Aláàfin of Oyo's Palace Administration: Àwọn nǹkan tí o kò mọ̀ nípa ààfin ìlú Oyo nìyí

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Báyìí ni à ń ṣe ní ilé wa èèwọ̀ ibòmíràn.
Ní ilẹ̀ Yorùbá, ohun gbogbo ló ní ètò àti ọ̀nà tí wọ́n ń gbà ṣe ètò inú ilé àti ọ̀dẹ̀dẹ̀ tí èyí kò sì yọ ààfin ìlú Oyo sílẹ̀.
Ní Ààfin ìlú Oyo, òjò tàbí oòrùn kìí pa Aláàfin nítorí wọ́n ti ṣètò ibi tí Ọba Aláàfin yóò máa gbà tí oòrùn tàbí òjò kò fi ní kàn án lára.
- Ó pé ọdún 35 tí Obafemi Awolowo kú, wo àwọn nkan mánigbàgbé tí o kò gbọ́ rí nípa rẹ̀
- Adelabu kéde èròńgbà rẹ̀ láti jẹ gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo
- Mọ̀lẹ́bí ṣàlàyé kíkún nípa bí agbébọn ṣe ṣekúpa Gloria Mathew àti àfẹ́sọ́nà rẹ̀ nínú igbó ní ìpínlẹ̀ Imo
- Ọwọ́ pálábá NDLEA tẹ aláboyún méjì, 'barber' kan àti àwọn afurasí mí tó gbé egbòogi
- Ẹ kò gbọdò lo 'Make Up'; ya 'tatoo'; fi kún èékánná tàbí kun àtíkè níta mọ́ lábẹ́ òfin wa- Iran
- Irọ́ ni, irọ́ kọ́ Toyin Adegbola àti àwọn míì sọ̀rọ̀ nípa fídíò Biola àti Olùdarí ere tí wọ́n jọ ní gbólóhùn asọ̀
Aláàfin nìkan ló ní àǹfàní láti gba ọ̀nà yìí gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Ọba Adeyemi kẹta nígbà tí Baba ń bẹ lókè eèpẹ̀.
Ní Ààfin, Aláàfin nìkan ni àǹfàní wà fún láti wọ bàtà tí ẹnikẹ́ni kò sì gbọdọ̀ gbìyànjú láti tàpá sí òfin yìí.
Bí àjòjì tàbí ẹnikẹ́ni bá gbìyànjú láti ṣe bí Aláàfin, tó fẹ́ yọ bàtà wọ̀, àwọn ẹ̀ṣọ́ ti wà ní sẹpẹ́ láti fi póró òfin gbé ẹni náà nítorí kò sí bí ènìyàn ṣe fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹ̀ṣọ́ náà kò ní mọ̀.
Bákan náà ní àwọn ènìyàn tó máa ń wà ní Ààfin ní ìgbà kan kìí dín ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (500) tí gbogbo wọn sì ní ojúṣe kan tàbí òmíràn tí wọ́n ń ṣe nínú ààfin.
Ọba Adeyemi ní gbogbo àwọn olorì tó wà ní Ààfin kọ́ ni ó jẹ́ aya tí ọba fẹ́ fúnra rẹ̀ nítorí àwọn tí Ọba jogún nígbà tí ọba kan bá gbésẹ̀ wà nínú ààfin.
Àwọn ìyàwó tí Aláàfin bá mú wá, nǹkan tí wọ́n ń ṣe ní ààfin, wọn kò ní mọ̀, àwọn ni wọn yóò máa kọ́ àwọn ìyàwó wọ̀nyẹn ní ẹ̀kọ́; báwo ni a ṣe ń tọ́jú Aláàfin àti oúnjẹ rẹ̀?
Ìyá Ilé Orí ní láti wà, Ìyá Káà Ọba, Ìyá Ayé Kalẹ̀, Ìyá Kòlárá, Ìyá Kòlárá Kékeré, Káà ọ̀dẹ̀.
Kòlárá Kékeré ni wọ́n ti ń gún iyán, gbogbo ẹni tó bá wà ní ààfin kò gbọ́dọ̀ lọ sí ìta ra nǹkan.
Ẹni tí ó máa gùn iyán ọ̀sán tí wà ní ààfin.
Káà Ilé Ẹyẹ wà, ibi tí wọ́n tí ń bọ̀ orí Aláàfin wà, ilé Ṣàngó wà.
Ìyàrá kan wà, ibẹ̀ ni wọ́n máa ń kó gbogbo adé sí, iná gbọ́dọ̀ wá níbẹ̀ ni gbogbo ìgbà.
- INEC lẹ́tọ̀ọ́ láti bẹ́gi dínà èróngbà Emefiele láti díje du ipò Ààrẹ- Ilé ẹjọ́
- Àwọn iléeṣẹ́ bàlúù ní Nàìjíríà ronúpìwàdà lórí wíwọ́gilé ìrìnnà òfúrufú ní Nàìjíríà lọ́jọ́ Ajé, ohun tó fàá nìyí
- ASUU fi oṣù mẹ́ta kún ìyanṣẹ́lódì wọn nítorí pé.......
- Ẹgbẹ́ CAN foríjin ilé ìfowópamọ́ Sterling, ìdí rèé
- Ẹbí kan pàdánù ọmọ mẹsan-án nínú èèyàn 435 tí omiyalé pa
- Iṣẹ́ Ọlọ́run tí mo gbé dáni kọjá ipò Ààrẹ Nàìjíríà – Bíṣọ̀ọ̀bù David Oyedepo
- Irọ́ ni pé Bola Tinubu fẹ́ kúrò ní ẹgbẹ́ òṣèlú APC- Agbẹnusọ Aṣíwájú
Moyọ̀ àti Àlàbá ni máa ń tọ́jú adé, ìlẹ̀kẹ̀ tí Aláàfin máa fi sì ọwọ́, lọ́dọ̀ wọn ló wà, wọ́n níláti ṣe nńkan sí i.
"Ìlẹ̀kẹ̀ ti ọrùn náà kò gbọ́dọ̀ wà lọ́dọ̀ Aláàfin, Kò sí adé lọ́dọ̀ mi, kò sí ìlẹ̀kẹ̀ lọ́dọ̀ mi."
Àwọn ìyá méjì ló máa ń pín iṣẹ́ àti ètò ṣe ní ààfin, olorì àgbà tó wà ní ìkápá gbogbo àwọn ọmọ àti àwọn olorì yòókù.
Ẹnìkejì ni Iya Naso tó wà ní ìkápá ètò tó ní ṣe pẹ̀lú Sango àti gbogbo àwọn òṣìṣẹ́ àwọn ààfin yòókù.























