2023 General Elections: Ẹ gba ìpínlẹ̀ Eko kúrò lọ́wọ́ àwọn àjòjì - Atiku sí Bode George

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Igbákejì Ààrẹ tẹ́lẹ̀ rí ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tó tún jẹ́ olùdíje sípò Ààrẹ Nàìjíríà, Alahji Atiku Abubakar ti pàrọwà sí àwọn àgbààgbà àti ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party (PDP) ní ìpínlẹ̀ Eko láti gba àkóso ìpínlẹ̀ Eko níbi ètò ìdìbò gbogbogboò tó ń bọ̀.
Atiku pàrọwà yìí nígbà tó ṣe àbẹ̀wò sí àgbà olóṣèlú ẹgbẹ́ PDP, olóyè Olabode George ní ilé ìgbé rẹ̀ tó wà ní Ikoyi, ìpínlẹ̀ Eko.
Atiku ní ó pọn dandan fún ẹgbẹ́ òṣèlú PDP ní ìpínlẹ̀ Eko láti fìmọ̀ ṣọ̀kan tí wọ́n bá fẹ́ ní àṣeyọrí níbi ètò ìdìbò tó ń bọ̀ lọ́nà.
- Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Ẹ̀sìn tó gbalẹ̀ kan l'Ekiti, a ti f'òfin bọ ọ̀rọ̀ Pasito Ade Abraham - Iléeṣẹ́ Ọlọ́pàá Ekiti
- Torí oge ṣíṣe, wo obìnrin tó ṣe ìrìbọmi omi tútù àmọ́ tó já sí ikú fún u
- Ṣé ó ṣeéṣe kí ẹgbẹ́ ASUU fi òpín sí ìyànṣẹ́lódì rẹ̀ lọ́jọ́ Aje?
- Ṣe gómìnà báńkì àpapọ̀ Nàìjíríà lè díje dupò Ààrẹ? Àlàyé rèé
- Àjọ̀ JAMB kéde àwọn nkan tí akẹ́kọ̀ọ́ kò gbọdọ̀ mú wọ yààrá ìdánwò fún UTME 2022
- Ikú d'óró! Wole Adetiran tó kọ orin àdákọ àgùnbánirọ̀ Naijiria 'NYSC Anthem' ti jáde láyé
- Wọ́n tún ṣàwárí ọ̀pọ̀lọpọ̀ owó tí Abacha jí kó ní UK
- Òkú obìnrin yìí kan ìlẹ̀kùn pósí gbà-gbà-gbà pé òun ò kú lọ́jọ́ ìsìnkú rẹ̀! Kàyéfì tuntun
- Aláàrun ọpọlọ kọlu Ààfin Soun Ogbomoso, ó fi ẹ̀ṣẹ́ yọ eyín Olóyè
- Ìwé mo yọ ọwọ́ mí o ṣe mọ́ tí APC ní k'áwọn olùdíje fọwọ́ sí kí làwọn ọmọ ẹgbẹ́ ń sọ?
- 'Ẹ yẹgi fún un'! Ọkùnrin ẹni ọdún 42 gba ìdájọ́ ikú lẹ́yìn tó pa Ọba aládé l'Ekiti
- Wo ǹkan 21 tó yẹ kí obìnrin mọ̀ nípa ojú abẹ́ rẹ̀, Vagina
- Kí ló fa gbas-gbos láàrín àwọn òṣèrébìnrin méjì, Laide Bakare àti Eniola Badmus?
Ó ní gbogbo àwọn ọmọ ẹgbẹ́ PDP lápapọ̀ mọ̀ wí pé orin ìṣọ̀kan ni òun máa ń kọ fún nítorí àti lè ṣe àṣeyè tí alákàn ń ṣepo.
Ó fi kun wí pé tí ẹgbẹ́ òṣèlú PDP yóò bá kẹ́sẹ járí ní ìpínlẹ̀ Eko, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìfarajìn ni àwọn ọmọ ẹgbẹ́ yóò ṣe.
Bákan náà ló pàrọwà sí àwọn ọmọ ẹgbẹ́ láti fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú àwọn adarí wọn kí ẹgbẹ́ náà le wà ní ìṣọ̀kan.
Nígbà tó ń fèsì sí ọ̀rọ̀ Atiku, Bode George ní kò sí àní àní wí pé Atiku mọ tinútẹ̀yìn Nàìjíríà nítorí ìrírí tó ti ní nígbà tó jẹ́ igbákejì Ààrẹ Nàìjíríà.
Bode George ní ètò ìdìbò gbogbogboò ọdún 2023 ní ẹgbẹ́ òṣèlú PDP ní láti gba àkóso orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, tí àwọn sì gbọdọ̀ rún tapá titan àwọn si.
Ó fi kun pé orílẹ̀ èdè Nàìjíríà nílò ẹni tó ní ìrírí àti ìmọ̀ kíkún nípà Nàìjíríà láti darí rẹ̀ tó sì jẹ́ pé Atiku ni fìlà náà yẹ.
Bákan náà ló ní àwọn gbọdọ̀ fìmọ̀ ṣọ̀kan ní ìpínlẹ̀ Eko nítorí ó pọn dandan fún àwọn láti gba ìpínlẹ̀ Eko lọ́wọ́ àwọn àjòjì.


















