Mwila Chansa lọ ṣiṣẹ́ àlááfíà ní Central African Republic, ó gba ọmọ tọ́

Oríṣun àwòrán, Mwila Chansa
Ọgagun kan nileeṣẹ ọmọ ogun Zambia to jẹ obinrin, Mwila Chansa ti sọrọ lori ohun to la kọja ninu igbiyanju rẹ lati gba ọmọ kan tọ lasiko to lọ ṣisẹ alaafia labe aisa United Nations ni Central African Republic.
Iya ọmọ naa loyun ibeji, amọ o dagberere faye ni kete to bi ọmọ akọkọ tan, ti ọmọ keji si ku ko to bi ọmọ naa.
Ọgagun Chansa gbọ itan aye ọmọ jojolo naa nigba to ṣabẹwo si Birao, to wa ni ala ilẹ Chad ati Sudan.
Lẹyin naa lo pinnu lati gba ọmọ naa tọ, amọ o ṣoro fun nitori ofin ẹsin Musulumi to wa nilẹ naa.
- Wo ǹkan tó ń fa 'body odour' àti bí o ṣè lè ṣẹ́gun rẹ̀
- Àsìkò ti tó kí ìjọba fihàn pé kò sẹ́ni tó kọjá òfin lórí ikú Deborah- Ẹgbẹ́ Mususlumi ní Nàìjíríà
- Ẹ̀rọ ayàwòrán CCTV ṣe àkọsílẹ̀ bí àwọn ọmọ ogun Russia ṣe pa aráàlú méjì ní Ukraine
- Ṣé lóòótọ́ ní pé arábìnrin tó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ajá tí pàdánù ẹ̀mí rẹ̀?
- Ngige kọrin tuntun mi ò díje dupò aàrẹ Nàìjíríà mọ́, mo ti padà sí ọ́ọ́fíìsì mínístá tí mo wà tẹ́lẹ̀
- Orí ìpìlẹ̀ àṣeyọrí Buhari ni máa mọ lé tí mo bá fi di Ààrẹ - Fayemi
- "Ọlọ́pàá ní kí n bọra sílẹ láti mọ bóyá obìnrin ní mí torí mo ní irùngbọ̀n"
- Wo bí wọ́n ṣe ń ṣètò ìṣàkóso ní Alaàfin ìlú Oyo bóyá aáàfin wà láyé tàbí o ti papòdà
Obinrin naa sọ fun BBC pe "Mo lọ soju opo Google lati ṣe iwadii bi mo ṣe le gba ọmọ tọ lorilẹ-ede CAR,
ṣugbọn gbogbo ohun ti mo n ri nibẹ ko kọja ti USAid lọ ati bi awọn ọmọ ilẹ Amẹrika ṣe le gba ọmọ tọ nibẹ, n ko ri nnkankan nipa bi ọmọ Zambia ṣe le gba ọmọ ni CAR."
Gẹgẹ bii ohun to sọ, o gba lati koju oniruru ipenija ko le gba ọmọ naa tọ ko to ri gbe lọ silu Luzaka ni Zambia.
O ni "Ọrọ ọmọ naa mu mi ranti itan to wa ninu bibeli."
"Gbigba ọmọ tọ dabi igba ti eeyan ba yofẹ ni, ọpọ okunrin ni yoo kọ ẹnu ifẹ si obinrin amọ ẹyọkan ṣoṣo lo maa mu ninu wọn."
- Anthony Albanese di olóòtú ìjọba Australia, ohun tó yẹ kí o mọ̀ nípa rẹ̀ rèé
- Ta ló gbé òkú ènìyàn sí pápákọ̀ òfurufú Muritala Muhammed l'Ekoo? FAAN bẹ̀rẹ̀ ìwádìí
- Àwọn alákatakítí ẹ̀sìn dáná sun ilé mẹ́fà, ṣọ́ọ̀bù méje ní Bauchi lórí ẹ̀sùn sísọ̀rọ̀ òdì sí Islam
- Osinbajo,Tinubu àti àwọn míì tó ṣetán láti kojú ìgbìmọ̀ àyẹwò APC réè lẹyìn tí wọn fí fọ́ọ̀mù ṣọ̀wọ̀
- Èmi ni màá jẹ́ afárá láàrín àwọn Mùsùlùmí àtí Krìsténì tí mo bá di Ààre - Bukola Saraki
- Ààrẹ ilẹ̀ Arab, UAE, Sheikh Khalifa ti papòdà ní ẹni ọdún mẹ́tàléláàdọ́rin
- Ọlọ́pàá Sokoto fèsì sí ẹni tó gbé ìròyìn pé ọmọ orílẹ̀èdè Niger lẹ́ni tó pa Deborah Samuel
- Ènìyàn kan kú, àwọn mìíràn há sínú rẹ̀ bí ilé ṣe tún dàwó ní ìpínlẹ̀ Eko
Iha wo ijọba Zambia kọ si igbesẹ naa?
Aarẹ Zambia, Hakainde Hichilema gbe oṣuba kare fun Chansa fun ifẹ ọmọniyea to ni lọkan, eyii to jẹ ko gba ọmọ naa tọ.
Igbeṣe Aarẹ naa jẹ ki ọpọ eeyan mọ si nipa ohun ti obinrin naa ṣe.
O ni "Ọpọ eeyan lo n pe mi lori aago lẹyin igbeṣe naa, o si jẹ iyalẹnu fun mi."
Ọgagun naa ti sọ orukọ ọmọ ọhun ni Thabo bayii, o si ni oun ni erongba ati iran ọjọ iwaju rere fun ọmọ naa.
Chansa sọ pe "Erongba mi fun ọmọ naa ni pe ko di Aarẹ orilẹ-ede Central African Republic lọjọ iwaju, mo si gbagbọ pe yoo ri bẹẹ."















