Obafemi Awolowo: Ó pé ọdún 35 tí Obafemi Awolowo kú, wo àwọn nkan mánigbàgbé tí o kò gbọ́ rí nípa rẹ̀

Oríṣun àwòrán, other
Oni, ọjọ kẹsan-an, oṣu Karun-un, ọdun 2022, lo pe ọdun marundinlogoji, ti Obafemi Jeremiah Awolowo, kú.
Ọjọ kẹsan, oṣu Karun-un, ọdun 1987 lo ku si ilu Ikenne, nipinlẹ Ogun, lẹni ọdun mejidinlọgọrin.
Odu ni oloogbe Awolowo laarin awọn ọmọ Naijiria, ati nilẹ okeere, nitori ipa ribiribi to ko ninu idagbasoke Naijiria.
Tani Oloye Obafemi Awolowo?
Wọn bi Awolowo ni ọjọ kẹfa, oṣu Kẹta, ọdun 1909, nipinlẹ Ogun.
O kẹkọọ gboye nipa eto ọrọ aje, to si tun gboye imọ ofin ni orilẹ-ede England lọdun 1945.
Ṣaaju asiko yii, Awolowo ṣiṣẹ gẹgẹ bi akọroyin, to si da ileeṣẹ iroyin Nigerian Tribune silẹ lọdun 1949.
Nigba to pada si Naijiria lẹyin eto ẹkọ rẹ, o di olori ẹgbẹ oṣelu Action Group,
- Àwọn èèkàn ìlú péjú s'Ibadan níbi ìsìnkú màmá Omotola àkọ́bí obìnrin Awolowo tó wọ káà ilẹ̀ lọ
- Seyi Awolowo, ọmọ-ọmọ Awolowo, kí ló ń wà lórí ètò BB Naija?
- Kiki Osinbajo gbóṣùbà fún Seyi Awolowo, MC Oluomo tọrọ ìbò fún Mike ní BBNaija
- Ìbéèrè àti ìdáhùn pẹ̀lú Seyi Awolowo ti BBNaija lórí BBC Yorùbá
- Wo okùnfà ìṣubú ìjọba alágbádá àkọ́kọ́ àti ẹ̀kọ́ fun olóṣèlú òde òní
- Buhari, Makinde, Sanwo-Olu kẹ́dùn pẹ̀lú ẹbí Tola Oyediran, àkọ́bí lóbìnrin tí Obafemi Awolowo bí tó papòdà
Lẹyin naa lo di olootu ijọba ẹkun Gusu Naijiria.
Gẹgẹ bi olootu ijọba, o ṣe idasilẹ eto ẹkọ ọfẹ nile ẹkọ alakọbẹrẹ, ati eto ilera ọfẹ, jakejado Gusu Naijiria.
Yatọ si eyi, oloogbe Awolowo, lo ṣagbatẹtu bi ijọba ṣe kọ papa iṣere akọkọ ni Naijiria, Liberty Stadium, nilu Ibadan.
Ipa kekere kọ ni Oloye Awolowo kó ninu ijagbara fun ominira Naijiria kuro lọwọ awọn oyinbo amunisin.
Lọdun 1963, ijọba ju si ẹwọn fun ẹsun pe o ru awọn eeyan soke lati tako ijọba. Ọdun 1966 lo to gba ominira, to si di minisita eto isuna.
Awọn nkan mii ti Awolowo ṣe ninu itan Naijiria
Awolowo lo fun owo Naira ni orukọ, nigba to fi jẹ minisita akọkọ fun eto iṣuna.
O da ileeṣẹ tẹlifisan akọkọ ni Africa, Western Nigeria Television silẹ nilu Ibadan, lọdun 1959. Ileeṣẹ tẹlifisan naa lo pada di NTA.
Oun lo kọ Ile gogoro 'skyscrapper' akọkọ ni Africa, Cocoa House, silu Ibadan
Obafemi Awolowo ni ẹni akọkọ ti wọn fun ni orukọ 'Asiwaju Omo Oodua', gẹgẹ bi olori oṣelu nilẹ Yoruba.
Awọn iwe to kọ ko to o ku ni:
•Path to Nigerian Freedom
•Awo - Autobiography of Chief Obafemi Awolowo
•My Early Life
•Thoughts on the Nigerian Constitution
•The People's Republic
•The Strategy & Tactics of the People's Republic of Nigeria
•The Problems of Africa - The Need for Ideological Appraisal
•Awo on the Nigerian Civil War
•Path to Nigerian Greatness
•Voice of Reason
•Voice of Courage
•Voice of Wisdom
•Adventures in Power - Book 1 - My March Through Prison
•Adventures in Power - Book 2 - Travails of Democracy
•My march through prison
•Socialism in the service of New Nigeria
•Selected speeches of Chief Obafemi Awolowo
•Philosophy of Independent Nigeria
•Memorable Quotes from Awo
•The Path to Economic Freedom in Developing Country
•Blueprint for Post-War Reconstruction
•Anglo-Nigerian Military Pact Agreement




















