Ogun Cultist: Ọwọ́ tẹ afurasí ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn ní ilé ìtura, wo nǹkan tí ọlọ́pàá ká mọ lọ́wọ́

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Ọwọ palaba ogbologbo ọmọ ẹgbẹ okunkun kan ti segi ni Ogun nibi lẹyin ti ọwọ awọn agbofinro tẹ.
Afurasi naa Christian Peter la gbọ pe ọwọ tẹ ni ọjọ Isegun tii se ọjọ Kẹwaa, osu Karun un, ọdun yi.
Ninu atẹjade ti alukoro ọlọpaa ipinlẹ Ogun, Abimbola Oyeyemi, fi sita,o ni o ti to ọjọ mẹtaa kan ti wọn ti n wa afurasi yi ki awọn ọlọpaa agọ to wa ni Mowe to wa pada ri mu.
- Ṣé lóòtọ́ ní Makinde gbà tíkẹ̀ẹ̀tì Sẹ́nétọ̀ lọ́wọ́ Kola Balogun fún Joseph Tegbe?
- Àwọn olùkọ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga gbogbonìṣe Poly ní Nàìjíríà , ASUP bẹ́rẹ́ ìyanṣẹ́lódì, wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀
- Buhari pàṣẹ fún àwọn mínísítà tó bá fẹ́ dupò òṣèlú láti kọ̀wé fi iṣẹ́ sílẹ̀ ní kíá
- Genevieve Nnaji fi fídíò sí Instagram, lẹ́yìn wákàtí díẹ̀ tí ìròyìn sọ pé ó ní àrùn ọpọlọ
- Johnson Sulemann sọ̀rọ̀ sókè lórí ẹ̀sùn tí Stephanie Otobo fi kàn án
- Buhari kò ní fi oṣù mẹ́fà kún ìjọba rẹ̀ bí àwọn kan ṣe ń bèrè - Ìjọba àpapọ̀̀̀
- Wo àwọn tó ra fọ́ọ̀mù ipò Ààrẹ ẹgbẹ́ òṣèlú APC
- Ṣé lóòtọ́ ni Jonathan ti gbẹ̀yìn darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ APC? Nkan tí PDP àti APC sọ rèé
- Wo ìdí tí Ilé aṣòfin àpàpọ̀ Nàìjíríà ṣe yí òfin ìdìbò padà fún ààrẹ, gómìnà, àwọn aṣòfin àtàwọn míràn
A gbọ pe ni ile itura kan to wa ni adugbo Olororo, Mowe ni o ti ko si awọn ọlọpaa lọwọ.
Gẹgẹ bi wọn se wi, kete to ri awọn ọlọpaa lo gbiyanju lati fẹsẹ fẹ sugbọn awọn agbofinro ri mu ko to ribi sa lọ.
Wọn ba igbanu kan lọwọ rẹ.
Nigba ti wọn yẹ inu rẹ wo, wọn ri pe ibọn agbelẹrọ kan pẹlu ọta mẹrin lo wa ninu rẹ.
Awọn ọlọpaa fidi rẹ mulẹ pe o wa lara awọn ọdaran to n ka awọn ara adugbo laya soke ni agbegbe Mowe/Ofada lẹnu ọjọ mẹta yi..

Oríṣun àwòrán, Ogun Police Command
Ẹwẹ, ọga ọlọpaa ni ipinlẹ Ogun, Kọmisana Lanre Bankole ti pasẹ ki wọn gbe afurasi yi lọ si ẹka ọtẹlẹmuyẹ to n se iwadii iwa ọdaran fun ẹkunrẹrẹ iwadii.

