PDP zoning: Ìgbákejì akọ̀wé ìkéde fún PDP sọ pé ẹkùn mẹ́fẹ́ẹ̀fà Naijiria ló ní ẹ̀tọ́ láti jẹ́ olùdíje ẹgbẹ́ fún ipò ààrẹ̀

Aisa ẹgbẹ osẹlu PDP

Oríṣun àwòrán, KOLA OLOGBODIYAN / FACEBOOK

Lati Ọjọru ti ẹgbẹ oṣelu Peoples Democratic Party, PDP, ti kede pe oun ko ni yan oludije kankan ni pọsin, ni awuyewuye ti n waye.

Ṣugbọn ninu ọrọ to ba BBC sọ, Ibrahim Abdullahi, to jẹ igbakeji akọwe ikede fun PDP, sọ pe ẹgbẹ gbe igbesẹ naa nitori pe dọgba-dọgba ni gbogbo ọmọ ẹgbẹ.

O ni lasiko ipade kan pẹlu awọn ọmọ ẹgbẹ naa ni Ila oorun Gusu, ni awọn ẹya Igbo ti beere fun pe ki ipo oludije fun ipo aarẹ bọ sọwọ wọn.

Ọgbẹni Abdullahi sọ pe amọ awọn ọmọ igbimọ oludari ẹgbẹ kọ̀, pẹlu alaye pe ẹkùn mẹfa lo wa ni orilẹ-ede Naijiria, gbogbo wọn lo si ni ẹtọ lati fa oludije kalẹ.

"Alaga ẹgbẹ wa nigba kan, Okwesilieze Nwodo, sọ pe lootọ ni awọn ẹya Igbo ṣatilẹyin fun ẹgbẹ, amọ ẹya naa lo yẹ ki anfaani lati dupo aarẹ bọ si lọwọ.

"To si bẹbẹ pe ki ẹgbẹ yọnda tikẹẹti fun wọn."

Abdullahi sọ pe nkan to ṣoro lati ṣe fun igbimọ alamojuto ẹgbẹ ni nkan ti Nwodo beere fun, nitori pe gbogbo ẹgbẹ ti fẹnuko pe wọn ko ni yọ ẹkun kankan silẹ.

O ni amọ o ṣe e ṣe lọjọ iwaju, ṣaaju ki idibo to waye, ti ẹgbẹ ba woye pe ki awọn eeyan kan jawọ ninu idije fun ẹnikan.

"Amọ, eyi yoo jẹ nkan ti gbogbo awọn oludije fi ara mọ."

Àkọlé fídíò, Mathew Okotie, Driver who returned laptop: Ṣé àwọn awakọ̀ olóòtọ́ ṣi kù ní Nàìjírípa?

O salaye pe lilo ẹya tabi ẹkun ti eeyan ti wa, lati fun wọn ni tikẹẹti oludije, ko si ninu ofin ati ilana ẹgbẹ oṣelu PDP.

"Bi eeyan ba ṣe gbajumọ si, lowo lọwọ, ati ifọwọ si gbogbo ẹgbẹ, la n lo."

O ni ọna ti ẹgbẹ naa yoo fi yọ Naijiria kuro ni inu wahala ti ẹgbẹ oṣelu APC ju u si, lo n bi gbogbo igbesẹ ti awọn n gbe lati yan ẹni ti yoo dije fun ipo aarẹ.

Ọjọru ni awọn alaṣẹ ẹgbẹ PDP kede pe awọn ko ni lo ilana 'zoning' lati yan oludije sipo aarẹ.

Ipade igbimọ to ga julọ lẹgbẹ oṣelu PDP

Oríṣun àwòrán, Pdp/ twitter

PDP ṣílẹ̀kùn ìdíje fún ipò ààrẹ gbayawu, Ó ní ẹnikẹ́ni tó bá nífẹ́ síi lè díje

Ẹgbẹ oṣelu PDP ni Naijiria ti wọgile lilo eto jẹ ki n jẹ lati fi yan oludije fun ipo aarẹ labẹ aṣia rẹ ju danu.

Igbimọ iṣakoso to ga julọ lẹgbẹ oṣelu PDP gbe igbesẹ yii nibi ipade rẹ ẹlẹkẹrindinlọgọrun iru ẹ to waye ni olu ileeṣẹ ẹgbẹ oṣelu naa ni ojule Wadata Plaza nilu Abuja; lẹyin to ṣe agbeyẹwo abajade igbimọ ti wọn gbe kalẹ lori ọrọ eto jẹ ki n jẹ lẹgbẹ oṣelu naa.

