Coronavirus Update: Gomina Sanwo-Olu sún ọjọ́ "ṣiṣẹ́ láti ilé" síwájú fún àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba

Oríṣun àwòrán, Twitter/gbenga omotoso
Ijọba ipinlẹ Eko ti pàṣẹ fawọn oṣiṣẹ ìjọba ti wọn ko to ipele Kẹrinla lati tubọ maa ṣiṣẹ lati ile wọn lọnà ati dẹkùn itankalẹ aarun Covid-19.
Labẹ aṣẹ yi, ile ni gbogbo awọn ti ko ba to ipele yi yoo ti ma ṣiṣe di ọjọ kini oṣu Keji ọdun 2021.
Atẹjade ti olori awọn oṣiṣẹ nipinlẹ Eko Hakeem Muri Okunnu fi sita salaye pe aṣẹ igbele yi ko kan awọn ti o n ṣiṣẹ to se pataki.
- Ìyàwó mi fi mí sílẹ̀ kó lọ sílé ọkùnrin míì nínú báráàkì kan náà, àmọ́ mò sí tún fẹ́ràn rẹ̀- Sọ́jà
- Wo àwọn ìṣesí ojoojúmọ́ mẹ́wàá tó le ṣàkóbá fún ọpọlọ rẹ
- Ààrẹ àná, Goodluck Jonathan ló fún mi ní 'oògùn' tí mo fi yọ Sanusi nípò Emir Kano- Ganduje
- Ẹ̀wọ̀n ọdún méje ni fún ẹni tó bá gba owó lọ́wọ́ rẹ̀ fún NIN - NIMC
- Ọdún Kérésì di kọ̀ọ̀ l‘Eko, ìjọba dènà Kánífà òpin ọdún, ayẹyẹ ṣíṣe àti òde fàájì
"Gomina Babajide Sanwo-Olu ti buwọlu afikun ọjọ t'awọn oṣiṣẹ ìjọba Eko yoo fi ṣe iṣẹ lati ile fawọn ti ko to ipele Kẹrinla"
"Gomina wa rọ awọn oṣiṣẹ lat da aaboo bo ara wọn nipa bíbọwọ fún ilana idaabobo ti ijọba gbe kalẹ"
Muri-Okunola tun tẹsiwaju pe ki wọn máa tẹlé àtẹ eto iṣẹ tó wà nilẹ ki gbogbo nkan baa le máa lọ ní irọwọrọsẹ lawọn ileesẹ ìjọba nipinlẹ ọhun.
Ìpínlẹ̀ Oyo, Eko àti Ogun fọnmú lórí ìlànà pínpín abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19
Ìpínlẹ̀ Eko, Oyo àti Ogun ní abẹ́rẹ́ covid-19 tí yóò kàn wọ́n kéré, wọ́n fẹ́ ra ti wọn.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Covid-19 vaccine: Ìjọba Oyo, Eko fẹ́ ra abẹ́rẹ́ àjẹsára fún aráàlú
Ijọba ipinlẹ Eko, Ogun ati Oyo wa lara awọn ipinlẹ to bu ẹnu ẹtẹ lu bi ijọba apapọ ṣe pin abẹrẹ ajẹsara Covid-19 fawọn ipinlẹ ni Naijiria.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Irú ẹ̀dá wo ni Lamidi Adeyemi? Aláàfin tó rí ìbẹ̀rẹ̀ àti opin sáà gómìnà mọ́kànlélógún l‘Oyo
- Èèrà kò gbọdọ̀ rin Mattew Kukah ní Sokoto, ẹ má halẹ̀ mọ - Ìjọba àpapọ̀
- Seyi Makinde ní ọwọ́jà Covid-19 kò rinlẹ̀ bí NCDC se kéde èèyàn 120 tó ní àrùn lọ́jọ́ kan l‘Oyo
- Njẹ́ ẹ ti gbọ́ nípa àríyá oníhòhò àti ìbálòpọ̀ tó fẹ́ wáyé ní Kaduna lásìkò ọdún?
- Ìjọba gbé ilé ijó oníhòhò tì pa lórí ẹ̀sùn títàpá sí ìlànà àti dẹ́kun coronavirus
- Ilé aṣòfin Amẹ́ríkà yọ ààrẹ Donald Trump nípò fún ìgbà kejì
- Ìdí mẹ́fà rèé tí Instagram, Facebook le fi wọ́gilé ojú òpó ìkànsíraẹni rẹ
- Ìdí tí àwọn èèyàn kan kò fí le ni àrùn Coronavirus
Akọsilẹ ajọ NPHCDA to n ri eto abẹrẹ ajẹsara Covid-19 fi sita wa safihan bi yoo se pin abẹrẹ naa fawọn ijọba ipinlẹ.

