Gbolohun ede Yoruba ni koko ti olukọ wa gbe yẹwo
Awọn isọri ọrọ to n wa ninu gbolohun ede yoruba ni a gbe yẹwo ati ọna ti wọn fi n jẹyọ.
Awọn ounjẹ ilẹ̀ Yoruba ni a gbe yẹwo lonii lori eto Akọmọlede ati Aṣa lori BBC Yoruba.
Arabinrin Stella Adedeji ni olukọ wa lati ileẹkọ C. A. C. High School ni ilẹ Oluji ni ipinlẹ Ondo ni guusu Naijiria.
Olukọ wa mẹnuba awọn oriṣii ounjẹ to wọpọ ni awọn agbegbe kọọkan ati bi wọn ṣe n se wọn.
Iwe itan Akojọpọ Alọ Ijapa lati ọwọ Ọjọgbọn Adeboye Babalola.
Alagba Oyelọwọ Lawrence Olufemi lati ile ékọ C.A.C. grammar school, Ọ̀kà ni ipinlẹ Ondo ni olukọ wa lori eto Akomolede ati Aṣa lori BBC Yoruba toni.
Olukọ wa yanana idi ti Yoruba se n lo ijapa gẹgẹ bii olu ẹda itan alọ apagbe wọn.
O mẹnuba awọn ọgbọn ẹwẹ ti ijapa ni, awọn iwa to n hu lati fi kọ ọmọ araye lọgbọn.
E to yii n waye pẹlu ajọṣepọ BBC Yoruba, ẹgbẹ Onimọ Yoruba YSAN ati apapọ ẹgbẹ Akomolede ni Naijiria





























