Ahmad Lawal: Ojúṣe olórí ni láti pèsè ààbò fáráàlú, kìí ṣe àwáwí

Oríṣun àwòrán, @Presidency
Aarẹ ile aṣofin agba niluu Abuja, Sẹnẹtọ Ahmad Lawan ti rọ awọn olori ni Naijiria pe, ki wọn ye ṣe awawi nipa ipenija ti wọn n doju kọ.
Sẹnẹtọ Lawan sọrọ yii nibi ayẹyẹ ranpẹ ọjọ ibi ọdun kejilelọgọta rẹ lọjọ Iṣẹgun niluu Abuja.
"Ojuṣe gbogbo awa olori ni lati wa nnkan se sí awọn ipenija to n dojuko kọ awọn ọmọ Naijiria," Lawan lo woye bẹẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ẹ dákẹ́ àhesọ ọ̀rọ̀, ohun tó pa ẹ̀gbọ́n àti àbúrò Orisabunmi rèé - Mọ̀lẹ́bí gbarata
- Wo àdánù tó wà nínú gbígba ayédèrú áápù fún ìforúkọsílẹ̀ NIN lórí ayélujára
- Àmúlò ẹ̀rọ POS fun òwò ṣíṣe, ṣé ó tọ̀nà nínú Islam àbí bẹ́ẹ̀ kọ́?
- Ìjọba ń ṣapá rẹ̀ lórí ìdènà Covid-19 àmọ́ àwọn awakọ̀ Eko ya aláìgbọràn - Ìjọba
- "Ẹ̀yin tẹ̀ ń parọ́ ẹlẹ́yà-mẹ̀yà mọ́ Amotekun Oyo, Seyi Makinde lẹ̀ ń dojú ìjà kọ"
- Kí ló ma n fa Àkúfà nílẹ̀ Yorùbá, àti ọ̀nà àbáyọ?
Amọ Sẹnẹtọ Lawan ni "kii ṣaaba rọrun nigba mii ṣugbọn awọn araalu maa n ro pe eremọde ni, ẹni to ba de ibẹ lo maa mọ pe ko rọrun."
Ṣugbọn aarẹ ile aṣofin agba ni ko gbọdọ si awawi kankan.

Oríṣun àwòrán, @HQNigerianarmy
Sẹnẹtọ Lawan sọ pe, oun ni igboya ninu ile igbimo aṣofin agba l'Abuja lati ṣe awọn ofin ti yoo wa ojutuu si iṣoro to n doju kọ orilẹede Naijiria.
Sẹnẹtọ Lawan ko ṣai gboṣuba fawọn aṣofin fun iṣọkan to wa laarin wọn bo tilẹ jẹ pe ọtọọtọ lẹgbẹ oṣelu wọn.
O kii wọn ku iṣẹ ribiribi ti wọn n ṣe nipa ṣiṣe ofin ti yoo mu ilọsiwaju ba Naijiria.
Gbogbo awọn sẹnẹtọ akẹgbẹ rẹ to wa nibi ayẹyẹ naa, lo ki aarẹ ile aṣofin agba ku oriire ọjọ ibi ọdun kejilelọgọta rẹ.
Ẹ́ ràgà bo ìṣọ̀kan Nàíjíríà, ìyàpà le mú ìṣẹ́ àwọn akọni wa já sásán - Osinbajo

Oríṣun àwòrán, @HQNigerianArmy
Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe igbakeji aarẹ, Yemi Osinbajo ti gba gbogbo ọmọ Naijiria nimọran lati mu isọkan orilẹede yii lọkunkundun nitori ninu irẹpọ ni Naijiria ti le lagbara si.
Osinbajo, ẹni to parọwa naa ni lai fi ti ẹya, ẹsin, ẹgbẹ oselu tabi iyapa miran se, ifẹ nikan lo le gbe Naijiria ro.
Igbakeji aarẹ parọwa bẹẹ nibi akanse isin alajumọse lati bẹrẹ ọsẹ iranti awọn ologun eyi to waye lọjọ Aiku nile ijọsin National Christian Centre, nilu Abuja.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Orí kó Sẹ́nátọ̀ Orilowo yọ lọ́wọ́ ikú lọ́jọ́ Àìkú
- Kí ló ń pa ẹbí Orisabunmi lọkọ́ọ̀kàn, àkúfà ni àbí àmúwá Ọlọ́run?
- August Agboola Brownie, ọmọ Yorùbá tí wọ́n n wárí fún ní Poland
- Enugu ni mo ti wa, mò ń wá bàbá mí n‘Ibadan, mà á pa ara mi tí ń kò bá ri- Vivian Omeh
- Àwọn olorì Aláàfin fi oríkì awúnilórí yẹ́ ọkọ wọn sí fún àádọ́ta ọdún tó gorí ìtẹ́
- Wo àwọn Ọ̀jọ̀gbọ́n fásitì tí àrùn Coronavirus gbẹ̀mí wọn
Osinbajo, ti akọwe ijọba, Boss Mustapha soju fun fikun pe gbogbo orilẹede to ba ni iyapa ẹya ati ẹsin lo maa n ja fitafita lati lati jere to wa ninu iyapa wọn.

Oríṣun àwòrán, @ProfOsinbajo
O wa rọ awọn ọmọ Naijiria lati fi ara wọn jin fun ifẹ ati isọkan orilẹede yii ati idagbasoke awujọ wa, lọna ati bu ọla fun awọn ologun to ti sun soju ija.
"Awọn akọni ologun to ti sun loju ija yii lo fi ẹmi wọn lelẹ fun isẹ idoola awọ nilẹ yi ati nibi gbogbo, iranti wọn si la jẹjẹ lati bọwọ fun ninu orin orilẹede wa to ni 'isẹ awọn akọni wa ko ni ja si asan.'
A seleri pe ẹjẹ wọn ti wọn ta silẹ ko ni ja si ofo, eyi si jẹ ajaga ti awọn alaaye gbọdọ maa ru kiri."

Oríṣun àwòrán, Facebook/Nigeria Airforce
Bakan naa ni Igbakeji Aarẹ tun kọrin re ki oloogbe Tolulope Arotile, ẹni to se ise akọni losu kẹwa ọdun 2019, nigba to di obinrin akọkọ ti yoo wa baalu ijagun ninu itan idasilẹ ẹka ologun ofurufu Naijiria.
"Bi o tilẹ jẹ pe wọn ge ẹmi rẹ kuru amọ o mu ala rẹ sẹ, eyi to wa lati daabo bo isọkan naijiria, alaafia rẹ ati ipese aabo to peye.
















