Online Banking: Wo awuyewuye tó súyọ lórí ìhà tí ẹ̀sìn Islam kọ sí lílo POS fun òwò ṣíṣe?

Oríṣun àwòrán, Google
Lilo ẹrọ POS fun owo ṣiṣe ni Naijiria, yala nipa fifi owo ranṣẹ tabi gbigba owo, ti da ọpọlọpọ awuyewuye silẹ laarin awọn Musulumi kan ni Naijiria.
Bi awọn kan ṣe n sọ pe Haramu ni ki ẹni to ni ẹrọ POS naa maa gba ele owo lọwọ awọn onibara rẹ, nitori ẹsin Islam kii ṣe ẹsin to maa n ni eeyan lara.
Amọ awọn eeyan miran n sọ pe ko si ohun to buru nibẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ẹ dákẹ́ àhesọ ọ̀rọ̀, ohun tó pa ẹ̀gbọ́n àti àbúrò Orisabunmi rèé - Mọ̀lẹ́bí gbarata
- Ìjọba ń ṣapá rẹ̀ lórí ìdènà Covid-19 àmọ́ àwọn awakọ̀ Eko ya aláìgbọràn - Ìjọba
- N kò jà fún ìṣọ̀kan Yorùbá láti wá ipò tàbí orúkọ - Sunday Igboho
- "Ẹ̀yin tẹ̀ ń parọ́ ẹlẹ́yà-mẹ̀yà mọ́ Amotekun Oyo, Seyi Makinde lẹ̀ ń dojú ìjà kọ"
- Afurasí agbébọn 47 bọ́ sọ́wọ̀ ikọ̀ ‘Operation Burst’ l‘Oyo
- Iye àwọn tó ń ní Covid-19 ti ń pọ̀ ju ilé ìwòsàn lọ, tó bá yá ọwọ́ wa ò ní ka mọ́ - NCDC
- Kí ló ma n fa Àkúfà nílẹ̀ Yorùbá, àti ọ̀nà àbáyọ?
- À ó ṣe àtúngbéyẹ̀wò àsìkò ìwọ́le àwọn akẹ̀kọ̀ọ́-Ìjọba apapọ̀
- Báwo ni #stingymenassociation ṣe gba ojú òpó twitter kan?
Ariyanjiyan yii lo waye lẹyin iwaasu ti onimọ nipa ẹsin Islam kan ṣe ni ipinlẹ Adamawa, iyẹn Sheikh Abubakar Muktar se lori amulo ẹrọ POS.

Oríṣun àwòrán, Malamai
Sheikh Abubakar sọ pe, ko ba ofin ẹsin Musulumi mu ki awọn oniṣowo POS maa gba ele owo lori iye owo ti wọn ba fi ranṣẹ, tabi san fun onibara wọn lati fi jere.
Bo tilẹ jẹ pe o ni kii ṣe ẹṣẹ ki awọn onile itaja igbalode lo ẹrọ POS, ti ọrọ naa si da fakinfa silẹ lori ayelujara.
Idi ree ti BBC ṣe kan si awọn onimọ ijinlẹ nipa ẹsin Islam, lati mọ ni pato ohun ti ẹsin naa sọ nipa lilo POS.

Oríṣun àwòrán, Google
Agba onimọ kan, Sheikh Aminu Daurawa sọ pe lilo POS jẹ idokowo lọna to ba ofin mu, nitori naa ko si ohun to buru ninu ki eeyan jere lori owo to ba n ṣe.
O ni "ti eeyan ba fẹ lọ gba owo nile ifowopamọ, yoo na owo ko to de ibẹ, nitori naa ko buru ki eeyan san owo perete lati gba owo niwaju ile rẹ lọwọ onisowo ẹrọ POS nirọrun.
Ni ti Sheikh Bashir Aliyu Umar, to jẹ Imamu Mọṣalaṣi Al-Furqan, to tun jẹ onimọ ijinlẹ nipa ile ifowopamọ, o ni aṣiṣe nla ni ki eeyan tako lilo POS gẹgẹ bii Musulumi.
Sheikh Bashir sọ pe awọn oniṣowo POS jẹ aṣoju banki, nitori naa ko buru ti wọn ba n jere kekeke lori iṣẹ ti wọn n ṣe.
Nigba to n da si ọrọ naa, Sheikh Ibrahim Khali to jẹ olori ẹgbẹ awọn Musulumi ni Kano sọ pe, awọn oniṣowo POS dabi oṣiṣẹ ijọba to n gba owo oṣu ni.
O ṣalaye pe owo ti wọn n ja lori idunadura kọọkan jẹ ere wọn.
O ni "iṣoro ti a ni nilẹ yii ni pe irufẹ nnkan bayii ṣe ajoji si awọn eeyan wa, ṣugbọn ko si ohun to buru ninu ki oniṣowo POS gba owo lọwọ onibara rẹ fun iṣẹ to ṣe fun.
Sheikh Nuru Khalid, naa ṣọrọ, o ni ohun to dara ni POS jẹ nitori o mu aye dẹrun fun ọpọ eeyan, o si ti ṣe ọpọ awọn Musulumi ni anfani ti ko ṣe fẹnu sọ.



















