Àwọn iléeṣẹ́ bàlúù ní Nàìjíríà yí ohùn padà lórí wíwọ́gié ìrìnnà òfúrufú nítórí owó epo bàlúù, wọ́n ní àwọn ti da ọ̀rọ̀ náà rò

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ẹgbẹ awọn onileeṣẹ baluu lorilẹede Naijiria, "Airline Operators of Nigeria, AON, ti so ipinnu rẹ lati woṣẹniran kaakiri gbogbo papakọ ofurufu to wa lorilẹede naa lọjọ Aje rọ na.
Igbesẹ ati maṣe tẹsiwaju pẹlu iyanṣẹlodi naa n waye lẹyin nnkan bii wakati mẹrinlelogun ti wọn kede pe awọn fẹ so gbogbo iṣẹ to nii ṣe pẹlu igbokegbodo kọ baluu awọn rọ nitori owo gegele to gun ori epo baluu.
Gẹgẹ bi ohun ti wọn ṣe lalaye, Naira aadọwaa ni wọn n ra jala epo baluu tẹlẹ, ṣugbọn bayii o ti gbẹnusoke di ẹẹdẹgbẹrin Naira, eleyi ti wọn ni o n mu inira ba owo wọn.
- Àwọn akẹ́kọ̀ọ́ bẹ̀rẹ̀ ìwọ́de ìfẹ̀hónú hàn nítorí ìyansẹ́lódí ASUU
- Ẹbí kan pàdánù ọmọ mẹsan-án nínú èèyàn 435 tí omiyalé pa
- Iṣẹ́ Ọlọ́run tí mo gbé dáni kọjá ipò Ààrẹ Nàìjíríà – Bíṣọ̀ọ̀bù David Oyedepo
- Irọ́ ni pé Bola Tinubu fẹ́ kúrò ní ẹgbẹ́ òṣèlú APC- Agbẹnusọ Aṣíwájú
- Ẹgbẹ́ CAN foríji ilé ìfowópamọ́ Sterling, ìdí rèé
- Wo ọ̀nà tí wọ́n ń pè ní "ọ̀nà ikú" tí àwọn ènìyàn ṣì ń ṣe ìrìnàjò lórí rẹ̀ síbẹ̀
- Kí nìdí táwọn iléeṣẹ́ bàlúù ní Nàìjíríà ṣe fẹ́ wọ́gilé ìrìnnà òfúrufú ní Nàìjíríà lọ́jọ́ Ajé?
Ẹgbẹ awọn onileeṣẹ baluu lorilẹede Naijiria, "Airline Operators of Nigeria, AON, wa ṣalaye ninu atẹjade kan ti wọn fi sita lalẹ ọjọ Aiku pe fun anfani ọrọ Aje orilẹede Naijiria ati ọrọ abo ni awọn fi tun ero awọn pa lori rẹ.
Lara awọn lọgalọga ileeṣẹ baluu ni Naijiria to buwọlu atẹjade naa ni Abdulmunaf Sarina, oludari agba ileeṣẹ baluu Azman Air; Shehu Wada, oludari agba ileeṣẹ baluu Max Air; oludari agba ileeṣẹ baluu, Obiora Okonkwo, oludari agba ileeṣẹ baluu, United Nigeria Airlines.
Awọn miran to tun buwọlu atẹjade naa ni, Roy Ilegbodu oludari agba ileeṣẹ baluu, Arik Air; Abdullahi Mahmood, oludari agba ileeṣẹ baluu Aero Contractors; pẹluu Allen Onyema to jẹ oludari agba ileeṣẹ baluu Air Peace.
Ṣaaju ni ileeṣẹ ijọba apapọ Naijiria to n ṣe kokaari ọrọ irinna ofurufu ti kọkọ fi ọkan awọn ọmọ Naijiria balẹ pe awọn n jiroro lori ọrọ naa ki irinna ofurufu ma baa dagun lọjọ Aje ọjọ kẹsan an oṣu karun un ọdun 2022.
O fi kun un pe ileeṣẹ baluu Ibom Air, Green Africa Airlines, Arik air, Dana Air, atawọn miran bẹẹ yoo ṣi maa ba iṣẹ wọn lọ.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Kí nìdí táwọn iléeṣẹ́ bàlúù ní Nàìjíríà ṣe fẹ́ wọ́gilé ìrìnnà òfúrufú ní Nàìjíríà lọ́jọ́ Ajé?
Ẹgbẹ awọn ileeṣẹ to n ṣe owo irinna ofurufu lorilẹede Naijiria, Airline operators of Naijiria ti faake kọri pe gbogbo igbokegbodo ọkọ ofurufu lawọn yoo bẹgi le lọjọ Aje ti ko si ni si baluu kankan ti yoo lanfani ati ṣiṣẹ jakejado orilẹede Naijiria.
