Buhari orders ministers to resign: Kìí ṣe àwọn mínísítà tó fẹ́ dupò nìkan ní Buhari ní kó fi iṣẹ́ sílẹ̀ , wo àwọn tó tún kàn

Oríṣun àwòrán, Nigeria presidency
Aarẹ Muhammadu Buhari ti paṣẹ fun gbogbo awọn ọmọ igbimọ alaṣẹ rẹ to fẹ dupo oṣelu lati fa akoso le ẹni to jẹ igbakeji wọn lọwọ.
Ikede tuntun yii waye ninu atẹjade kan ti akọwe ijọba apapaọ, Boss Mustapha fi sita ni owurọ Ọjọbọ.
Ọjọru ni Aarẹ Buhari kede, lati ẹnu minisita fun eto iroyin, Lai Muhammed, pe ki gbogbo awọn minsiita fo fẹ lọ dije fun ibo ọdun 2023 kọwe fi ipo wọn silẹ titi ọjọ kẹrindinlogun, oṣu Karun-un.
- Àwọn olùfẹ̀hónúhàn dáná sun dúkìá bí ìwọ́de ṣe ń le si
- Ọwọ́ tẹ afurasí ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn ní ilé ìtura, wo nǹkan tí ọlọ́pàá ká mọ lọ́wọ́
- Ẹ múra o, ọ̀wọ́n gógó bẹntiró ń rúgbó bọ̀- IPMAN ṣèkìlọ̀ fún àwọn ọmọ Nàìjíríà
- PDP wọ́gilé ìlànà jẹ kí n jẹ 'zoning' fún yíyan olùdíje ipò ààrẹ
- Èèyàn 60 l'erin ti pa láàrín ọdún yìí nìkan lórílẹ̀èdè Zimbabwe
- Àwọn olùkọ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga gbogbonìṣe Poly ní Nàìjíríà , ASUP bẹ́rẹ́ ìyanṣẹ́lódì, wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀
- Ọ̀rọ̀ pátà dídọ̀tí tún rúná sí ìjà láàrin Nkechi Blessing àti ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ tẹ́lẹ̀, Falegan
Ninu ikede ti Mustapha fi sita, o ni aṣẹ naa tun kan awọn aṣoju Naijiria nilẹ okeere, awọn olori ileeṣẹ ati ajọ to jẹ ti ijọba, to fi mọ awọn mii ti ijọba yan sipo gẹgẹ bi oloṣelu.
"Gbogbo awọn minisita ti aṣẹ yii kan, gbọdọ fa akoso ileeṣẹ ti wọn n mojuto le minisita keji lọwọ, tabi akọwe agba, nibi ti ko ba ti si minisita keji.
"Awọn to jẹ aṣoju orilẹ-ede gbọdọ fa akoso le igbakeji wọn tabi oṣisẹ to ga ju lọ lọwọ."
Fun awọn to wa ni awọn ajọ ati ileeṣẹ ijọba mii, wọn gbọdọ fa iṣẹ le oludari agba to wa ni ẹka wọn lọwọ.
Boss Mustapha sọ pe ni kiakia ni aṣẹ naa fidi mulẹ.
Buhari pàṣẹ fún àwọn mínísítà tó bá fẹ́ dupò òṣèlú láti kọ̀wé fi iṣẹ́ sílẹ̀ ní kíá
Aarẹ Muhammadu Buhari ti paṣẹ fun gbogbo awọn minsita rẹ lati kọwe fi ipo wọn silẹ ti yoo ba fi di ọjọ kẹrindinlogun, oṣu Karun-un.
Minisita fun eto iroyin, Lai Mohammed lo kede aṣẹ naa lẹyin ti wọn pari ipade igbimọ alaṣẹ Niajiria to waye nile ijọba nilu Abuja.
Awọn minisita ti ọrọ naa kan ni Rotimi amaechi, minisita fun eto irinna; Chris Ngige, minisita fun ọrọ oṣiṣẹ; Abubakar Malami, minisita fun eto idajọ; ati Godswill akpabio, minisita fun ọrọ Niger Delta.
Gbogbo awọn minisita yii lo ti fi erongba wọn han pe awọn fẹ dije fun boya ipo gomina, sẹnetọ tabi aarẹ.
Awọn yooku ni Uche Ogar, minisita keji fun iwakusa; Pauline Tallen, minisita fun ọrọ awọn obinrin.
- Ìjọba Oyo dá ẹ̀kọ́ nípa ìmọ̀ ìtàn "History" padà sí ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀bẹ̀rẹ̀
- Human Rights Watch fẹ̀sùn àìbìkítà kan ìjọba Naijiria lẹ́yìn ikú awọn olùwọ́de lásìkò ìwọ́de EndSARS
- Olùkọ́ Chrisland College mẹ́rin fojú balé ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn ìbálòpọ̀
- Ṣé lóòtọ́ ni Jonathan ti darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ APC? Nkan tí PDP àti APC sọ rèé
- Wo ìdí tí Ilé aṣòfin àpàpọ̀ Nàìjíríà ṣe yí òfin ìdìbò padà fún ààrẹ, gómìnà, àwọn aṣòfin àtàwọn míràn
- Ìdí mẹ́ta tí Goodluck Jonathan kò fi lè díje dupò lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú kankan lásìkò yìí
- Wo àwọn tó ra fọ́ọ̀mù ipò Ààrẹ ẹgbẹ́ òṣèlú APC
Ṣaaju, ni ọjọ karundinlọgbọn, oṣu Keji, ọdun 2022, ni Aarẹ Buhari kesi ile aṣofin agba, lati ṣe atunsẹ si abala kẹrinlelọgọrin ofin , eyi to fi ofin de pe ẹni to ba di ipo osẹlu mu ko gbọdọ dije fun ipo.
Ṣugbọn awọn aṣofin ko ṣe bẹẹ si ofin to ni iru ẹni naa gbọdọ kọkọ kọwe fi iṣẹ silẹ ni ipo rẹ, ko to le dije.
Koda, ile ẹjọ giga ijọba apapọ nilu abuja paṣẹ pe Buhari, minisita fun eto idajọ, abubakar Malami, ati awn aṣofin, ko gbọdọ yi ofin naa àda rara.
Ọjọ Iṣẹgun ni ile aṣofin agba buwọlu ofin kan pe igbakeji aarẹ, awọn ọmọ ileegbimọ aṣofin, gomina atawọn igbakeji wọn, awọn ọmọ ileegbimọ aṣofin ipinlẹ, awọn alaga kansu, kansilọ atawọn ọmọ igbimọamuṣẹya ẹgbẹ oṣelu gbogbo, le dupo osẹlu lai fi ipo ti wọn wa silẹ.

















