Fayemi declares for presidency: Kayode Fayemi sọ pé ètò ààbò ni yóò jẹ́ kókó nínú ìjọba òun

KAYODE FAYEMI

Oríṣun àwòrán, Screenshot

Gomina ipinlẹ Ekiti, to tun jẹ ẹni to fẹẹ dije fun ipo aarẹ labẹ ẹgbẹ́ oselu All Progressives Congress, APC, Kayode Fayemi, ti sọ pe oun yoo mọ lé awọn ipilẹ isẹ ti Aarẹ Buhari fi lelẹ.

Fayemi sọ ọrọ yii lasiko to lọ si ipinlẹ Borno ati Yobe, lati beere fun atilẹyin awọn asoju ẹgbẹ́ APC, saaju idibo abẹnu.

Ninu ọrọ rẹ, o ni "ori aṣeyọri Aarẹ Muhammadu Buhari, la o mọ lé, a o si tete mojuto àwọn ibi to kù diẹ kaato si.

Fayemi sọ pe eto aabo ni yoo jẹ koko ninu iṣejọba oun, gẹgẹ bi ẹni to jẹ onimọ nipa eto aabo.

" Mo ni iwe ẹri imọ ijinlẹ ọmọwe ninu ẹ̀kọ́ nipa ogun jija, mo si sisẹ gẹgẹ bi akọṣẹmọṣẹ ninu iṣejọba Aarẹ Obasanjo."

Àkọlé fídíò, Mothers day: Lẹ́yìn Olorun, Ìyá mi ló kù- Papa Ajasco, Abiodun Ayeyinka

Bakan naa lo sọ pe ipa kekere kọ ni oun ko lati da alaafia pada lasiko ogun to waye ni Sierra Leone, Liberia, Rwanda, ati Sri Lanka.

O ni" a ti ni ilana ti ao lo lati mu alaafia wa fun àwọn eeyan wa, ka le ṣe iṣẹ́ agbẹ pẹlu ifọkanbalẹ, lọ sile ẹ̀kọ́ ni ifọkanbalẹ, ka si tun ma a gbe ninu alaafia."

Fayemi sọ pe ko si nkan to burú ki òun ṣe awọn nkan ti oun ṣe nilẹ okeere, fun orile-ede to fun oun ni ohun gbogbo.

Àkọlé fídíò, Alaafin stool: Wo ẹni tó ṣeẹṣe pé kí Aláàfin kàn lẹ́yìn ìpapòdà Oba Lamidi Adeyemi

Nigba to n fun Fayemi ni esi, alaga ẹgbẹ́ APC nipinlẹ Borno, Ali Bukar Dalori, sọ pe Fayemi ni awọn yan laayo nipinlẹ naa.

Nitori àwọn amuyẹ rẹ, ati nitori oore to ṣe fun awọn alaga ẹgbẹ́ naa ni gbogbo ipinlẹ labẹ isakoso oun.

Bukar Dalori sọ pe adari to nifẹ awọn eeyan rẹ lo le ṣe bẹẹ.

Bákan naa ni ọrọ ri nipinlẹ Yobe.

Igbakeji gomina to soju gomina Mai Mala Buni, sọ pe ti Fayemi ni àwọn n ṣe.

Fayemi jẹjẹ fun awọn aṣojú Yobe ti yoo dibo abẹnu pe ọna abayọ kiakia ni oun yoo wa si igbesunmọmi ati awọn rògbòdìyàn mii to n waye ni Naijiria.

Ọjọ kẹrin, oṣu Karun-un, ọdun 2022, ni Gomina Kayode Fayemi kede ni gbangba pe oun naa yoo dupo aarẹ lati inu ẹgbẹ́ oselu APC lọdun 2023.

Saa kejì lo n lo lọwọ gẹgẹ bi gomina ipinlẹ Ekiti.

Àkọlé fídíò, Wo àwọn ohun tí BBC fìdí rẹ̀ múlẹ̀ nípa ohun tí àwọn ọmọ ẹgbẹ́ IPOB ń gbé sorí ayélujára