Gẹgẹ bi alaye ti alukoro apapọ ẹgbẹ oṣelu PDP, Debọ Ologunagba ṣe, igbimọ alakoso to ga julọ ti fọwọ si ṣiṣi ilẹkun idije fun ipo aarẹ lẹgbẹ oṣelu naa silẹ gbaragada.

Bakan naa lo tun ọ ọ siwaju pe ẹgbẹ oṣelu naa n sa ipa lati rii pe oludije alafẹnuko, ti oyinbo n pe ni "Consensus candidate" ni wọn yan dipo didibo.

O ni igbimọ akoso naa tun ti yan aarẹ tẹlẹ fun ile aṣofin agba Naijiria, Sẹnetọ David Mark lati jẹ alaga ipade itagbangba lati yan oludije ipo aarẹ wọn.

Àkọlé fídíò, Iyabo Anisulowo:Ẹ̀yin ọ̀dọ́ Nàìjíríà, ẹ má bínú, kò rọrùn fún ọ̀dọ́ láti dìde nínú ìṣèlú

Ki lawọn ohun ti igbimọ akoso to ga julọ ni PDP gbe yẹwo fi pinnu ?

"Igbimọ alakoso NEC gba amọran igbimọ ti wọn gbe kalẹ lori ilana jẹ ki n jẹ lẹgbẹ oṣelu naa wọle pe nitori ilana apapro kan ko ga jukan lọ, ki ẹgbẹ oṣelu naa o fọgbọn ṣe e lori ọrọ ilana jẹ ki n jẹ o ko ma baa fa wahala lẹyin o rẹyin."

Bakan naa ni wọn tun kede pe ọjọ kejidinlọgbọn ati ikọkandinlọgbọn oṣu karun un ọdun 2022 lawọn yoo ṣe eto ipade itagbangba apapọ wọn ati ipade lati yan oludije fun ipo aarẹ nilu Abuja.

Àkọlé fídíò, Ó yẹ kí a wádìí ikú tó pa Oba Lamidi Adeyemi, Baba gbọ́dọ̀ padà- Sat Guru Maharaj-ji

Awọn agbofinro gbọdọ gbe Emefiele lọ sile ẹjọ - PDP

Amọṣa ẹgbẹ oṣelu PDP ko ṣai tun tẹnumọ ipe to ti kọkọ pe lopin ṣẹ to kọja pe ki awọn agbofinro fi panpẹ ofin gbe gomina banki apapọ Naijiria, Godwin Emefiele ti wọn ni o gba iwe ati dije fun ipo aarẹ lẹgbẹ oṣelu APC lai jẹpe o kọwe fi ipo rẹ silẹ.

Àkọlé fídíò, Osun spider man: Mo ń ṣe ìtanijí láti gbógunti ìdọ̀tí láwùjọ ló sún mi dé ìdí 'Spider man'

Ẹgbẹ oṣelu PDP ni nṣe ni Emefiele fi juujuu bo orilẹede Naijiria loju ko da wọn fi ẹsun ṣiṣe owo ilu baṣubaṣu kan pe o lọwọ ninu bi eto ọrọ aje Naijiria ṣe dẹnukọlẹ.

Alukoro ẹgbẹ oṣelu PDP, Debọ Ologunagba ṣalaye siwaju sii pe igbimọ akoso to ga julọ ni ẹgbẹ oṣelu PDP "tako bi gomina banki apapọ Naijiria, Gọdwin Emefiele ṣi ṣe wa nipo lẹyin to ti gba kaadi gẹgẹbi ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC."

Àkọlé fídíò, Basorun Akinade Ayoola Yusuf: Ìsìnkú Aláàfin Oyo àti Ooni Ile Ife yàtọ̀ nílẹ̀ Oodua

Wọn ni gẹgẹ bi alabojuto gbogbo awọn ohun elo ẹlẹgẹ ti ajọ INEC fi n ṣeto idibo rẹ gbogbo, to si tun ti wa fidimulẹ pe ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC ni bayii, Ọgbẹni Emefiele ko ṣee fi ọkan tan mọ lati wa ni iṣakoso awọn ohun elo idibo ẹlẹgẹ naa nitori ati lee ṣeto idibo ti ko lẹjambakan ninu rara mọ.

Àkọlé fídíò, Babalawo, Ọ̀pẹ̀lẹ̀ ni wọ́n fi ń yan Ọba fún wa, kí ló dé tẹ́ẹ fẹ́ wo owó yan Soun fún wa? - Ọmọ ìdílé òyè l'Ogbomoso