Political gimmicks: Wo àwọn òjé tí àwọn olóṣèlú máa fi ń jẹ àwọn ènìyàn bí ètò ìdìbò bá ti ń súnmọ́lé

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Bí ètò ìdìbò gbogbogboò ọdún 2023 ṣe ti ń súnmọ́ ètilè, a ṣe àgbéyẹ̀wò díẹ̀ lára àwọn ìwà àti àwọn òjé tí àwọn olóṣèlú ti ṣe rí lásìkò tí ètò ìdìbò ń bọ̀
Bí àwòràn gómìnà tẹ́lẹ̀ rí ní ìpínlẹ̀ Ekiti, Ayodele Fayose, níbi tó ti ń jẹ àmàlà ní búkà kan nílùú Abuja lẹ́yìn tó gba fọ́ọ̀mù láti díje sípò Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà gba orí ẹ̀rọ ayélujára mú ìrántí gbogbo àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó máa ń wáyé lásìkò tí ètò ìdìbò máa ń súnmọ́.
Ní agbègbè Wuye ní Abuja ni Fayose mórílé lẹ́yìn tó gba fọ́ọ̀mù tań láti lọ jẹ àmàlà pẹ̀lú oríṣiríṣi nǹkan inú ẹran gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀ lọ́pọ̀ ìgbà láti fi hàn wí pé òun ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú ènìyàn òun.
Ọ̀pọ̀ ènìyàn, lórí ayélujára ní ìwà tí Fayose hù yìí kìí ṣe àkọ́kọ́ rẹ̀ nítorí láti ìbẹ̀rẹ̀ ọdún 2000 ni Fayose ti ń ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà tó ń díje sípò gómìnà lọ́dún 2003.
- 'Ètò ayẹ́yẹ́ ìsìnkú Oba Lamidi Adeyemi kòí tíì wáyé, àfọ̀mọ́ Aàfin ń lọ lọ́wọ́'
- Ó pé ọdún 35 tí Obafemi Awolowo kú, wo àwọn nkan mánigbàgbé tí o kò gbọ́ rí nípa rẹ̀
- Èsì àyẹ̀wò ohun tó ṣekú pa gbajúmọ̀ akọrin ẹ̀mí, Osinachi Nwachukwu ti jáde
- Gomina Yahaya Bello ra fọ́ọ̀mù N100m láti gba iṣẹ́ lọ́wọ́ Ààrẹ Buhari
- Àwọn ológun pa ikọ̀ Boko Haram ogún, wọ́n dóòlà àwọn obìnrin tó wà ní ìgbèkùn
- Mo ti gbà báyìí pé ohun gbogbo tó n dán kọ́ ni wúrà - Olori Badirat Adeyemi
- Lukman gbẹ̀yín ẹbí lọ bẹ́ orí ìkókó ti wọ́n sìn ní Abeokuta, àṣírí tú bó ṣe fẹ́ tàá
- Ẹ dáríjìn mí ọmọdé ló ń ṣe mí, mo kábàmọ́ ìwà tí mo wú - Akẹ́kọ̀ọ́ Chrisland Schools
- Óṣe! Àwọn ọmọdé mẹ́rin pàdánù ẹ̀mí wọn bí wáyà iná ṣe já lé wọn lórí
- Àwọn ènìyàn Nàìjíríà fi ìdùnnú hàn bí ìjọba ṣe ṣí àwọn ibodè mẹ́rin mìíràn
Tí ètò ìdìbò bá ti ń bọ̀ lọ́nà, pàápàá tó bá ti ku bí ọdún kan tàbí oṣù díẹ̀, lára ohun tí àwọn olóṣèlú máa ń ṣe ni kí wọ́n máa ra àgbàdo jẹ ní ẹsẹ̀ títì, wọ ilé onídìrí lọ láti máa bá àwọn ènìyàn ṣerun, gun ọ̀kadà àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.
Àwọn irúfẹ́ ìwà yìí máa ń fa awuyewuye lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Nàìjíríà tó jẹ́ wí pé tí àwọn kan máa ń sọ wí pé ẹ̀tàn lásán ni wọ́n ń fi gbogbo àwọn olóṣèlú máa ń fi ìwà bẹ́ẹ̀ ṣe.
Bí ètò ìdìbò gbogbogboò ọdún 2023 ṣe ti ń súnmọ́ ètilè, a ní ká ṣe àgbéyẹ̀wò díẹ̀ lára àwọn ìwà àti àwọn òjé tí àwọn olóṣèlú ti ṣe rí lásìkò tí ètò ìdìbò ń bọ̀.

