Secret Cult in Ogun: Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá fojú afurasí ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn hàn ní Ijebu Ode

Oríṣun àwòrán, Facebook/Nigeria Police
Ileesẹ ọlọpaa ipinlẹ Ogun ti safihan awọn afurasi ọmọ ẹlẹgbẹ okunkun mọkanla, ti wọn lo gbẹmi awọn araalu mẹẹdọgbọn nilu Ijebu Ode nikan ati agbegbe rẹ.
Kọmisana ọlọpa nipinlẹ Ogun, Edward Ajogun lo sisọ loju isẹlẹ yii lasiko to n safihan awọn afurasi ọdaran naa nibi ipadepẹlu awọn alẹnulọrọ lori eto aabo lẹkun ileesẹ ọlọpaa to wa nilu Ijebu Ode.
- Ohun tí o kò mọ̀ nípa Ebila "One Million Boys" àti Ekugbemi, olórí ẹgbẹ́ òkùnkùn méjì tó da ìlú Ibadan rú
- Ẹgbẹ́ òkùnkùn yìnbọn lu ọmọ kan ní ikùn lásìkò ìdárò akẹẹgbẹ́ wọn
- Àwọn agbófinró ti mú Eji tó jẹ́ igbákejì Ebila, olórí ẹgbẹ́ òkùnkùn "One Million Boys" sí gbaga
- Ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn ṣoro ní Ijebu Ode, ọ̀pọ̀ ẹ̀mí sọnù
- "Òògùn ni wọ́n fi bò mí lójú tí mo fi bá ara mi láàrin àwọn ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn"
- Ayẹyẹ ìgbaniwọlé sínú ẹgbẹ́ òkùnkùn bẹ́yìn yọ, wọ́n lu ọmọ ẹgbẹ́ tuntun pa
- Ọwọ́ tẹ 'pásítọ̀' tó ń ṣe ẹgbẹ́ òkùnkùn ní Bàrígà
- Ẹ̀yin ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn tẹ fẹ́ ṣe àjọ̀dún lónìí, lákọ la ń dúró dè yín - Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá
Ajogun ni ileesẹ ọlọpaa yoo tẹsẹ bọ sokoto kannaa pẹlu awọn ẹlẹgbẹ okunkun, to si ni awọn ti wọn se afihan wọn yii pẹlu awọn mii to si ti na papa bora, lo lọwọ ninu pipa awọn eeyan mẹẹdọgbọn naa.
O wa n kọminu lori ija ojoojumọ to n waye nilu Ijebu Ode ati agbegbe rẹ lori ija agba laarin awọn ẹlẹgbẹ okunkun, to si fọwọ gbaya pe, ileesẹ ọlọpaa yoo kọju oro si wọn.
Bakan naa lo fikun pe ọwọ sinku ọlọpaa ti ba eeyan mẹrindinlogun, ti wọn si ba awọn ohun ija oloro lọwọ wọn.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ẹ̀yin adarí Nàíjíríà, ẹ dẹ́kun àwáwí asán lórí ètò ààbò tó mẹ́hẹ - Ààrẹ àṣòfin àgbà
- Ẹ dákẹ́ àhesọ ọ̀rọ̀, ohun tó pa ẹ̀gbọ́n àti àbúrò Orisabunmi rèé - Mọ̀lẹ́bí gbarata
- Wo àdánù tó wà nínú gbígba ayédèrú áápù fún ìforúkọsílẹ̀ NIN lórí ayélujára
- Àmúlò ẹ̀rọ POS fun òwò ṣíṣe, ṣé ó tọ̀nà nínú Islam àbí bẹ́ẹ̀ kọ́?
- Ìjọba ń ṣapá rẹ̀ lórí ìdènà Covid-19 àmọ́ àwọn awakọ̀ Eko ya aláìgbọràn - Ìjọba
- "Ẹ̀yin tẹ̀ ń parọ́ ẹlẹ́yà-mẹ̀yà mọ́ Amotekun Oyo, Seyi Makinde lẹ̀ ń dojú ìjà kọ"
- Kí ló ma n fa Àkúfà nílẹ̀ Yorùbá, àti ọ̀nà àbáyọ?
Ksmisana ọlọpa fikun pe wọn ti gbe awọn afurasi ọhun lọ sile ẹjọ lori ẹsun ipaniyan, idigunjale ati sise ẹgbẹ okunkun.
Afurasí agbébọn 47 bọ́ sọ́wọ̀ ikọ̀ 'Operation Burst' l'Oyo

