Secret Cults in Nigeria: Ìyá àti ọmọ tó wà nínú Márúwá bá ìjà ẹgbẹ́ òkùnkùn lọ

Ko din ni ogun eeyan to dagbere faye nigba ti ọpọ miran fi ara gbọgbẹ lorisirisi lasiko tawọn tawọn ẹgbẹ okunkun fija pẹẹta nilu Ijebu Ode.
Gẹgẹ bi iwe iroyin Punch ti sọ, ọsẹ meji sẹyin ni ija naa ti bẹrẹ, ti apapọ iye eeyan to si ti ba rin ti le ni ogun.
Iroyin naa ni ẹgbẹ okunkun Eiye ati Aiye ni wọn n doju ija kọ ara wọn, eyi to mu ki ohun gbogbo poluku musu lawọn agbegbe kan nilu naa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Àlàyé rèé lórí ìdí tí mo fi lọ sílé Tinubu - Rashidi Ladoja
- ‘Sim Card’ títà àti ìforúkọsílẹ̀ rẹ̀ dèèwọ̀ ní Nàíjíríà - NCC
- Ààrẹ Akufo-Addo la Mahama mọ́lẹ̀ wọlé ìbò ààrẹ Ghana fún sáà kejì
- Ẹ̀yin tí ẹ máa ń bú àwon tó sanra ni ẹ ń jẹ́ kí wọ́n ronú pa ara wọn - Eniola Badmus
- Ilé aṣòfin kò láṣẹ kankan láti pe ààrẹ Buhari wá rojọ́ lórí ọ̀rọ̀ ètò àbò - Malami
- Ṣé lóòtọ́ ni tírélà ti gba ààrín Ronke Odusanya àti bàbá ọmọ rẹ̀, Jago? Nkan tí a mọ̀ nìyíì
- Mo ti kúrò ní ààfin Oyo, kí ìròyìn tó ò jáde pé èmi àti Wasiu Ayinde n fẹ́ ara wa - Olori Badirat
Lara awọn adugbo ta gbọ pe ọrọ naa kan ni Gareeji Epe, Ejinrin Road, Adefisan, Gareeji Ibadan, Onirugba, Tatina ati oju ọna Benin si Ondo.
Koda wọn ni iya kan ati ọmọbinrin rẹ, ti wọn wa ninu kẹkẹ Maruwa ni ọta ibọn seesi ba, ti wọn si jẹ Ọlọrun nipe.

Ọpọ eeyan niroyin naa lo ku iku aimọdi lati ipasẹ wahala naa ni gareeji Epe, Road, Adefisan, Gareeji Ibadan, Onirugba, Tatina ati oju ọna Benin si Ondo.
Bẹẹ si ni ọpọ awọn eeyan lo n sa asala fun ẹmi wọn lasiko rogbodiyan awọn ọmọ ẹgbẹ okunkun naa.
Ọ̀rẹ́bìnrin míì dáná sí ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ lára lẹ́yìn tó kọ̀ láti fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí aya

Oríṣun àwòrán, verifiedNG
Lẹyin bi ọsẹ meji ti ọdọbinrin kan danu sun ile ọrẹkunrin rẹ nibi ti ina ti mu ololufẹ rẹ to wa nile, ọdọbinrin mii tun ti dana si ọrẹkunrin rẹ lara ni ijọba ibilẹ Gboko nipinlẹ Benue.
Iroyin ti a gbọ ni pe ọdọbinrin naa gbe igbesẹ yii lẹyin ti ololufẹ rẹ lati ṣe igbeyawo pẹlu rẹ.
Ohun tawọn to mọ nipa iṣẹlẹ naa sọ ni pe ọdọbinrin yii sọna si ile ololufẹ rẹ lẹyin ọkunrin naa ti orukọ rẹ n jẹ Jude atawọn ti sun tan.
- Kí làwọn nǹkan tó lè rán ọkùnrin sí ọ̀run alákeji lásìkò ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin?
- Wo bí o ṣe lè ṣe eré ìdárayá tí yóò fún ọ ní adùn àti okun fún ìbálòpọ̀
- Àjọ ọlọpàá Eko kédé pé ìbalòpọ̀ nítà kò bójúmu
- Lóòtọ́ ni ọkọ mi lù mí bí àṣọ òfì, àmọ́ gómìnà ti bá wa parí ẹ̀, ẹ máa gbàdúrà fún ìdílé mi- Dokita Ifeyinwa
- Mi ò kí n ṣe afẹfẹ-yẹ̀yẹ̀ lórí ayélujára nítorí pé mí ò ní dúkìá tí mó le fihàn- Ronke Oshodi-Oke
- Ìgbìmọ̀ aláṣẹ APC jáwe lọ gbéle rẹ fún ìgbákejì alága: Hilliard Eta!
Ni deedee aago kan aabọ oru ni a gbọ pe obinrin yii lọ ṣiṣẹ laabi ọhun.
Ṣugbọn ori ko awọn to wa ninu ile yọ bo tilẹ ina mu Jude eyi to mu ki ara rẹ bo yanayana.
Apa ina ko pọju lara mama rẹ ati aburo rẹ ọkunrin ti wọn jọ wa nile lasiko iṣẹlẹ naa.
Awọn mẹtẹẹta ti wa ni ile iwosan bayii nibi ti wọn ti n gba itọju fun ara wọn.
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Benue, DSP Catherine Anene fidi iṣẹlẹ naa mulẹ fawọn akọroyin.
Anene ṣalaye pe lootọọ nile iṣẹ ọlọpaa gba ipe pe ọdọbinrin kan tu epo si ile ọrẹkunrin rẹ ti o si tun fi ina sii.
Amọ agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa awọn ko tii ri ọdọbinrin naa mu.
- Kí làwọn nǹkan tó lè rán ọkùnrin sí ọ̀run alákeji lásìkò ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin?
- Arábìnrin lẹ̀dì àpò pọ̀ pẹ̀lú ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ pé kó ó jí òun gbe, ọ̀rẹ́kùnrin gba 700k tán ló bá sálọ
- Èsì ìdìbò tí yóò gbé aàrẹ tuntun wọlẹ́ ní Ghana rèé...
- Ìdí rèé táwọn àkàndá ẹ̀dá fi dí iwájú iléeṣẹ́ ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo pa l'Agodi n'Ibadan




