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Obaseki àti Oshiomhole jẹ àgbàdo lórí ìrìn
Níbi ètò ìpolongo sí ìdìbò tó gbé gómìnà ìpínlẹ̀ Edo, Godwin Obaseki wọlé ní sáà àkọ́kọ́ rẹ̀ lọ́dún 2016 ní Obaseki àti bàbá ìsàlẹ̀ rẹ̀, tó tún jẹ́ èèkàn nínú ẹgbẹ́ òṣèlú APC, Adams Oshiomhole ra àgbàdo lójú ọ̀nà.
Ní ojú ọ̀nà yẹn náà ni wọ́n ti ń ya àgbàdo jẹ ní ẹsẹ̀ títì ní ìlú Benin tí ń ṣe olú ìlú ìpínlẹ̀ Edo láti fi han àwọn alátìlẹyìn wọn, gẹ́gẹ́ bí èrò wọn wí pé kò sí ìyàtọ̀ láàárín àwọn.

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Oshiomhole tún padà sí yíya àgbàdo jẹ
Bí ètò ìdìbò ọdún 2020 sí ìbò gómìnà tún ṣe tún ń bọ̀ lọ́nà ní ìpínlẹ̀ Edo ní ọdún 2020, Oshiomhole àti Obaseki ti pín gààrí, àwọn méjéèjì ti ṣe lọ́tọ́ọ̀tọ̀ tó mú Obaseki fi fi ẹgbẹ́ APC sílẹ̀ bọ́ sí PDP.
- ASUU fi oṣù mẹ́ta kún ìyanṣẹ́lódì wọn nítorí pé.......
- Ẹgbẹ́ CAN foríjin ilé ìfowópamọ́ Sterling, ìdí rèé
- Àwọn iléeṣẹ́ bàlúù ní Nàìjíríà ronúpìwàdà lórí wíwọ́gilé ìrìnnà òfúrufú ní Nàìjíríà lọ́jọ́ Ajé, ohun tó fàá nìyí
- INEC lẹ́tọ̀ọ́ láti bẹ́gi dínà èróngbà Emefiele láti díje du ipò Ààrẹ- Ilé ẹjọ́
- Mọ̀lẹ́bí ṣàlàyé kíkún nípa bí agbébọn ṣe ṣekúpa Gloria Mathew àti àfẹ́sọ́nà rẹ̀ nínú igbó ní ìpínlẹ̀ Imo
- Ṣé Christiano Ronaldo yóò dúró tàbí kò ní dúró n'Manchester United fún sáà líìgì tó ń bọ̀?
- Ẹ kò gbọdò lo 'Make Up'; ya 'tatoo'; fi kún èékánná tàbí kun àtíkè níta mọ́ lábẹ́ òfin wa- Iran
- Ìpapòda Aláàfin kò ní dá ètò ìfinijoyè Gbajabiamila dúró- Ọyọmesi
- Irọ́ ni, irọ́ kọ́ Toyin Adegbola àti àwọn míì sọ̀rọ̀ nípa fídíò Biola àti Olùdarí ere tí wọ́n jọ ní gbólóhùn asọ̀
Fọ́nrán Oshiomhole kan gba orí ayélujára kan níbi tó ti ń jẹ àgbàdo tí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ sì ń sàá.
Lẹ́yìn ò rẹyìn, Obaseki padà fi fọ́nrán tó jẹ́ wí pé òun àti Oshiomhole ti ṣe irú rẹ̀ sẹ́yìn fi bu pé kò ní ọ̀wọ̀ kankan fún àwọn ènìyàn àti pé àwọn ènìyàn kìí ṣe adìẹ tí yóò máa sáré tẹ̀lé àgbàdo kiri.

