Goodluck Jonathan: Ẹgbẹ́ PDP àti APC sọ̀rọ̀ lórí ìròyìn pé Jonathan ti lọ sí ẹgbẹ́ APC

Oríṣun àwòrán, GOODLUCK JONATHAN / FACEBOOK
Ariyanjiyan ṣi n waye lori iroyin pe aarẹ Naijiria tẹlẹ, Goodluck Jonathan, ti darapọ mọ ẹgbẹ oṣelu All Progressives Congress, APC.
Ọjọ Aje ni iroyin naa jade, pẹlu afikun pe ẹgbẹ awọn fulani darandaran ti ra fọọmu fun lati dupo aarẹ labẹ asia ẹgbẹ APC.
Bo tilẹ jẹ pe Jonathan funra rẹ ti kede pe oun ko ran ẹnikẹni niṣẹ lati ra fọọmu fun oun.
- Ó pé ọdún 35 tí Obafemi Awolowo kú, wo àwọn nkan mánigbàgbé tí o kò gbọ́ rí nípa rẹ̀
- Adelabu kéde èròńgbà rẹ̀ láti jẹ gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo
- Ọwọ́ pálábá NDLEA tẹ aláboyún méjì, 'barber' kan àti àwọn afurasí mí tó gbé egbòogi
- Ẹ kò gbọdò lo 'Make Up'; ya 'tatoo'; fi kún èékánná tàbí kun àtíkè níta mọ́ lábẹ́ òfin wa- Iran
- Wo àwọn òjé tí àwọn olóṣèlú máa fi ń jẹ àwọn ènìyàn bí ètò ìdìbò bá ti ń súnmọ́lé
- Kò sí akẹ́kọ̀ọ́ ìpínlẹ̀ Sokoto, Zamfara tí yóò ṣe ìdánwò WASSCE lọ́dún 2022
- Ìdí mẹ́ta tí Goodluck Jonathan kò fi lè díje dupò lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú kankan lásìkò yìí
Ninu atẹjade kan to fi sita, agbẹnusọ fun aarẹ tẹlẹ naa, Ikechukwu Eze ni Jonathan kọ ẹbun naa jalẹ.
Agbẹnusọ fun ẹgbẹ oṣelu APC, Felix Morka sọ fun BBC pe oun ko ni le fidi iroyin naa mulẹ pe lootọ ni Jonathan ti wa si APC.
Lori pe boya o ṣe e ṣe fun ẹni ti kii sẹ ọmọ ẹgbẹ APC lati ra fọọmu oludije, Ọgbẹni Morka sọ pe "awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC nikan lo ni ẹtọ lati ṣoju ẹgbẹ naa ninu eto idibo.
"Lootọ ni ẹgbẹ tabi ẹnikẹni le ra fọọmu, ṣugbọn nibi eto ayẹwo ti yoo waye fun gbogbo wọn ni iwadii yoo ti fihan boya ọmọ ẹgbẹ ni onitọhun, imọ eto ẹkọ to ni, iye asiko to ti wa ninu ẹgbẹ.
"Awọn nkan wọnyii si ni yoo sọ boya wọn o fun ni tikẹẹti lati ṣoju ẹgbẹ ninu eto idibo."
Jonathan ko tii sọ boya o ti kuro ni PDP lọ si APC - PDP
Lori ọrọ yii kan naa, agbẹnusọ ẹgbẹ osẹlu Peoples Democratic Party, PDP, Debo Ologunagba, sọ pe oun ko le gbẹnusọ fun Goodluck Jonathan.
"Oun ni yoo fi ẹnu ara rẹ sọ boya o ti kuro ninu ẹgbẹ PDP.
"O ti sọrọ pe oun ko ran ẹnikẹni lati gba fọọmu ẹgbẹ osẹlu APC fun oun. Nitori naa, ko si nkan mii ti mo tun fẹ sọ mọ."
Mi ò rán Miyetti Allah níṣẹ́ láti ra fọ́ọ̀mù ìdíje ààrẹ lẹ́gbẹ́ òṣèlú APC fún mi - Jonathan
Aarẹ tẹlẹ lorilẹede Naijiria, Goodluck Jonathan ti kede rẹ sita lohun goorogo pe oun ko nifẹ si didje fun ipo aarẹ lẹgbẹ oṣelu APC, nitori naa oun ti kọ fọọmu idije ti ẹgbẹ awọn fulani, Miyetti Allah ra lorukọ oun.
Ni ọjọ Aje ni ẹgbẹ Miyetti Allah kede pe awọn ti ra fọọmu idije ọlọgọrun miliọnu Naira lorukọ Goodluck Jonathan lati dije fun ipo aarẹ Naijiria lọdun 2023.

Oríṣun àwòrán, Others
Amọṣa, aarẹ ana, Goodluck Jonathan ti ni ohun ko ran ẹnikẹni niṣẹ lati lọ ree ra fọọmu idije fun oun.
"O ti wa si eti igbọ wa pe pe awọn ẹgbẹ kan ti lọ ra fọọmu idije lẹgbẹ oṣelu APC lorukọ aarẹ tẹlẹ, Ọmọwe Goodluck Ebele Jonathan."
"A fẹ laa ko yeawọn eeyan pe bi aarẹ tẹlẹ naa ba fẹ dije fun ipo ibo kankan, yoo mu erongba rẹ han ni gbangba, kii ṣe ni kọọrọ"
- 'Ètò ayẹ́yẹ́ ìsìnkú Oba Lamidi Adeyemi kòí tíì wáyé, àfọ̀mọ́ Aàfin ń lọ lọ́wọ́'
- Ó pé ọdún 35 tí Obafemi Awolowo kú, wo àwọn nkan mánigbàgbé tí o kò gbọ́ rí nípa rẹ̀
- Èsì àyẹ̀wò ohun tó ṣekú pa gbajúmọ̀ akọrin ẹ̀mí, Osinachi Nwachukwu ti jáde
- Gomina Yahaya Bello ra fọ́ọ̀mù N100m láti gba iṣẹ́ lọ́wọ́ Ààrẹ Buhari
- Àwọn ológun pa ikọ̀ Boko Haram ogún, wọ́n dóòlà àwọn obìnrin tó wà ní ìgbèkùn
- Mo ti gbà báyìí pé ohun gbogbo tó n dán kọ́ ni wúrà - Olori Badirat Adeyemi
- Lukman gbẹ̀yín ẹbí lọ bẹ́ orí ìkókó ti wọ́n sìn ní Abeokuta, àṣírí tú bó ṣe fẹ́ tàá
- Ẹ dáríjìn mí ọmọdé ló ń ṣe mí, mo kábàmọ́ ìwà tí mo wú - Akẹ́kọ̀ọ́ Chrisland Schools















