Adejare Adeboye: Àwọn kan ní ṣé ọ̀nà láti gba owó oṣù àkọ́kọ́ lọ́wọ́ ọmọ ìjọ kọ́ ní ìkéde ààwẹ̀ ọlọ́jọ́ 63

Adejare Adeboye

Oríṣun àwòrán, @PastorEAAdeboye

Awọn eeyan lori ayelujara ti ko ẹnu bo Pasitọ igba fun ijọ Redeemed, RCCG, Olusọagutan Enoch Adeboye lori aawẹ ọlọjọ mẹtalelọgọta to kede .

Pasitọ Adeboye paṣẹ lọjọ Aiku, ọjọ kẹwaa oṣu kini ọdun 2021 pe ki gbogbo awọn ọmọ ijọ naa lagbaye gba awẹ ọjọ mẹtalelọgọta naa.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Gẹgẹbi iransẹ Ọlọrun naa ṣe sọ, ọpẹ ni ọjọ mọkanlelogun akọkọ ti wọn ba aawẹ naa yoo da le lori, ọjọ mọkanlelogun keji yoo da lori adura fun idile and bibeere fun aanu.

Pasitọ Adeboye ni ipele kẹta awẹ naa yoo wa lati gba adura fun ijọ, idile ati ara wọn.

Ikede ti Adeboye se lori ayelujara

Oríṣun àwòrán, @PastorEAAdeboye

Amọ ọpọ ọmọ Naijiria ko jẹ ki ikede naa balẹ loju opo Twitter, bi wọn ṣe n ka ikede naa, ni wọn n fesi loniruuru le lori.

Àkọlé fídíò, Nigeria Car Innovator: Olatunde Ibitoye ní ọdún mẹ́ta ní òun fi ṣe ọkọ̀ náà torí ọ̀dá owó

Fun awọn kan, bi eto oselu orilẹde Naijiria ṣe dagun lo mu ki ijọ maa kede awẹ ọlọjọ gbọọrọ bii eyi ti ijọ RCCG kede naa.

Ikede ti Adeboye se lori ayelujara

Oríṣun àwòrán, @PastorEAAdeboye

Bi o tilẹ jẹ pe awon kan dahun pe ṣaaju iṣejọba to wa lode bayii ni ijọ naa ti n seto awẹ ati adura ibẹrẹ ọdun.

Ikede ti Adeboye se lori ayelujara

Oríṣun àwòrán, @PastorEAAdeboye

Ẹwẹ, awọn kan naa n beere pe ṣe kii ṣe ara ọna ati maa gba owo osu akọkọ lọwọ awọn ọmọ ijọ ni wọn se kede aawẹ naa, gẹgẹ bi awọn ijọ kan ti maa nṣe.