Oríṣun àwòrán, Facebook/Nigeria Police Force
Afurasi agbebọn mẹtadinlaadọta ni ọwọ sinkun ikọ digboluja Operation Burst ti tẹ nilu Igangan, nipinlẹ Oyo.
Agbarijọpọ awọn ọlọpaa, ọmọ ogun ni wọn jijọ sisẹ naa, ti wọn si ri awọn nkan ija oloro gba lọwọ awọn afunrasi yii.
Owurọ kutu ọjọ Aiku ni operation Burst ri wọn mu lẹ́gbẹ odo Ofiki loju ọna Tapa /Igangan ni ijọba ibilẹ ariwa Ibarapa nipinlẹ Oyo.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Iye àwọn tó ń ní Covid-19 ti ń pọ̀ ju ilé ìwòsàn lọ, tó bá yá ọwọ́ wa ò ní ka mọ́ - NCDC
- Kí ló ma n fa Àkúfà nílẹ̀ Yorùbá, àti ọ̀nà àbáyọ?
- À ó ṣe àtúngbéyẹ̀wò àsìkò ìwọ́le àwọn akẹ̀kọ̀ọ́-Ìjọba apapọ̀
- Báwo ni #stingymenassociation ṣe gba ojú òpó twitter kan?
- Àfàìmọ̀ ká máa dá ìforúkọsílẹ NIN dúró tórí ewu coronavirus- Mamora
- Pásítọ̀ Adeboye kéde ààwẹ̀ ọjọ́ 63 fọ́mọ ìjọ rẹ̀, ariwo sọ lórí ayélujára
Iroyin kan ti ko fidi mulẹ lo ni awọn agbegbọn naa n korajọpọ lati gbẹsan ikọlu to waye si wọn lati ọwọ ikọ Amotẹkun lagbegbe naa lọjọ Abamẹta to kọja.
Iroyin naa ni ibi ti wọn pejọ si naa ni ikọ Operation Burst ti hu gbọ nipa rẹ, to si ko gbogbo awọn agbegbọn ọhun si ahamọ.

Oríṣun àwòrán, Oyo State Government
Amọtẹkun, ninu ọrọ rẹ ni oun ati awọn fijilate Miyetti Allah, awọn ọlọdẹ pẹlu awọn awọn mii, ni wọn dijọ se ikọlu naa eyi to wa lati mu awọn agbegbọn to n dunkooko mọ alaafia ilu.
Olugbenga Fadeyi, tii se agbẹnusọ fun ileesẹ ọlọpaa ipinlẹ Oyo fidi ọrọ yii mulẹ, to si ni awọn ti ko awọn afurasi agbebọn naa lọ si ileesẹ ọtẹlẹmuye ọlọpaa to wa ni Iyaganku fun iwadii to munadoko.
O ni ''A n tẹsiwaju pẹlu iwadii wa bo tilẹ jẹ pe awọn agbegbọn naa ni awọn n tọ pinpin awọn ajinigbe kan to fẹ gba owo lọwọ mọlẹbi eeyan ti wọn ji gbe ni''
Amọ sa, oludari awọn ọmọ ẹgbẹ OPC ni ipinlẹ Oyo, Rotimi Oluomo sọ fun ileesẹ Punch pe awọn afurasi yi gan lo ji eeyan gbe, ti awọn OPC to pẹlu Operation Burst si jẹri si ọrọ yi.
Bakan naa ni oludari OPC ni agbegbe Ibarapa sọ pe inu ọkọ bọọsi mẹta ni wọn ti mu awọn afurasi naa to digun mọra.
"Afurasi ti Àmọ̀tẹ́kùn bá lu lálù bẹ́, ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá ò ni gbàá sátìmọ́lé"

