Bukola Saraki 2023 Election: Èmi gan an ni ọmọ Nàìjíríà tó wà fún gbogbo ọmọ Naijiria- Bukola Saraki

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Ọjọ Kejidinlọgbọn si ikọkandinlọgbọn, ninu Osu Karun un ni idibo abẹle ẹgbẹ oṣelu PDP naa yoo waye.
Oludije fun ipo aarẹ ni ẹgbẹ oṣelu PDP, Bukola Saraki ti ni oun ni yoo jẹ olulaja laarin awọn Musulumi ati ọmọlẹyin Kristi.
Saraki sọ eyi lasiko to n ba awọn aṣoju oludibo labẹle sọrọ lori idibo abẹle ẹgbẹ to n bọ ṣaaju idibo sipo aarẹ ni ọdun 2023.
Awọn oludije sipo aarẹ ni ẹgbẹ oṣelu naa wa ki awọn oludije to le ni ẹgbẹrun mẹta (3,700) dibo yan an gẹgẹ bi ẹni ti yoo gbe asia ẹgbẹ naa.
- Àsìkò ti tó kí ìjọba fihàn pé kò sẹ́ni tó kọjá òfin lórí ikú Deborah- Ẹgbẹ́ Mususlumi ní Nàìjíríà
- Ẹ̀rọ ayàwòrán CCTV ṣe àkọsílẹ̀ bí àwọn ọmọ ogun Russia ṣe pa aráàlú méjì ní Ukraine
- Ṣé lóòótọ́ ní pé arábìnrin tó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ajá tí pàdánù ẹ̀mí rẹ̀?
- Ngige kọrin tuntun mi ò díje dupò aàrẹ Nàìjíríà mọ́, mo ti padà sí ọ́ọ́fíìsì mínístá tí mo wà tẹ́lẹ̀
- Orí ìpìlẹ̀ àṣeyọrí Buhari ni máa mọ lé tí mo bá fi di Ààrẹ - Fayemi
- "Ọlọ́pàá ní kí n bọra sílẹ láti mọ bóyá obìnrin ní mí torí mo ní irùngbọ̀n"
- Wo bí wọ́n ṣe ń ṣètò ìṣàkóso ní Alaàfin ìlú Oyo bóyá aáàfin wà láyé tàbí o ti papòdà
- Osinbajo,Tinubu àti àwọn míì tó ṣetán láti kojú ìgbìmọ̀ àyẹwò APC réè lẹyìn tí wọn fí fọ́ọ̀mù ṣọ̀wọ̀
Igba wo ni PDP yoo yan awon ọmọ Oye?
Ọjọ Kejidinlọgbọn si ikọkandinlọgbọn, ninu Osu Karun un ni idibo abẹle ẹgbẹ oṣelu PDP naa yoo waye.
Ninu ọrọ rẹ, Saraki ni oun ṣetan lati tun orilẹede Naijiria ṣe, ti oun yoo si jẹ afara laarin awọn ọmọ Naijiria ni Ariwa ati Guusu orilẹede naa.
''Emi ni ma a jẹ afara laarin awọn Musulumi ati Kristẹni, afara laarin awọn ara Guusu ati Ariwa orilẹede Naijiria.''
Bakan naa lo rọ wọn ki wọn dibo gẹgẹ bi ọkan wọn ba ṣe gba wọn laaye.
''Iṣoro ti Naijiria ni nipe ko si adari to yanju bi o ṣe yẹ lati tukọ orilẹede Naijiria.''
''Ohun ti Naijiria nilo ni awọn ọmọ wa ni ọjọ iwaju, Naijiria ati ẹgbẹ oṣelu PDP.
Bakan naa lo parọwa si wọn lati dibo yan oun, ki oun le da ẹgbẹ oṣelu naa pada si ipo.
Ìdí mọ́kànlá nìyìí tí mo fi fẹ́ díje dupò ààrẹ ní Naijiria - Bukola Saraki
2023 Election: Bukola Saraki ní òun kò ní fi ààyè sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Naijiria láti máa sálọ sí òkè òkun
Oludije fun ipo aarẹ ni Naijiria ati aarẹ Ile Igbimọ aṣ̣ofin tẹlẹri, Bukola saraki ti fi idi rẹ mulẹ wi pe oun yoo dije du ipo aarẹ lorilẹede Naijiria ninu idibo to n bọ ni ọdun to n bọ.
Saraki sọ eyi lasiko to n ṣe ipade pọ pẹlu awọn oniroyin ni ilu Abuja.
Ninu ọrọ rẹ, Saraki ni idibo ọdun to n bọ yoo fi aye silẹ fun awọn eniyan lati ni ireti ju asiko ti ko si ireti lọ.