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Omisore náà fi àwòrán ibi tó ti ń jẹ àgbàdo sórí ayélujára
Kò sí bí ènìyàn kò ní fẹ́ rín ẹ̀rín àríntàkìtì nígbà tó bá kọ́kọ́ rí àwòrán olóyè Iyiola Omisore níbi tó ti mú àgbàdo méjì sí ọwọ́ stún rẹ̀ méjéèjì bí ẹni wí pé ẹ̀rù ń bàá láti jẹ́.
Ọ̀pọ̀ ènìyàn tilẹ̀ sọ nígbà náà wí pé yóò rí bẹ̀ nítorí kìí ṣe ìfẹ́ àwọn ara ìlú ló mu fi ra àgbàdo nírònà bíkòṣe nítorí pé àwòrán tó fẹ́ fi yà.
Yàtọ̀ sí àwòrán yìí, àwọn ìgbà mìíràn ni Omisore ti ya àwòrán ara rẹ̀ lórí ọ̀kadà, ra gúgúrú lẹ́sẹ̀ títì, gbé ṣíbí ìrẹsì dání lórí àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Sanwo-Olu
Ṣaájú ọjọ́ ìdìbò tó gbé gómìnà ìpínlẹ̀ Eko, Babajide Sanwo-Olu wọlé ọ̀kan-ò-jọ̀kan àwọ̀ ni Sanwo-Olu gbéwọ̀ bí ọ̀gà.
Lára àwọn àwòrán ohun tí Sanwo-Olu ṣe nígbà náà tó fẹ́rẹ̀ fa orí ayélujára ya ni ìgbà tí òun àti igbákejì rẹ̀ Obafemi Hamzat ń dirun fún obìnrin kan ní agbègbè Computer Village, Ikeja.
Àwòrán míì ni èyí tó fi ìgbà tí àti igbákejì rẹ̀ ń kọ́ṣẹ́ bí ènìyàn ṣe le tún fóònù ṣe, ìgbà tí wọ́n ṣe àbẹ̀wò sí ṣọ́ọ̀bù Mẹkáníìkì kan tí wọ́n sì ń ba pààrọ̀ ọ́ìlì ọkọ̀. Gbogbo rẹ̀ láti fa ojú àwọn ènìyàn mọ́ra láti dìbò fún wọn.
Nígbà tí àwòrán Sanwo-Olu mìíràn níbi tó ti ń ra bọ̀ọ̀lì tún lu orí ayélujára nínú oṣù kejì ọdún 2021, àwọn ènìyàn ní ó padà sí ẹsẹ̀ àárọ̀ rẹ̀ ni.

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Melaye kiri ọjà
Ní ọdún 2016 tí àwòrán Dino Melaye níbi tó ti gbé àtẹ ẹ̀pà lórí bí ẹni tó ń kiri ọjà gba orí ayélujára ni àwọn ènìyàn kó ẹnu bòó wí pé ẹ̀tàn lásán ni.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àdúgbò tí Melaye ti ya àwòrán náà kìí ṣe ọjà, Melaye ní òun kìí ṣe ẹlẹ́tàn nítorí òun kiri ọjà dáadáa nígbà tí òun wà ní kékeré.

Oríṣun àwòrán, TWITTER
Osinbajo nínú ọkọ̀ BRT
Nínú oṣù kejìlá, ọdún 2014, Ọ̀jọ̀gbọ́n Yemi Osinbajo tó jẹ́ olùdíje sípò igbákejì Ààrẹ orílẹ̀ èdè yìí gbé àwòrán ibi tó ti wọ ọkọ̀ BRT tó sì ń bá àwọn ènìyàn tàkurọ̀sọ sórí ayélujára Twitter rẹ̀.
Mélòó la fẹ́ kà nínú eyín adípèlé ni ọ̀rọ̀ àwọn ọ̀kan-ò-jọ̀kan ìwà tí àwọn olóṣèlú máa ń wù lásìkò tí ètò ìdìbò bá ń bọ̀.
Bí ètò ìdÌbò gbogbogboò ọdún 2023 ṣe ń súnmọ́ etílé ẹyẹ àdán BBC doríkodò ó ń wòṣe ẹyẹ àwọn olóṣèlú lórí itú tí wọ́n yóò tún pa àti wí pé ǹjẹ́ àwọn òjé yìí yóò tún jẹ àwọn ọmọ Nàìjíríà.




