Oríṣun àwòrán, Reuters
Ilana bi ijọba apapọ se pin abẹrẹajẹsara:
Kano - 3,557 , Lagos - 3,131, Katsina - 2,361, Kaduna - 2,074, Bauchi -1,900, Oyo - 1,848, Rivers - 1,766, Jigawa - 1,712, Niger - 1,558 , Ogun - 1,473.
Sokoto - 1,468, Benue - 1,423, Borno - 1,416, Anambra - 1,379, Kebbi - 1,268, Zamfara - 1,336, Delta - 1,306, Imo - 1,267, Ondo - 1,228, Akwa Ibom -1,161.
Adamawa - 1,129, Edo - 1,104, Plateau - 1,089, Enugu - 1,088; Osun - 1,032; Kogi - 1,030; Cross River - 1,023; Abia - 955; Gombe - 908; Yobe - 842; Ekiti - 830; Taraba - 830; Kwara - 815; Ebonyi - 747; Bayelsa - 589; FCT - 695, Nasarawa - 661.

Ki ni Gomina Seyi Makinde sọ nipa abẹrẹ naa:
Gomina Seyi Makinde ipinlẹ Oyo sọ pe abẹrẹ ti ijọba apapọ pin fun ipinlẹ Oyo ti kere ju.
Makinde ni ijọba yoo ra abẹrẹ naa fúnra rẹ, ki awọn eeyan ipinlẹ naa le jẹ anfaani abẹrẹ ọhun.
Ipinlẹ Eko iyalẹnu ni ilana pinpin abẹrẹ naa jẹ:
Bakanna, Kọmiṣọna feto iroyin ati aato ni ipinlẹ Eko, Gbenga Omotosho sọ pe, iyalẹnu ni bi ajọ NPHCDA ṣe pin abẹrẹ Coronavirus fawọn ipinlẹ jẹ.
Ọgbẹni Omotosho ni ko si adehun kankan laarin ijọba apapọ ati awọn ipinlẹ lori iye abẹrẹ ti yoo kan ipinlẹ kọọkan, ki ajọ NPHCDA to gbe nọmba ti yoo kan ipinlẹ kọọkan jade.
Kọmiṣọna ni ijọba ipinlẹ yoo ra abẹrẹ ajẹsara Covid-19 tirẹ fawọn eeyan ipinlẹ naa.
Amọ, o ni ipinlẹ Eko ko ní ṣalai gba eyi ti ijọba apapọ pin fun wọn.
Ipinlẹ Ogun ni ko ye oun bi ijọba se pin iye abẹrẹ to pin fun oun:
Ipinlẹ Ogun ni tiẹ sọ pe, ko gba ibikan ye oun bi ijọba ṣe pin iye abẹrẹ ti yoo kan ipinlẹ kọọkan.
Oludamọran fun Gomina ipinle Ogun lori eto iroyin, Ọgbẹni Remmy Hazzan lo kede bẹẹ.
Hazzan sọ pe ipinlẹ Eko, Ogun ati Olu ilu Naijiria Abuja ti ajakalẹ arun Covid-19 ti ṣọṣẹ julọ, ló yẹ kó lanfaani abẹrẹ ajẹsara Covid-19 ju awọn ipinlẹ to ku lọ.
"Ko tii ye wa nipinlẹ Ogun, idi ti a ko fi gba ju iye abẹrẹ perete ti ajọ NPHCDA pin kan wa lọ," Ọgbẹni Hazzan lo sọ bẹẹ.
Ẹgbẹ Dokita rọ ijọba lati kọkọ fun awọn osisẹ eleto ilera ni abẹrẹ naa:
Ẹwẹ, ẹgbẹ awọn dokita ni Naijiria, NMA ti rọ ijọba apapọ lati fun awọn oṣiṣẹ eleto ilera lanfaani ati kọkọ gba abẹrẹ ajẹsara Covid-19.
Aarẹ ẹgbẹ NMA, Ọjọgbọn Innocent Ujah ni, awọn oṣiṣẹ eleto ilera lo n foju wina ajakalẹ arun coronavirus julọ nitori awọn lo n tọju awọn to larun naa nile iwosan.
O fikun ọrọ rẹ pe, ko si ohun to buru níbẹ ti awọn oloṣelu ati awọn to ba ri ọwọ họri ba lọ gba abẹrẹ naa loke okun.

