Tola Oyediran: Buhari, Makinde, Sanwo-Olu ń ṣèdárò Tola Oyediran ọmọ Obafemi Awolowo tó papòdà

Tola Oyediran

Oríṣun àwòrán, Tribuneonline

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Ọpẹ eekan lagbo oṣelu lo ti n ranṣẹ ibanikẹdun si ẹbi mama Tola Oyediran tii ṣe akọbi obinrin Oloye Obafemi Awolowo to jade laye lọjọ Ẹti.

Aburo oloogbe naa, Ọmọwe Tokunbo Dosunmu-Awolowo to ba BBC Yoruba ṣalaye pe ni bii deedee aago mejila ọsan ti mama jẹ Ọlọrun nipe.

Ẹwẹ, Aarẹ Muhammadu Buhari ti kẹdun pẹlu idile oloogbe Tola Oyediran.

Ninu atẹjade ti oludamọran Aarẹ Buhari lori ọrọ iroyin, Garba Shehu fi sita, Buhari ni ki wọn dupẹ lọwọ Eledua fun igbe aye to daara ti mama gbe nigba to wa laye.

Buhari ni oloogbe naa gbiyanju agbara rẹ lati ṣe iranwọ fawọn eeyan to layika rẹ eleyi ti awọn eeyan yoo maa fi ṣe iranti rẹ lọ laelae.

Aarẹ gbadura wi pe ki ọlọrun tẹ mama si afẹfẹ rere ki O si tun awọn ẹbi rẹ ninu.

Àkọlé fídíò, Ogbomsho shooting, End Sars, End SWAT: Isiaka fi ọmọbìnrin kan àti ìyàwó tó lóyún sínú síl

Gomina Seyi Makinde ipinlẹ Oyo naa ti ṣapejuwe iku mama Oyediran gẹgẹ bi adanu nla fun orilẹede Naijiria.

Ninu iṣẹ ibanikẹdun to fi ṣọwọ si igbimọ alaṣẹ iwe iroyin Tribune, Makinde ni lootọọ ni mama ti ku, ṣugbọn ipa to ni lawujọ ko le parẹ laelae.

Tola Oyediran Awolowo

Oríṣun àwòrán, Tribune Newspaper

Bakan naa lo sọ pe awọn eeyan yoo maa ṣe iranti mama Oyediran gẹgẹ bi ẹnikan to tẹ le awọn ilana ti Oloye Awolowo la kalẹ titi to fi ku.

Makinde ko ṣalai ki aburo oloogbe, Dokita Dosunmu-Awolowo ati iyawo igbakeji aarẹ Dolapo Osinbaji pẹlu igbakeji Aarẹ rẹ ku ara fẹraku.

Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu naa ko gbẹyin ninu awọn to n ṣedaro ẹn'ire to lọ.

Skip X post
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post

O ni adanu nla ni iku mama Oyediran jẹ fun ẹbi, atawọn ọrẹ rẹ to fi mọ ile iwe iroyin Tribune.

Sanwo-Olu ni olori to ṣee fi ọkan tan ni mama nigba aye rẹ ati pe ẹlẹyinju aanu ati onirẹlẹ eniyan ni.

Tola Oyediran ọmọ Obafemi Awolowo ti jáde láyé

Iku n pa ni, ilẹ n jẹ eeyan. Iroyin to n tẹ wa lọwọ lo sọ pe Tola Oyediran Awolowo ti papoda.

Ọjọ kinni oṣu kejila ọdun 2020 yii ni mama Oyediran to jẹ ọkan ninu awọn ọmọ olootu ijọ iwọ oorun guusu Naijiria nigba kan ri, Oloye Obafemi Awolowo ko ba ṣe ayẹyẹ ọjọ ibi ọgọrin ọdun laye.

Oun ni omọ Awowlọwọ to dagba ju ki iku to mu un lọ.

Tola si ni alaga igbimọ alaṣẹ iwe iroyin Tribune titi ti o fi faye silẹ.

Dokita Tokunbọ Dosunmu ṣalaye fun BBC pé Arabinrin Tola Oyediran Awolowo ko ṣaarẹ rara ki ọlọjọ to de.

O ni nkan bii aago mejila ọsan oni ni alumuntu wọle de were to mu ẹgbọn oun lọ.

Bakan naa lo ni ẹbi ṣi wa ninu irora ati iyalẹnu pe ṣe gbogbo ẹ ti pari naa ni yẹn ni asiko yii.

BBC gbadura pe ki Olorun tu ẹbi ti ọrọ kan naa ninu lasiko yii

Àkọlé fídíò, Gbajúgbajà òsèré tó tún mọ́ ọbẹ̀ sè