Muhammadu Buhari yóò gbé ìjọba kalẹ̀ lẹ́yìn sáà rẹ̀ lọ́dùn tó ń bọ̀ - Ijọba Àpapọ̀

Oríṣun àwòrán, @Presidency
Buhari kò ní fi oṣù mẹ́fà kún ìjọba rẹ̀ bí àwọn kan ṣe ń bèrè - Ìjọba àpapọ̀̀̀
Ijọba apapọ ti sọ pe Aarẹ Muhammadu Buhari ko ni lo kọja iye ọdun to yẹ ko lo lori oye, bẹẹ ni yoo gbe ijọba silẹ lẹyin saa rẹ loṣu karun un ọdun 2023.
Ṣaaju ni awọn agbẹjọro agba meji ni Naijiria, Aare Afe Babalola ati Robert Clarke ti kọkọ sọ pe o ṣeeṣe ki Buhari ma gbe ijọba silẹ lọdun to n bọ, amọ o le ṣagbekalẹ ijọba fidihẹ ti nnkan ko ba ṣenu ire ni ẹka eto aabo.
- Báwo ni ọ̀rọ̀ ilé ṣe fa Gbas-gbos láàrín Mercy Aigbe, ìyáále rẹ̀ àti ọkọ rẹ̀?
- Wo àwọn tó ra fọ́ọ̀mù ipò Ààrẹ ẹgbẹ́ òṣèlú APC
- Human Rights Watch fẹ̀sùn àìbìkítà kan ìjọba Naijiria lẹ́yìn ikú awọn olùwọ́de lásìkò ìwọ́de EndSARS
- Ṣé lóòtọ́ ni Jonathan ti gbẹ̀yìn darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ APC? Nkan tí PDP àti APC sọ rèé
- Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ Uche Igwe di èrò iléẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pínpín fídíò ìbálòpọ̀ ọmọdé
- Kò sí akẹ́kọ̀ọ́ ìpínlẹ̀ Sokoto, Zamfara tí yóò ṣe ìdánwò WASSCE lọ́dún 2022
- Kọ́ńdọ̀ọ̀mù méjìlá lá rí ní iyàrá ilé ìtura tí wọ́n ti fípa bá arábìnrin Ulochi lòpọ̀- Olọ́pàá
Clark sọ pe iwe ofin Naijiria faye gba Buhari lati fi kun akoko rẹ lori oye lọna ati le mu alaafia ba ilu.
Afe Babalola sọ pe o yẹ ki ijọba apapọ gbe ijọba fidihẹ kalẹ, ko si sun eto idibo ọdun 2023 siwaju lọna ati le kọ iwe ofin tuntun, amọ ọpọ araalu ni ko faramọ aba naa.
Erongba ijọba apapọ lori aba naa
Ninu atẹjade kan ti agbẹnusọ Buhari, Mallam Garba Shehu fi lede, o ni Aarẹ Muhammadu Buhari ko nilo lati ṣafikun ijọba rẹ pẹlu oṣu mẹfa ko to le yanju iṣoro to n koju eto abo Naijria.
- Èmi ò gbé'ṣẹ́ rán ẹnikẹ́ni láti ra fọ́ọ̀mù ìdíje ààrẹ fún mi o, ẹ máà kóbá mi -Ààrẹ tẹ́lẹ̀ Goodluck Jonathan fún Miyetti Allah lésì
- Wo àwọn òjé tí àwọn olóṣèlú máa fi ń jẹ àwọn ènìyàn bí ètò ìdìbò bá ti ń súnmọ́lé
- Ìpapòda Aláàfin kò ní dá ètò ìfinijoyè Gbajabiamila dúró- Ọyọmesi
- Ó pé ọdún 35 tí Obafemi Awolowo kú, wo àwọn nkan mánigbàgbé tí o kò gbọ́ rí nípa rẹ̀
- Ìdí mẹ́ta tí Goodluck Jonathan kò fi lè díje dupò lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú kankan lásìkò yìí
- Wo ìdí tí Ilé aṣòfin àpàpọ̀ Nàìjíríà ṣe yí òfin ìdìbò padà fún ààrẹ, gómìnà, àwọn aṣòfin àtàwọn míràn
Garba Shehu tun kọ aba awọn agbẹjọro agba naa pe ki Buhari fa ijọba le ijọba fidihẹ lọwọ.
O ni ti ijọba Buhari ba ṣe bẹẹ, yoo tẹ ẹtọ awọn ọmọ Naijiria lati dibo yan ẹni to wu wọn sori oye loju mọlẹ.
Kini Garba Shehu tun sọ?
Gẹgẹ bii atẹjade naa ṣe sọ, ijọba Buhari n ṣiṣẹ takun-takun, o si ti n ṣe aṣeyọri ninu igbiyanju rẹ lati mu alafia pada si Naijiria, eyii to gbagbọ pe yoo yanju ko ti di oṣu Karun un ọdun to n bọ to yẹ ko gbe ijọba kalẹ.
O ni "Oloye Roberk Clerk jẹ ẹni iyi lawujọ, o si le ni erongba rere nipa ọrọ to sọ pe ki Buhari ṣe afikun ijọba rẹ pẹlu oṣu mẹfa, amọ a fẹ jẹ ko ye gbogbo ọmọ Naijiria pe Aarẹ Buhari yoo gbe ijọba kalẹ lọjọ kọkandinlọgbọn, oṣu Karun un, ọdun 2023 gẹgẹ bii alakalẹ ofin."
"Niwọn igba to jẹ pe Buhari ni oloṣelu akọkọ ti yoo gba ijọba lọwọ oloṣelu ẹgbẹ rẹ ninu ẹgbẹ alatako, ko ni fi ẹtọ araalu du wọn."
Awọn ẹgbẹ oṣelu n fẹ ki INEC sun gbedeke eto idibo abẹle siwaju:
Ẹwẹ, awọn ẹgbẹ oṣelu kan ti ke si ajọ eleto idibo, INEC, pe ko sun gbedeke ọjọ kẹta, oṣu Kẹfa siwaju gẹgẹ bii ọjọ ti awọn ẹgbẹ oṣelu gbọdọ pari eto idibo abẹle wọn, ki wọn si fi orukọ awọn to n dije du ipo ti wọn yan sọwọ.
Amọ INEC ti sọ ṣaaju ninu atẹjade kan pe oun ko ni sun gbedeke naa siwaju fun awọn idi kan ti oun ko le yẹ.

