Oríṣun àwòrán, @didacus_dee
Kii ṣe iroyin tuntun pe itankalẹ arun Covid-19 ti bẹrẹ fun igbakeji ni Naijiria.
Ṣugbọn o seni laanu pe ọpọlọpọ araalu ni ko tẹle ilana idaboobo lọwọ arun naa, bo tilẹ jẹ pe lojoojumọ ni ijọba ati awọn alaṣẹ eto ilera n polongo pe ka tẹle ofin itakete sira ẹni.
Lara awọn akiyesi wa, paapaa nipinlẹ Eko ni pe, awọn ọkọ ero n ko ero kun inu ọkọ wọn lai bọwọ fun ilana arun Coronavirus.
Ṣaaju nigba ti arun naa kọkọ gbalẹ, ijọba paṣẹ fun awakọ ero lati din ero wọn ku, ki wọn o si ri daju pe awọn ero naa wọ ibomu.
Ṣugbọn lasiko yii, ko wọpọ lati ri awọn eero ọkọ to wọ ibomu, bẹẹ ni awọn awakọ naa n ko ọpọ ero laisi titakete sira ẹni.
Ta lo ni ẹbi iwa yii, ṣe ijọba ni tabi araalu tabi awọn ọlọkọ ero?
Lori eyi, Kọmisana fun eto iroyin nipinlẹ Eko, Ọgbẹni Gbenga Omotoso sọ fun BBC pe, gbogbo igba ni ijọba n kilọ fun awọn awakọ yii, to si tun n ba awọn olori wọn ṣe ipade loore-koore, nitori ki wọn o le maa tẹle ilana Covid-19.
O ni "Ọkọ meji ni ọwọ ti tẹ, ti ijọba si ti sọ fun awọn naa pe, o ṣe e ṣe ki wọn o padanu iwe irinna wọn gẹgẹ bi awakọ, ti wọn ba tun kọ lati tẹle ofin ijọba lori Coronavirus."

Oríṣun àwòrán, @adelajaniyi
O ni awọn awakọ naa lo kọ lati gbọran si aṣẹ ijọba.
O ṣalaye pe ko rọrun fun ijọba lati gbe igbesẹ to le lori ọrọ naa, nitori pe ọpọ eeyan lo tun n bu ijọba fun bi awọn agbofinro ṣe n ko awọn eeyan kan nile ijo.
"Awọn oṣiṣẹ ilu bi LASTMA ti ijọba n ran lati mu iru awọn awakọ bẹ ẹ, n fi ẹmi wọn wewu ni."
"O yẹ ki awọn araalu naa mọ pe ija yii kii ṣe tijọba nikan."
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- N kò jà fún ìṣọ̀kan Yorùbá láti wá ipò tàbí orúkọ - Sunday Igboho
- "Ẹ̀yin tẹ̀ ń parọ́ ẹlẹ́yà-mẹ̀yà mọ́ Amotekun Oyo, Seyi Makinde lẹ̀ ń dojú ìjà kọ"
- Afurasí agbébọn 47 bọ́ sọ́wọ̀ ikọ̀ ‘Operation Burst’ l‘Oyo
- Iye àwọn tó ń ní Covid-19 ti ń pọ̀ ju ilé ìwòsàn lọ, tó bá yá ọwọ́ wa ò ní ka mọ́ - NCDC
- Kí ló ma n fa Àkúfà nílẹ̀ Yorùbá, àti ọ̀nà àbáyọ?
- À ó ṣe àtúngbéyẹ̀wò àsìkò ìwọ́le àwọn akẹ̀kọ̀ọ́-Ìjọba apapọ̀
- Báwo ni #stingymenassociation ṣe gba ojú òpó twitter kan?





















