Ganduje: Gòmìna Ganduje ni yíyọ Sanusi nípò Emir Kano wà fún àtúnṣe ètò oyè jíjẹ ní ìlú Kano

Emir ana nilu Kano, Sanusi Lamido Sanusi

Oríṣun àwòrán, Twitter/Maigaskiya

Gomina ipinlẹ Kano, Ganduje ti sọ pe oun ko kabamọ bi oun ṣe rọ Emir ilu Kano tẹlẹ, Sanusi Lamido Sanusi loye.

O ni tẹlẹ gan an kii ṣe Sanusi lo tọ si ipo naa, awọn alagbara ijọba nigba naa lo kan fi iyansipo rẹ ṣe ọna ati fi la aarẹ igba naa, Goodluck Jonathan loju.

Gomina Ganduje to sọrọ nibi ifilọlẹ iwe kan nipa aarẹ ana, Goodluck Jonathan ṣalaye kikun nipa iṣẹlẹ naa.

O ni wi pe lasiko ti wọn yan Sanusi Lamido Sanusi gẹgẹ bii Emi ilu Kano loṣu kẹfa, ọdun 2020, lẹyin oṣu meji ti aarẹ Jonathan yọọ nipo gomina banki apapọ Naijiria, oun mọ pe kii ṣe igbesẹ to tọ nigba naa.

O ni nikete ti oun di gomina loun ti sọ ọ fun ara oun pe oogun ti Jonathan lo lori ọrọ Sanusi ṣe pataki pupọ.

Àkọlé fídíò, Kollington ṣàlàyé bí orin Fuji ṣe bẹ̀rẹ̀ gan an ní Nàiìjíríà

Ganduje ni aarẹ ana, Goodluck Jonathan gbe igbesẹ akin lati yọ Sanusi nipo gomina banki apapọ Naijiria nitootọ.

Àkọlé fídíò, Akomolede ati Aṣa: Mọ̀ síi nípa ìró afárànma àti agbárànmọ́ fáwẹ́ẹ̀lì Yorùbá

Bi o tilẹ jẹ pe o fa ẹtanu rẹ laarin awọn eeyan kan; sibẹ oun ri i gẹgẹ bi igbesẹ to tọ gẹgẹ bi oogun to yẹ ni lilo to dabi ọna abayọ lati wo wahala igba naa.

"Oogun naa, bi o tilẹ jẹ pe mi o kii ṣe dokita iṣegun oyinbo, oogun yii kan naa yoo wulo fun iṣẹ kan naa, arun kan naa ati fun eeyan kan naa.

Àkọlé fídíò, Ọgbà ẹ̀wọ̀n ni wọ́n ti já àbálé Esra lábẹ́ àwáwí àyẹ̀wò wúndíá

Ganduje ni: "Nitori naa mo gbe igbesẹ oogun ti Jonathan gbe lati doola ilana ati eto Ọba jijẹ ni Kano, mo si lo o daadaa.

Fun idi eyi. igun kan naa lemi ati aarẹ ana, Jonathan wa.

Àkọlé fídíò, Africa Eye: Wo ìtàn ìyá kan ìyá kan àtàwọn olè ajọ́mọgbé tó n ta ọmọ ní Kenya

Ẹ wo o, emi ko kabamọ rara nitori pe mo yọ Sanusi loye Emir ti Kano"

Lasiko iṣejọba Rabiu Kwankwaso gẹgẹ bii gomina ipinlẹ Kano ni wọn fi Sanusi Lamido Sanusi joye Ẹmir ilu Kano ṣugbọn ni ọjọ Kẹsan an oṣu kẹta ọdun 2020 ni wọn rọọ loye.