Oyo Chieftancy Coronation: Ìpapòda Aláàfin kò ní dá ètò ìfinijoyè Femi Gbajabiamila dúró- Ọyọmesi

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Ti baba ba ku, baba nii ku, adiyẹ kii si ku kaa dọmọ rẹ nu.
Ni kete ti Alaafin ilu ọyọ, Ọba Lamidi Adeyemi tẹri gbaṣọ ni ọpọlọpọ ti sọ pẹ oye Aarẹ Baasofin ti ilẹ Yoruba ti Alaafin fẹ fi da Abẹnugan ile igbimọ aṣojuṣofin orilẹ ede Naijiria, Femi Gbajabiamila lọla ni o ṣe ṣeeṣe ki o ma waye mọ.
Ṣugbọn ọrọ yipada ni ọjọ Aiku, ọjọ kẹjọ, oṣu karun-un, ọdun 2022 nigba ti Oyomesi ni ipapoda Alaafin ko ni da jijẹ oye naa duro.
- Ó pé ọdún 35 tí Obafemi Awolowo kú, wo àwọn nkan mánigbàgbé tí o kò gbọ́ rí nípa rẹ̀
- Mọ̀lẹ́bí ṣàlàyé kíkún nípa bí agbébọn ṣe ṣekúpa Gloria Mathew àti àfẹ́sọ́nà rẹ̀ nínú igbó ní ìpínlẹ̀ Imo
- Irọ́ ni, irọ́ kọ́ Toyin Adegbola àti àwọn míì sọ̀rọ̀ nípa fídíò Biola àti Olùdarí ere tí wọ́n jọ ní gbólóhùnasọ̀
- INEC lẹ́tọ̀ọ́ láti bẹ́gi dínà èróngbà Emefiele láti díje du ipò Ààrẹ- Ilé ẹjọ́
- Àwọn iléeṣẹ́ bàlúù ní Nàìjíríà ronúpìwàdà lórí wíwọ́gilé ìrìnnà òfúrufú ní Nàìjíríà lọ́jọ́ Ajé, ohun tó fàá nìyí
- ASUU fi oṣù mẹ́ta kún ìyanṣẹ́lódì wọn nítorí pé.......
- Wo àwọn òjé tí àwọn olóṣèlú máa fi ń jẹ àwọn ènìyàn bí ètò ìdìbò bá ti ń súnmọ́lé
Basorun ilu Oyo, Oloye Olayinka Ayoola lo sọ ọrọ naa nigba ti Gbajabiamila ṣe abẹwo si Aafin ilu Oyo lati ba idile Alowolodu, Oyomesi ati gbogbo ilu Oyo kẹdun Alaafin Adeyemi to lọ darapọ mọ awọn babanla rẹ
Oloye Ayoola ni ifinijoye naa jẹ nnkan ti Ọba Adeyemi fẹ ko ṣeeṣe ki wọn to waja ṣugbọn àwọn alalẹ ko kọ.
Ninu ọrọ mọlẹbi Alowolodu, Ọmọọba Akeem Adeyemi sọ pe tori Gbajabiamila jẹ ọkan lara awọn Yoruba to gbe Aṣa ati iṣe ẹya naa larugẹ ni Ọba Lamidi fi ni pe oye naa tọ sii.
O ni "Alaafin ni gẹgẹ bi ọmọ Yoruba, Gbajabiamila koju oṣuwọn lati di Aarẹ Baasofin ilẹ Yoruba, o si di dandan lati di ṣiṣe."
Ayẹyẹ ifinijoye naa lo yẹ ko waye lọjọ kẹtadinlọgbọn oṣu karun-un, ọdun 2022 lati fi ṣami ayẹyẹ ọjọ ibi abẹnugan naa.
- Ẹbí kan pàdánù ọmọ mẹsan-án nínú èèyàn 435 tí omiyalé pa
- Ẹgbẹ́ CAN foríjin ilé ìfowópamọ́ Sterling, ìdí rèé
- Iṣẹ́ Ọlọ́run tí mo gbé dáni kọjá ipò Ààrẹ Nàìjíríà – Bíṣọ̀ọ̀bù David Oyedepo
- Irọ́ ni pé Bola Tinubu fẹ́ kúrò ní ẹgbẹ́ òṣèlú APC- Agbẹnusọ Aṣíwájú
- Ṣé Christiano Ronaldo yóò dúró tàbí kò ní dúró n'Manchester United fún sáà líìgì tó ń bọ̀?
















