No-fly zone: Garba Shehu ṣàlàyé ìdí tí Aàrẹ Buhari ṣe kéde pé kí ọkọ̀ òfurufú má fò ní Zamfara mọ́

Oríṣun àwòrán, others
Lọjọ Iṣẹgun ni aarẹ Muhammadu Buhari kede pe ki ọkọ ofurufu ma fo mọ lori afẹfẹ ni ipinlẹ Zamfara.
O ni oun gbe igbesẹ yii lati mojuto eto aabo ẹkun naa.
Kini itumọ 'No-Fly Zone" ?
Eyi ni ikede nipa agbegbe kan ti ijọba ma paṣẹ waa le lori pe wọn ko ni le fo lori rẹ.
Eyi ja si pe ọkọ ofurufu kankan ko ni le gba ibẹ koja ni igba gbendeke asiko naa.
Awọn ologun lo maa n ni agbara lori irufẹ agbegbe bayii.
Wọn ko ni faaye gba gbogbo ọkọ ofurufu yoowu ko jẹ lati fo nibẹ.
Iru agbegbe yii maa n saaba jẹ nigba ogun tabi ti ilu tabi agbegbe naa ko ba fararọ.
- Ewú ńbẹ! tí ìjọba ìpínlẹ̀ bá sàkóso gbèndéke owó oṣù òṣìṣẹ́,wọ́n ò ní san N30,000, N10,000 ní wọ́n má á san -NLC
- Àwọn ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ tó dá mi lọ́nà lọ́jọ́ Ẹtì fẹ́ pa mí ni -Sunday Igboho
- Nǹkan dé, Igboho ní káwọn ọ̀dọ́ ilẹ̀ Yorùbá lọ múra ògùn jọ nítorí ohun tó ń bọ̀ lọ́nà
- Ọlọrun má jẹ́ kí a jẹ́ gbèsè lókù báyìí tí a kò kó ọjá lọ sílẹ̀ Yorùbá mọ́- Hausa Oníṣòwò
Garba Shehu ṣàlàyé ìdí tí Aàrẹ Buhari ṣe kéde pé kí ọkọ̀ òfurufú má fò ní Zamfara mọ́
Olubadamọran si aarẹ Buhari lori eto iroyin, Garba Shehu ti ṣalaye idi ti Buhari fi kede pe ọkọ ofurufu ko gbọdọ fo mọ ni Zamfara.
O ni ọpọlọpọ ọkọ ofurufu aladani ni awọn kan fi maa n ko ẹru iwakusa kuro ni agbegbe yii.
Koda, O ni wọn n lo ọkọ ofurufu wọnyii lati fi ko nkan ogun ati ohun eelo iṣọṣẹ bii ibọn.
Garba Shehu tun ni wọn n fi ọkọ ofurufu aladani yii ti wọn tun fi n ji goolu ko lọ si Dubai lati ipinlẹ Zamfara.
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Ijeoma ní òun kìí ṣe ọmọ Nàìjíríà mọ́, South Africa tó yàn dípò bá tún lé e jáde
- Owó Taxi ní ìpínlẹ̀ Ondo tí padà sí N50 látí N100 nítorí kò sí gbígba ''tíkẹ́ẹ̀tì'' NURTW mọ́
- Abẹ́rẹ́ àjẹsára, Covid 19 ti balẹ̀ bàgẹ̀ sí orílẹ̀èdè Naijiria
- Ẹ kó àwọn ọkọ̀ yín tó ti dẹnukọlẹ̀ kúrò lójú popo tàbí kí a gbẹ́sẹ̀lé wọn- FRSC sí àwọn awakọ̀
- Ohun tó yẹ kí ó mọ̀ nípa oríṣìíríṣìí ìlẹ̀kẹ̀ ìbàdí rè é
Se iru rẹ ti ṣẹlẹ ri ni Naijiria?
Saaju asiko yii ni Olubadamọran fun eto aabo ni Naijiria nigba kan ri, Ogagun agba to ti fẹyinti Babagana Monguro kede iru ikede yii.
O ni eyi ko ṣẹyin alami ti ijọba igba naa gbọ alami pe awọn kan fẹ ṣọṣẹ ni eyi ti wọn fi kede nigba naa.
Lọdun 2017 ni Baba=gana Munguno kede pe ọkọ ofurufu kankan ko gbọdọ fo kọja ni Abuja nigba naa.
Koda, o tun ti ilekun papakọ ofurufu Abuja nigba naa pa.

Oríṣun àwòrán, @Presidency
Kò sí ìwakùsà àti ìrìnàjò ọkọ̀ òfurufú mọ́ ní ìpínlẹ̀ Zamfara- Aàrẹ Buhari
Aarẹ Muhammadu Buhari ti fofin de irinajo ọkọ ofurufu ni ipinlẹ Zamfara nitori ipo ti eto abo ipinlẹ naa wa lasiko yii.