- Óṣe! ènìyàn kan kú ẹlòmíràn farapa bí ọkọ̀ ńlá ṣe jábọ́ léwọn lórí l'Eko
- Wo àwọn iṣẹ́ méje tí o lè kọ́ láàrín oṣù mẹ́ta ti ASUU da iṣẹ́ sílẹ̀
- Ààrẹ Buhari pàrọwà sí ASUU láti padà sẹ́nu iṣẹ́ nítorí àwọn akẹ́kọ̀ọ́
- Fí fún ẹkùn tàbí ẹ̀yà kan ní tíkẹ́ẹ̀tì 'zoning' kò sí nínú òfin ẹgbẹ́ wa - PDP
- Mọ̀ síi nípa IPOB tó ń gbé orí ayélujára dá rúgúdú sílẹ̀ nítorí ọ̀rọ̀ Biafra
- Wo àwọn mínísítà ìjọba Nàìjíríà tó ti kọ̀wé fipò sílẹ̀ nítorí àṣẹ Ààrẹ Buhari
Laarin ọdun meji ni eto ilera ọfẹ yoo wa fun awọn ọmọ Naijiria lati ipele ida meje to wa si ida aadọta.
Saraki to jẹ gomina ipinlẹ Kwara tẹlẹ ṣalaye nkan mọkanla ti oun yoo ṣe ti wọn ba yan oun si ipo gẹgẹ bi aarẹ orilẹede Naijiria.
Awọn ohun mọkanla ti ma a ṣe niyii ti mo ba di aarẹ ni Naijiria
Bukola Saraki ni oun dije dupo aarẹ nitori oun ni igbagbọ pe Naijiria yii yoo ṣeeṣe fun awọn eniyan, ti wọn yoo si ṣe aṣeyọri.
Ninu ọrọ rẹ ni aṣofin tẹlẹri naa, Bukola Saraki ti ni ti wọn ba dibo yan oun ni oun yoo mu gbogbo ileri mọkanla yii ṣẹ;
•Ohun akoko ti maa ṣe nipe ki n ri daju pe ko si ọmọde kan ti ko lọ si ileẹkọ, ko si jẹ anfaani eto ẹkọ to mu irorun wa fun awọn eniyan.
•Ipese eto ilera fun awọn agbalagba ati gbogbo ọmọ Naijiria lati ida meje si ida aadọta laaarin ọdun meji.
- Kìí ṣe àwọn mínísítà tó fẹ́ dupò nìkan ní Buhari ní kó fi iṣẹ́ sílẹ̀ , wo àwọn tó tún kàn
- Ọ̀rọ̀ pátà dídọ̀tí tún rúná sí ìjà láàrin Nkechi Blessing àti ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ tẹ́lẹ̀, Falegan
- Èèyàn 60 l'erin ti pa láàrín ọdún yìí nìkan lórílẹ̀èdè Zimbabwe
- Àwọn olùfẹ̀hónúhàn dáná sun dúkìá bí ìwọ́de ṣe ń le si
- Ẹ múra o, ọ̀wọ́n gógó bẹntiró ń rúgbó bọ̀- IPMAN ṣèkìlọ̀ fún àwọn ọmọ Nàìjíríà
- Ọwọ́ tẹ afurasí ọmọ ẹgbẹ́ òkùnkùn ní ilé ìtura, wo nǹkan tí ọlọ́pàá ká mọ lọ́wọ́
•Ni asiko mi, opin yoo de ba igbesunmọmi ati iwa ọdaran nitori awọn agbofinro ati ileeṣẹ ọmọogun yoo gba ẹkọ ati ohun ẹṣọ ogun.
•Ma a ri daju pe iwe ofin Naijiria mulẹ daradara laisi pe awọn kan n doju ofin naa boḷẹ
•Idi ti mo fi fẹ di ipo aarẹ mu ni wipe mo fẹ ṣiṣẹ pẹlu awọn olokowo ati aladani lati kọ awọn ọdọ to le ni miliọnu kan ni iṣẹ ọwọ ni ọdọọdun.
•Ida abọ miliọnu ile igbe ni maa pese fun awọn ọmọ Naijiria
•Ma a ṣe atilẹyin fun Naijiria ki wọn le di ipo wọn mu daradara ninu awọn orilẹede to wa ni ilẹ adunlawọ.
•Bukola Saraki ni oun yoo ri daju pe eto ẹkọ ni awọn fasiti gbooro si to si ni awọn ọna igbalode bi ti awọn fasiti to leke ni agbaye.
•Bakan naa lo fikun un pe oun yoo ri daju pe awọn eniyan ko kaakiri lọ si oke ọkun lati lọ wa iṣẹ nitori awọn yoo pese iṣẹ fun awọn ọdọ, ti owo gọbọi yoo si ma a wọle fun wọn.

























