World Most Dangerous Road: Kí ló le ṣe okùnfà kí ènìyàn ṣe ìrìnàjò lórí ọ̀nà ikú?

Àìrìn jìnà ni a ò rí abuké ọ̀kẹ́rẹ́, onírúurú àrà ń bẹ lókè eèpẹ̀.
Ní orílẹ̀ èdè Bolivia, tó wà ní ẹkùn gúúsù Amẹ́ríkà, ọ̀nà kan wà tí wọ́n ń pè ní ọ̀nà ikú nítorí bí ó ṣe tóóró tó àti wí pé kò gba ọkọ̀ méjì papọ̀ lẹ́yìn ọkọ̀ kan tó bá ń rìn lórí rẹ̀.
Ọ̀nà márosẹ̀ náà tó jẹ́ kílómítà mẹ́rìnlélọ́gọ́ta ni fífẹ̀ rẹ̀ kò ju mítà mẹ́ta lọ pẹ̀lú àwọn kọ̀rọ̀ àti ìyànà lóríṣiríṣi.
- Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Ẹ̀sìn tó gbalẹ̀ kan l'Ekiti, a ti f'òfin bọ ọ̀rọ̀ Pasito Ade Abraham - Iléeṣẹ́ Ọlọ́pàá Ekiti
- Ẹ gba ìpínlẹ̀ Eko kúrò lọ́wọ́ àwọn àjòjì - Atiku sí Bode George
- Ṣé ó ṣeéṣe kí ẹgbẹ́ ASUU fi òpín sí ìyànṣẹ́lódì rẹ̀ lọ́jọ́ Aje?
- Mo dúpẹ́ ó! Mo bẹ́ orí fún gbogbo àgbẹ̀ àti olùfọkànsìn tó ń dáwó fọ́ọ̀mù Ààrẹ fún mi àmọ́ ẹ jẹ́ n lo óògùn ara mi - Emefiele
- Torí oge ṣíṣe, wo obìnrin tó ṣe ìrìbọmi omi tútù àmọ́ tó já sí ikú fún u
Àwọn ẹlẹ́wọ̀n Paraguay, lẹ́yìn ogun Chaco tó wáyé láàárín ọdún 1932 sí 1935, ló la ọ̀nà náà.
Ọ̀nà ọ̀hún tí ilé ìfowópamọ́ ìdàgbàsókè ilẹ̀ Amẹ́ríkà pè ní ọ̀nà tó léwu jùlọ ní àgbáyé ló gbẹ̀mí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ní ìbẹ̀rẹ̀ ọdún 1990.
Kò dín ní ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún kan mítà tí ọ̀nà náà fi ga sí ilẹ̀ tó sì ṣe tóóró tó jẹ́ wí pé agbára káká ni ọ̀kadà tàbí kẹ̀kẹ́ yóò fi kọjá lára ọkọ̀ lójú ọ̀nà náà láì kọlu ọkọ̀ ọ̀hún.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀nà yìí léwu púpọ̀, ó jẹ́ ọ̀nà tó máa ń wu àwọn ènìyàn tó bá fẹ́ràn ìnàjú láti lọ nítorí àwọn ohun mèremère tó kún ojú ọ̀nà náà.

Kí ló le mú ènìyàn láti gbé ọkọ̀ sórí ọ̀nà ikú?
Ọ̀nà yìí ló já sí ẹkùn Yunga níbi tí wúrà àti coca sodo sí.
Tí ènìyàn bá ti rin ìrìn wákàtí méjì gbáko pẹ̀lú ọkọ̀ lórí ọ̀nà ikú yìí, Coroico ni ènìyàn yóò já sí tó jẹ́ ibi tí wọ́n ti ń wà wúrà (góòlù) ní ìgbà kan rí.

Coroico jẹ́ ibìkan tí kò ní wu ènìyàn láti kúrò níbẹ̀ nítorí gbogbo àwọn ohun ìgbafẹ́ tó wà níbẹ̀.
Àyè wà ní ojú ọ̀nà náà láti jẹ, mu àti láti sùn, tí ó sì ti ko ipa nínú ìdàgbàsókè tó ti bá orílẹ̀ èdè Bolivia báyìí.
Coca jẹ́ ohun tó pàtàkì sí àṣà ẹkùn gúúsù Amẹ́ríkà
Nítorí ilẹ̀ ọlọ́ràá tí Yunga àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò tó máa ń rọ̀ níbẹ̀ ti sọ́ di agbègbè tó jẹ́ mímọ̀ fún ètò ọ̀gbìn.
Ó jẹ́ ibi tí àawọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀yà bíi Tiwanaku àti Inca tí máa ń gbin oúnjẹ bíi kọfí, ọ̀gẹ̀dẹ̀, ọsàn, ẹ̀gẹ́, coca àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.
- Àjọ̀ JAMB kéde àwọn nkan tí akẹ́kọ̀ọ́ kò gbọdọ̀ mú wọ yààrá ìdánwò fún UTME 2022
- Ikú d'óró! Wole Adetiran tó kọ orin àdákọ àgùnbánirọ̀ Naijiria 'NYSC Anthem' ti jáde láyé
- Wọ́n tún ṣàwárí ọ̀pọ̀lọpọ̀ owó tí Abacha jí kó ní UK
- 'Ẹ yẹgi fún un'! Ọkùnrin ẹni ọdún 42 gba ìdájọ́ ikú lẹ́yìn tó pa Ọba aládé l'Ekiti
- Aláàrun ọpọlọ kọlu Ààfin Soun Ogbomoso, ó fi ẹ̀ṣẹ́ yọ eyín Olóyè
Láti ọjọ́ pípẹ́ ni coca ti jẹ́ ohun èlò pàtàkì fún àṣà gúúsù Amẹ́ríkà, tí Bolivia sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn orílẹ̀ èdè tó ń pèsè rẹ̀ lọ́pọ̀ yanturu.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilẹ̀ ni Bolivia fi jin gbígbin coca, tí ìdá méjì nínú mẹ́ta rẹ̀ sì wà ní Yunga.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ àwọn ẹ̀yà Spain dẹ́yẹ sí lílo coca, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n ti mọ ìwúlò rẹ̀ fún ìwòsàn, oúnjẹ àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí ní lò ó.
Láti bí ọdún ẹgbẹ̀rún ọdún mẹ́jọ báyìí ni wọ́n ti ń lò ó níbi ayẹyẹ ètò ẹ̀sìn, gẹ́gẹ́ bí owó, òògùn àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.





















