Kidnapping: Àwọn ajínigbé jí àlùfáà ìjọ àti ọmọ rẹ̀ gbé, bèrè mílíọ̀nù mẹ́wàá náírà gẹ́gẹ́ bí owó ìtúsílẹ̀ ní ìpínlẹ̀ Ondo

Oríṣun àwòrán, Others
Ileeṣẹ ọlọpaa ni Ondo bẹrẹ iṣẹ lori alufaa ti wọn ji gbe nibẹ
Àwọn ajínigbé jí àlùfáà ìjọ gbé, bèrè mílíọ̀nù mẹ́wàá náírà owó ìtúsílẹ̀
Àlùfáà ìjọ kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olu Obanla ti kó sọ́wọ́ àwọn ajínigbé ní ìpínlẹ̀ Ondo.
Bayii ni ẹbi alufaa naa fi sita pe wọn ṣi n wa owo itanran naa nitori ko si agbara lati wa milionu mewaa naira ti ajinigbe n beere
- Ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn Aiye méjìdínlógún kò sí pámpẹ́ ọlópàá Ekiti lórí ikú èèyàn méjì
- Wo ohun tí iléeṣẹ́ ológun ṣe fun obìnrin yìí lẹ́yìn ọdún Mẹ́tàdínlọ́gọ́rin tí wọ́n gba àkàrà òyìnbó lọ́wọ́ rẹ̀
- Àwọn ọ̀dọ́ dáná sun ilé mẹ́fà, ṣọ́ọ́bù méje ní Bauchi nítórí obìnrin tí wọ́n ló bú Ànọ́bì lórí Whatsapp
- Manchester City gba adé Premier League ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì ti 2021/ 2022
- Ọlọ́pàá ìpínlẹ Ogun mú olùkọ́ tó fipá bá akẹ́kọ̀ọ́ ọmọ ọdún mẹ́sàn-án lòpọ̀
- Ìwà aṣemáṣe gbaṣẹ́ lọ́wọ́ dókítà àti nọ́ọ̀sì ní ìpínlẹ̀ Oyo
- Wo bí àwọn agbébọn ṣe pa Okechukwu Okoye, aṣòfin kan ní ìpínlẹ̀ Anambra tí wọ́n sì gé orí rẹ̀ sọnù
- Òkú mẹ́ta, alàyè márùn-ún lá ti yọ nínú ilé tó wó ní Lagos Island
- Fífẹ̀ ju ìyàwó kan lọ ni àṣírí ẹ̀mí gígùn'
Àlùfáà ọ̀hún ń ṣe ìrìnàjò kọjá ní òpópónà Ifon-Okeluse ní ìjọba ìbílẹ̀ Ose, ìpínlẹ̀ Ondo kí àwọn ajínigbé náà tó dá wọn lọ́nà.
Gẹ́gẹ́ bí ìròyìn ṣe sọ, àwọn ajínigbé náà wọ àlùfáà Obanla wọ inú igbó kan ní agbègbè náà.
Lẹ́yìn èyí ni wọ́n kàn sí àwọn ẹbí àlùfáà náà láti mú mílíọ̀nù mẹ́wàá náírà wá ká àwọn tó le tú àlùfáà sílẹ̀ .
Àwọn ẹbí Obanla ní mílíọ̀nù kan náírà ni àwọn ní ṣùgbọ́n àwọn ajínigbé náà kọ̀ jálẹ̀ wí pé àwọn kò ní gba mílíọ̀nù kan náírà.
Yàtọ̀ sí àlùfáà Obanla, àwọn ajínigbé náà tún jí ọmọ àlùfáà náà tí wọ́n jọ ń ṣe ìrìnàjò lọ sí Okeluse gbé.
Nígbà tó fìdí ìṣẹ̀lẹ̀ náà múlẹ̀, agbẹnusọ ọlọ́pàá ìpínlẹ̀ Ondo, Funmilayo Odunlami ní iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ti ń ṣiṣẹ́ láti gba àwọn ènìyàn náà kalẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ajínigbé.
Odunlami ní lóòótọ́ ni ọ̀rọ̀ náà ṣẹlẹ̀ àti pé ẹ̀ka tó ń mójútó ìṣẹ̀lẹ̀ ìjínigbé ti wà lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.

Oríṣun àwòrán, Screenshot
- "Ogun ló gbé mi lọ sí Central African Republic, àmọ́ ọmọ ni mo gbé bọ̀"
- Ta ló gbé òkú ènìyàn sí pápákọ̀ òfurufú Muritala Muhammed l'Ekoo? FAAN bẹ̀rẹ̀ ìwádìí
- Anthony Albanese di olóòtú ìjọba Australia, ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa rẹ̀ rèé
- Àwọn alákatakítí ẹ̀sìn dáná sun ilé mẹ́fà, ṣọ́ọ̀bù méje ní Bauchi lórí ẹ̀sùn sísọ̀rọ̀ òdì sí Islam
- Ìjọba Eko fún àwọn ọlọ́jà Alaba Rago ní gbèdéke láti fi ibẹ̀ sílẹ̀ fún àtúnṣe
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá nawọ́ gán afurasí mẹ́fà lórí ikú "Sound Engineer"

