Oríṣun àwòrán, @NDLEA
Kini o tun ti ṣẹlẹ sẹyin?
Ọwọ́ pálábá NDLEA tẹ aláboyún méjì, 'barber' kan àti àwọn afurasí mí tó gbé egbòogi
Aláboyún méjì afurasí mìíràn rèé tí NDLEA mú láàrin ọsẹ tó kọjá ní Nàìjíríà
Igbiyanju ajọ to n gbe ogun ti lilo egboogi oloro tun ti ja si rere nipa bi ọwọ wọn se tẹ awọn aboyun meji kan ati awọn afurasi meji mii to fẹ gbe oogun oloro gba papakọ ofurufu ipinlẹ Eko lọ si oke okun.
Ni ọsẹ to kọja yi ni ọwọ palaba awọn taa n wi yi segi.
Alukoro ajọ naa Femi Babafemi lo fidi ọrọ yi mulẹ ninu atẹjade kan to fi sita.
- ASUU fi oṣù mẹ́ta kún ìyanṣẹ́lódì wọn nítorí pé.......
- Ẹgbẹ́ CAN foríjin ilé ìfowópamọ́ Sterling, ìdí rèé
- Ẹbí kan pàdánù ọmọ mẹsan-án nínú èèyàn 435 tí omiyalé pa
- Àwọn iléeṣẹ́ bàlúù ní Nàìjíríà ronúpìwàdà lórí wíwọ́gilé ìrìnnà òfúrufú ní Nàìjíríà lọ́jọ́ Ajé, ohun tó fàá nìyí
- INEC lẹ́tọ̀ọ́ láti bẹ́gi dínà èróngbà Emefiele láti díje du ipò Ààrẹ- Ilé ẹjọ́
- Iṣẹ́ Ọlọ́run tí mo gbé dáni kọjá ipò Ààrẹ Nàìjíríà – Bíṣọ̀ọ̀bù David Oyedepo
- Irọ́ ni, irọ́ kọ́ Toyin Adegbola àti àwọn míì sọ̀rọ̀ nípa fídíò Biola àti Olùdarí ere tí wọ́n jọ ní gbólóhùnasọ̀
- Mọ̀lẹ́bí ṣàlàyé kíkún nípa bí agbébọn ṣe ṣekúpa Gloria Mathew àti àfẹ́sọ́nà rẹ̀ nínú igbó ní ìpínlẹ̀ Imo
- Ṣé Christiano Ronaldo yóò dúró tàbí kò ní dúró n'Manchester United fún sáà líìgì tó ń bọ̀?
Kini ajọ NDLEA sọ?
Babafemi ni ọkan ninu awọn afurasi to dari lati orileede Brazil,Nworie Philip Chikwendu,ni ọwọ awọn kọkọ tẹ lọjọ Kẹta, osu Karun.
O ni awọn ri i mu nigba to n gbiyanju lati gbe egboogi oloro wọ Naijiria lati Brazil.
Asiri tu nigba ti wọn tu ẹru rẹ ti wọn si ba egboogi oloro cocaine to ko pamọ sinu bata to ko pamọ sinu baagi agbepọnyin rẹ.
Wọn tẹsiwaju lati tu bata to wọ sẹsẹ ti wọn si tun ri pe o gbe cocaine meji pamọ sibẹ ti apapọ cocaine ti wọn ka mọ lọwọ si jẹ 800grams.
Nigba ti wọn bẹrẹ si ni fọrọ wa lẹnu wo, Nworie to si gẹri gẹri loun n se ni Brazil sọ pe oun wa si Naijiria pada lati wa sinku baba oun.
O jẹwọ pe ọrẹ rẹ kan to wa ni Sao Paulo lo fi isẹ oogun oloro tita lọ to si ni o fun oun ni miliọnu meji Naira toun ba gbe egboogi oloro wa si Naijiria.
Lọjọ Keji ọjọ yi laarin ọsẹ taa n sọ nipa rẹ,ajọ NDLEA da awọn paali ọti kan ti wọn fura si pe egboogi oloro wa ninu wọn.
Kia ni wọn ti mu arakunrin kan to n gbe ẹru wọle to si jẹ ẹni to gbe awọn ọti yi wọle lati Dubai,arakunrin Shola Ogunrinde.
Wọn lawọn tẹsiwaju iwadii awọn lẹyin ti wn mu Shola tan ti ọwọ si gba ibẹ tẹ obinrin alaboyun kan arabirin Seun Babatunde to ni ile ọti kan to wa ladugbo Iyana Ipaja.
Wọn si paali yi nisoju arakunrin Shola ati arabirin alaboyun yi ti wọn si ba aimọye igbo ati egboogi kan torukọ rẹ n jẹ ecstacy(MDAM) ninu agolo ọti yi.
Nigba ti arabirin Babatunde jẹwọ fun awọn ọlọpaa, o ni ọkọ oun to wa ni Dubau lo gbe awọn egboogi oloro yi ransẹ soun.
Alaboyun keji taa n wi ni arabinrin Gloria Asibor.
Lọjọ Karun un, osu karun un tii se Ọjọbọ ni panpẹ ofin mu nigba to fẹ wọ baalu kan lọ si Bolonia ni Spain gba Turkey.
Wọn tu ẹru to gbe lọwọ ti wọn si ri ounjẹ to gbe sinu rẹ.
Ninu ounjẹ yi ni wọn ti ba egboogi oloro tabilẹẹti Tramadol ti o ko si inu ede.



















