Shireen Abu Aqla: Ìtàn àkọ̀ròyìn Al Jazeera tí wón pa ní Israel rè é

Oríṣun àwòrán, Others
Ìtàn àkọ̀ròyìn Al Jazeera tí wón pa ní Israel rè é
Ọdun marundinlogun ni oniroyin naa fi jẹ gbajugbaja ti wọn mọ fun iṣẹ takuntakun loju ogun gẹgẹ bi akọroyin.
Gbajugbaja oniroyin ọmọ ilẹ Palestine, Shiren Abu Aqla ni wọn ti pa lasiko to n ṣiṣẹ gẹgẹ bi oniroyin fun ileeṣẹ iroyin Aljazeera.
Abu Aqla lo ṣiṣẹ oniroyin ni agbegbe West Bank ni ibi ti ija ti ma n waye laarin Palestine ati Israel.
- Óṣe! ènìyàn kan kú ẹlòmíràn farapa bí ọkọ̀ ńlá ṣe jábọ́ léwọn lórí l'Eko
- Àwọn Aláṣẹ ilẹ̀ Palestine ní eèyàn 139 ló ti kú ní Palestine nínú ìja Isreal àti Palestine
- Ìdí mọ́kànlá nìyìí tí mo fi fẹ́ díje dupò ààrẹ ní Naijiria – Bukola Saraki
- Aàrẹ Joe Biden sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́ lórí ìja Isreal àti Palestine
- Mọ̀ síi nípa Agbẹjọ́rò àti ajàfẹ́tọ̀ọ́ ọmọniyàn ni Nàìjíríà tó lọ sí ẹ̀wọ̀n nígbà 32
- Ààrẹ Buhari pàrọwà sí ASUU láti padà sẹ́nu iṣẹ́ nítorí àwọn akẹ́kọ̀ọ́
- Wo àwọn iṣẹ́ méje tí o lè kọ́ láàrín oṣù mẹ́ta ti ASUU da iṣẹ́ sílẹ̀
Ileeṣẹ Al Jazeera ni Qatar ni awọn ikọ ọmọogun ilẹ Israel lo pa oṣiṣẹ wọn lai ni idi.
Bakan naa ni ileeṣẹ eto ilera ni Palestine ni Abu Aqla ku lasiko to n kọ Iroyin nipa bi Ilẹ Israel ṣe ṣekọlu si ibugbe ogunlende ni Jenin.
Atẹjade naa ni ẹni ti iṣẹlẹ naa ṣoju rẹ ni wọn yinbọn fun arabinrin naa ni ori lati ọọkan.
Bio tilẹ jẹ pe o wọ ibori ati ewu to sọ wi pe akọroyin ni, wọn yinbọn lu u ni ori.
Amọ Olootu Ilẹ Israel ni oṣeeṣe ko jẹ agbẹbọn ọmọ ilẹ Palestine lo yinbọn lu u lasiko ti wọn doju ibọn kọ ikọ Ologun ilẹ Israel.
Tani Akọroyin Shireen Abu Aqla ti wọn yinbọn pa?
Ọdun 1971 ni wọn bi Shireen Abu Aqla ni Jerusalem, to si lọ si ileẹ̀kọ́ Rosary Sisters High school ni agbegbe Beit Hanina, Jerusalem.
O kọkọ lọ si fasiti Jordan University of Science and Technology lati lo kọ imọ nipa Art.
Lẹyin naa lo kẹkọ gboye Bachelor's degree ni imọ iroyin lati fasiti Yarmouk University ni Jordan.
- Ẹkún tún sọ ní Zamfara, àwọn agbébọn pa èèyàn 48
- Èsì ìdánwò UTME abala àkọ́kọ́ yóò jáde lọ́sẹ̀ yìí- Àjọ JAMB
- Irọ́ ni pé Bola Tinubu fẹ́ kúrò ní ẹgbẹ́ òṣèlú APC- Agbẹnusọ Aṣíwájú
- Iṣẹ́ Ọlọ́run tí mo gbé dáni kọjá ipò Ààrẹ Nàìjíríà – Bíṣọ̀ọ̀bù David Oyedepo
- Ẹbí kan pàdánù ọmọ mẹsan-án nínú èèyàn 435 tí omiyalé pa
- Ẹgbẹ́ CAN foríjin ilé ìfowópamọ́ Sterling, ìdí rèé
- Àwọn iléeṣẹ́ bàlúù ní Nàìjíríà ronúpìwàdà lórí wíwọ́gilé ìrìnnà òfúrufú ní Nàìjíríà lọ́jọ́ Ajé, ohun tó fàá nìyí
- Mọ̀lẹ́bí ṣàlàyé kíkún nípa bí agbébọn ṣe ṣekúpa Gloria Mathew àti àfẹ́sọ́nà rẹ̀ nínú igbó ní ìpínlẹ̀ Imo
O ṣiṣẹ pẹlu ọpọlọpọ ileeṣẹ iroyin ti ilẹ Palestine to fi mọ ''Voice of Palestine ati Amman TV.
Ọdun 1997 lo darapọ mọ Aljazeera lẹyin ọdun kan ti wọn da silẹ, to si jẹ ọkan lara awọn oṣiṣẹ akọkọ ni ileeṣẹ naa.
Ọdun marundinlogun ni oniroyin naa fi jẹ gbajugbaja ti wọn mọ fun iṣẹ takuntakun loju ogun gẹgẹ bi akọroyin.