Oríṣun àwòrán, Ondo
Saaju la ti sọ fun yin pe, ní òwúrọ̀ ojó Ajé ni adarí ikọ̀ Àmọ̀tẹ́kùn ẹka Ibadan North, Oyinwola Simeon ti sàlàyé pé, ilé iṣẹ ọlọpàá méjì kọ̀ láti gba àwọn ọdaran ti àwọn mú si agọ́ wọ́n.
Nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ lo ti sàlàyé pé, ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá kọ̀ láti fi àwọn ọ̀daran méjì tí àwọn mú, ti wọ́n si ka ǹkan ìjà mọ́ lọ́wọ́ lọ́jọ́ Sátidé mọ́lé.
Nínú ìfọ̀rọ̀wanilẹnuwò pẹ̀lú oníròyìn ni ọ̀gbẹ́ni Simeon ti fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé, àgọ́ ọlọ́pàá Iyaganku àti Mọkola ni wọ́n kó àwọn ọdaran náà lọ, ti wọn sì kọ̀ láti gbà wọ́n si atimole.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Kí ló ma n fa Àkúfà nílẹ̀ Yorùbá, àti ọ̀nà àbáyọ?
- Pásítọ̀ Adeboye kéde ààwẹ̀ ọjọ́ 63 fọ́mọ ìjọ rẹ̀, ariwo sọ lórí ayélujára
- Ìgbákejì ààrẹ, tètè yọ Trump nípò, bí bẹ́ẹ̀ kọ́... Ilé aṣòfin Amẹ́ríkà yarí
- Ìwádìí BBC rèé lórí ìjà APC tó fẹ́ gbẹ̀mí Sẹ́nátọ̀ l‘Osun
- Ìlú tuntun tó kún fún ohun àdáyébá láìsí ọkọ̀ tàbí òpópónà ń bọ̀ ní Saudi Arabia
- Mo ti gba ọmọ Igbo tó ń wá bàbá rẹ̀ bí ọmọ, kó má ba à pa ara rẹ̀ - Iba Oluyole
- Lẹ́yìn ọgọ́rùn ún ọjọ́ tí wọn ti Lekki Toll Gate pa, ẹ wo owó gọbọi tíjọba Eko ń pàdánù
- Ẹ́ ràgà bo ìṣọ̀kan Nàíjíríà, ìyàpà le mú ìṣẹ́ àwọn akọni wa já sásán - Osinbajo
Ó ní wọ́n sàlàyé pé àwáwí tí wọ́n ń sọ ni pé, kò si ọgá kankan nitòsí láti mójú tó ọ̀rọ̀ náà.

Oríṣun àwòrán, Amotekun
" A mú àwọn olè méjì ní ọjọ́ Àbámẹ́ta, ní ǹkan bi aago méjì lágbègbè Inálende nílùú Ibadan, lẹ́yìn àyẹ̀wò, a ri ìbọn ibílẹ̀ gba lọwọ wọn.
Wọn sì jẹ́wọ́ pé àwọn jí ǹkan tí a bá lára wọn ni, àti pé àwọn máa n jalè lágbègbè Iwo Road, Inalende ati gbogbo agbegbe rẹ̀.
Àwọn ǹkan ti a rí lára wọn ni aago ọwọ́, ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ ìgbàlóde àti àwọn ǹkan míran."
Gẹ́gẹ́ bi alákoso náà ṣe sọ, ní kété ti wọ́n mú wọ́n tan ti wọ́n sì fọ̀rọ̀ wá wọ́n lẹ́nu wò, ni wọn mórílé àgọ́ ọlọpàá Mokọla sùgbọ́n ti àwọn ọlọ́pàá tó wà níbẹ̀ kọ̀ láti gbà wọ́n.

Oríṣun àwòrán, Oyo Affair
O ni awọn ọlọpaa naa ni kò sí DPO nílé, wọn sì ni kí wọ́n maa lọ si àgọ́ ọlọ́pàá Iyaganku.
" Bákan náà ni ńkan ti wọ́n sọ níbẹ̀, "kò sí ọgá kankan nílé, gbogbo wọn lo ti rìnrìn àjò, a ò sì le gba ẹnikẹni sí inú ọgbà wa"
Ẹ̀wẹ̀, ìwádìí BBC lọ́wọ́ agbẹnusọ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Oyo Olugbenga Fadeyi lórí ọ̀rọ̀ náà ló ti sàlàyé pé, ó jọ bi ẹni pé, ikọ̀ Àmọ̀tẹ́kun fẹ́ràn láti máa fi àwọn oníròyin bá ọlọ́pàá jà.
Fadeyi sàlàyé pé, alábaṣiṣẹ́ pọ̀ lóyẹ ki ikọ̀ Àmọ̀tẹ́kùn àti ọlọ́pàá jẹ́, nítorí náà, kò sí ìdí tí ọlọ́pàá yóò fi ṣe ẹsun ti wọ́n fi kan wọ́n.
Ó sàlàyé pé òun yóò túbọ̀ sàlàyé lórí ọ̀rọ̀ náà ti ìwádìí bá parí, sùgbọ́n ó fi kun pé, "àwọn Àmọ̀tẹ́kùn ń lo ìbọ̀n, kò si ni bójú mu ki wọ́n ti ṣe ọdaran léṣe tan, kí wọn wá gbé e wá si agọ́ ọlọ́pàá, kí ọ̀daràn lọ ku síbẹ̀"
Fadeyi ni "wọn kò lé gbé ọdaran tí wọ́n ti ṣe léṣé, tí o sì ti ku ẹ̀mí kan lẹ́nu rẹ̀ wá sí àgọ́ ọlọ́pàá, ọlọ́pàá ko ni gbà a, àwọn lo mọ bí wọ́n ṣe mú wọ́n, ta ló fẹjọ́ sùn wọ́n, ọlọ́pàá kìí ṣe iṣẹ́ wọn bẹ́ẹ̀"




