Ẹgbẹ naa ni gbogbo ẹbẹ ti ijọba apapọ n bẹ lori ọrọ naa ko lee wọle bẹẹ ni igbesẹ igbẹyinbẹbọ jẹ ti ileeṣẹ ọkọ baluu Ibomair.
- Wo ọ̀nà tí wọ́n ń pè ní "ọ̀nà ikú" tí àwọn ènìyàn ṣì ń ṣe ìrìnàjò lórí rẹ̀ síbẹ̀
- Gọngọ sọ! Adarí ìpolongo ètò ìdìbò Tinubu fi ẹgbẹ́ òṣèlú APC sílẹ̀
- Mo dúpẹ́ ó! Mo bẹ́ orí fún gbogbo àgbẹ̀ àti olùfọkànsìn tó ń dáwó fọ́ọ̀mù Ààrẹ fún mi àmọ́ ẹ jẹ́ n lo óògùn ara mi - Emefiele
- Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Ẹ̀sìn tó gbalẹ̀ kan l'Ekiti, a ti f'òfin bọ ọ̀rọ̀ Pasito Ade Abraham - Iléeṣẹ́ Ọlọ́pàá Ekiti
- Bíbéli mi ló sọ pé kí n fẹ́ ìyàwó omidan mẹ́rin, kìí ṣe ẹ̀ṣẹ̀- Pásítọ̀
- A kọ̀ láti yí ọkàn wà padà lórí ìpinnu Yorùbá Nation- Ilana Omo Oodua
Ẹgbẹ awọn ileeṣẹ to n ṣe owo irinna ofurufu lorilẹede Naijiria naa ni bi owo epo baluu ti wọn mọ si JetA1 ṣe gbowolori lati naira aadọwa , (N190) ti wọn n ra a tẹlẹ si ẹẹdẹgbẹrin naira, (N700) bayii lo wa igbesẹ ẹhonu wọn naa.
Lati ọjọ Ẹti ni ẹgbẹ ọhun ti fi ọrọ ẹdun ọkan wọn ranṣẹ si ijọba lorilẹede Naijiria ati gbogbo awọn alẹnulọrọ lori rẹ pe ki wọn wọn tete wa nnkan ṣe si nitori owo epo naa to n fojojumọ gọbọi sii ti fẹ gbẹmi ileeṣẹ awọn.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ileeṣẹ Ibom Air ni awọn ko lee kọ ẹyin si awọn onibara to ti sanwo iṣẹ fun awọn
Ileeṣẹ baluu Ibom Air ni tirẹ ti sọ pe awọn ko ni lee kopa ninu iyanṣẹlodi naa nitori pe awọn ko lee kọ̀ ẹyin si awọn onibara to ti sanwo iṣẹ fun awọn.
Ninu atẹjade kan ti ileeṣẹ baluu IbomAir fi sita lọjọ Satide, o niawọn onibara awọn kan ti san asansilẹ owo fun irinna wọn lọjọ ti iyanṣẹlodi naa fẹ waye ti awọn ko si lee ja wọn ni tanmọn-ọn ki awọn ma baa lugbadi ẹipẹjọ wọn.
Ileeṣẹ baluu naa ni eyi ko sọ pe awọn naa ko mọ bi epo irnna baluu ṣe wọn gogo yii lara o tabi wa ni iṣọkan pẹlawọn akẹgbẹ wọn lori ohun ti wọn n ja a fun.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Arowa ti ijọba apapọ pa sawọn ileeṣẹ baluu ni Naijiria.
Ijọba apapọ pẹlu ti kọ si awọn onileeṣẹ baluu ni Naijiria naa lati bu omi suuru mu ki wọn si dakundabọ fi iye denu lori iyanṣẹlodi wọn naa.
Ijọba apapọ ni igbesẹ ti n lọ labẹnu lati yanji ẹhonu wọn.
Minisita feto irinna ofurufu ni nIajiria, Hadi Sirika ninu atẹjade kan ti amugbalẹgbẹ fun un lori ọrọ ibaṣepọ pẹlu araalu, James Odaudu fi sita ṣọ pe, "Nigba ti igbesẹ lati yanju ẹdun wọn n lọ lọwọ, a n rawọ ẹbẹ sawọn ileeṣẹ baluu naa lati ro ti ọpọlọpọ wahala ati inira ti igbesẹ wọn naa le e mu ba awọn arinrinajo lati Naijiria ati oke okun."


















