Yoruba Nation: Kò sí ẹni tàbí ohun tó le mú mi yi ìpinnu padà lórí Yorùbá Nation - Banji Akintoye

Oríṣun àwòrán, Screenshot
Ọ̀jọ̀gbọ́n Banji Akintoye, tó jẹ́ olùdásílẹ̀ Ìlànà Ọmọ Oòduà káàkiri àgbáyé ti jiyàn rẹ wí pé ìròyìn òfégè ni ìròyìn tí ilé iṣẹ́ Sahara Reporters gbé jáde pé òun ti yọwọ́ nínú ẹgbẹ́ Ìlànà Ọmọ Oòduà.
Nínú àtẹ̀jáde kan tí Banji Akintoye fi léde lọjọ́ Ẹtì, ọjọ́ Kẹtàlá, ọdún 2022 ni irọ́ tó jìnà sí òótọ́ ni pé ò ń gbèrò láti pa ẹgbẹ́ Ìlànà Ọmọ Oòduà tí fún ìdí kankan.
Ní ọjọ́bọ̀ ni Sahara Reporters fi ìròyìn kan léde wí pé àwọn kan ti ń fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ owó àgbọ́forísọ̀pó lọ Akintoye láti yí ìpinu rẹ̀ padà lórí Ilana Omo Oodua.
- Okùnrin tó bá ọmọ ọdún 16 lòpọ̀, tó tún ya fọ́tò ìhòhò rẹ̀ dèrò àtìmọ́lé l’Ogun
- Ìpàdé ìjọba Nàìjíríààti ASUU lórí ìyanṣẹ́lódì tún forí ṣánpọ́n
- Mr Macaroni, Serap, Oby Ezekwesili, Amnesty International faraya lórí Deborah tí wọ́n pa ní Sokoto lórí ẹ̀sùn pé ó sọ̀rọ̀ lódì sí Ànọ́bì
- Àwọ̀n ènìyàn rò pé wèrè, ajínigbé ni mí, àmọ́ mo ti kọ́ ilé janturu, fẹ́ ìyàwó mẹ́sàn àn , bí ọmọ 35 – Alfa to n ṣa irin ni atan
- Oloye Adeniji Ige, Mínísítà ètò ìròyìn tẹ́lẹ̀rí ní Nàìjíríà dágbére fún ayé lẹ́ni ọdún mẹ́rìndínláàdọ́rùn ún
Ó ní ó jẹ́ ohun ìyàlẹ́nu fún òun wí pé àwọn kan ròó wí pé òun yóò tìtorí owó gbàgbé gbogbo ìjìjàgbara tí òun ń ṣe fún Yorùbá nation, kí òun wá gbà láti lọ máa darí ẹgbẹ́ ìkówójọ kan.
Ó ni èyí jẹ́ ìtàbùkù òun àti ríra èébú fún òun.
Ó fi kun pé lẹ́nu ìgbà tí àwọn ti dá Ilana Omo Ooduasílẹ̀, ó ti gbòòrò débi wí pé àwọn ọmọ Yorùbá káàkiri ti ń ri gẹ́gẹ́ bí agboòrùn tí wọ́n le sá sí abẹ́ rẹ̀ láti fi gba ara wọn sílẹ̀ lọ́wọ́ ìjọba arẹ́nijẹ, àìsí ètò ààbò àti ètò ọrọ̀ ajé tó ti dorí kodò ní Nàìjíríà.
Ẹnìkankan kò ì tíì gbé owó wá fún mi
Bákan náà ló tẹ̀síwájú wí pé títí di àsìkò yìí, òun kò ì tíì rí ẹnìkankan gbé owó wá fún òun láti ọ̀dọ̀ ìjọba àti pé òun kò lérò wí pé ìjọba le ronú kan òun láti gbé owó fún.
Akintoye sọ síwájú pé ìjọba àpapọ̀ lábẹ́ ìdarí Ààrẹ Muhammadu Buhari mọ òun dáadáa, tí wọ́n sì mọ̀ wí pé àwọn kò lè fi owó ra òun.
- Ó dàbí ẹni pé ẹ kò mọ̀ ìdí tí mo fi ń díje dupò ààrẹ, òhun rè é - Tinubu ṣàlàyé
- Ìtàn àkọ̀ròyìn Al Jazeera tí wón pa ní Israel rè é
- Ohun tí a mọ nípa ikọlù àwọn agbébọn sí ilé ìtura ní Ikorodu rèé
- Ìdí mọ́kànlá nìyìí tí mo fi fẹ́ díje dupò ààrẹ ní Naijiria – Bukola Saraki
- Óṣe! ènìyàn kan kú ẹlòmíràn farapa bí ọkọ̀ ńlá ṣe jábọ́ léwọn lórí l'Eko
Bẹ́ẹ̀ náà ló ní láìpẹ́ yìí ni ẹ̀yà Yorùbá yóò bọ́ lọ́wọ́ gbogbo ìyà àti ìṣẹ́ tó ń bá orílẹ̀ èdè Nàìjíríà fínra, tí ilẹ̀ Yorùbá yóó sì dá dúró èyí tí yóò mú ìdàgbàsókè bá àwọn ènìyà inú rẹ̀.
Ó fi kun pé kò sí àníàní tàbí à ń padà sẹ́yìn lórí ìjìjàgbara fún ìdásílẹ̀ Yorùbá nation.



