Oríṣun àwòrán, Nig Govt
Bẹẹ naa ni Aarẹ Buhari tun gbẹsẹle gbogbo ohun to jọ mọ iwakusa ni ipinlẹ ọhun.
Olubadamọran fu Aarẹ lori eto abo, ajagunfẹyinti Babagana Monguno lo fin ọrọ naa lede lẹyij ipade awọn adari ijọba to waye nile ijọba apapọ niluu Abuja.
- Àwọn òṣìṣẹ́ Shoperite bẹ̀rẹ̀ ìfẹ̀hónúhàn ní Ibadan, Akure, Eko àtàwọn ìlú míràn
- Owó Taxi ní ìpínlẹ̀ Ondo tí padà sí N50 látí N100 nítorí kò sí gbígba ''tíkẹ́ẹ̀tì'' NURTW mọ́
- Abẹ́rẹ́ àjẹsára, Covid 19 ti balẹ̀ bàgẹ̀ sí orílẹ̀èdè Naijiria
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Ijeoma ní òun kìí ṣe ọmọ Nàìjíríà mọ́, South Africa tó yàn dípò bá tún lé e jáde
- Owó Taxi ní ìpínlẹ̀ Ondo tí padà sí N50 látí N100 nítorí kò sí gbígba ''tíkẹ́ẹ̀tì'' NURTW mọ́
Eyii n tumọ si pe baalu ileeṣẹ awọn ọmọ ogun nikan lo lẹtọ labẹ ofin lati fo ni ofurufu ipijlẹ naa.
Ọgagun Monguno sọ pe oju awọn wa lara gbogbo awọn ti kii ṣe oṣiṣẹ ologun nipinlẹ naa, ati pe gbogbo ohun ti yoo gba ni awọn yoo fun ki alaafia le pada si agbegbe naa.
O sọ siwaju si pe gbogbo awọn ileeṣẹ ijọba apapọ to n ṣiṣẹ ifimufinlẹ lo ti gbaradi lati ri pe awọn kọlọrọsi kankan ko sọ Naijiria sinu idamu.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, Aarẹ Muhammadu Buhari ti paṣẹ fun awọn ọga agba ileeṣẹ ọmọ ogun lati gba iṣakoso gbogbo awọn agbegbe ti awọn oniṣẹ ibi ti n ṣọṣẹ.

Oríṣun àwòrán, Bashir ahmad/twitter
Àwọn aṣòfin àgbà buwọ́lu orúkọ àwọn olórí ológun tuntun
Service chiefs: Àwọn aṣòfin àgbà buwọ́lu orúkọ àwọn olórí ológun tuntun
Ileegbimọ aṣofin agba lorilẹede Naijiria ti buwọlu orukọ awọn ọga agba ileeṣẹ ologun tuntun ni Naijiria.
Wọn buwọlu orukọ wọn lẹyin ti igbimọ tẹẹkoto nile naa gbe wọn kalẹ pe wọn ti wẹ yan kainkain lati jẹ aṣaaju fun awọn ẹka ileeṣẹ ọmọ ogun lorilẹede Naijiria.
- Abẹ́rẹ́ àjẹsára, Covid 19 ti balẹ̀ bàgẹ̀ sí orílẹ̀èdè Naijiria
- 'Tinubu kò ṣe nǹkan ètùfù tó lè fi máa kíyèsí ẹ̀yìnkùlé nítorí EFCC'
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Ijeoma ní òun kìí ṣe ọmọ Nàìjíríà mọ́, South Africa tó yàn dípò bá tún lé e jáde
- Owó Taxi ní ìpínlẹ̀ Ondo tí padà sí N50 látí N100 nítorí kò sí gbígba ''tíkẹ́ẹ̀tì'' NURTW mọ́
Ni Ọjọru to kọja ni aarẹ ile naa, Sẹnetọ Ahmad Lawan gbe iwe ti aarẹ kọ lati fi orukọ wọn ṣọwọ si awọn aṣofin agba ka iwaju ile naa to si fun igbimọ tẹẹkoto lori aabo ni ile naa ni gbendeke ọsẹ meji lati fi ṣe ayẹwo wọn fun igbọwọle.
Awọn olori ileeṣẹ ologun tuntun naa niwọnyii:
Ọgagun agba (Major General) Lucky Eluonye Onyenuchea lrabor - Ọgagun agba patapata
Ọgagun agba (Major General) Ibrahim Attahiru - Olori ileeṣẹ ọmọogun oriilẹ.
Ọgagun agba oju omi (Rear Admiral) Awwal Zubairu Gambo- Olori ileeṣẹ ọmọogun ojuomi.
Ọgagun agba ofurufu (Air Vice Marshal) Isiaka O. Amao- Olori ileeṣẹ ọmọogun ofurufu.
Sẹnetọ Lawan to jẹ aarẹ ile aṣofin agba ke sawọn olori ileeṣẹ ologun naa lati tubo kara masiki gbigbogun ti igbesunmọmi ki wọn si jẹ awọn ibuba wọn run.
- A ò ní kó oúnjẹ lọ sílẹ̀ Yorùbá láì jẹ́ pé ààbò wà fáwọn Fulani níbẹ̀- Miyetti Allah
- Genevieve ṣàlàyé ànfààní tó wà nínú ìbásùn òwúrọ̀ kùtù fáwọn lọ́kọ láya
- Nítorí 'áfúsá', àwọn nọ́ọ̀sì bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì l'Ondo
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Ijeoma ní òun kìí ṣe ọmọ Nàìjíríà mọ́, South Africa tó yàn dípò bá tún lé e jáde
- Àwọn ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ tó dá mi lọ́nà lọ́jọ́ Ẹtì fẹ́ pa mí ni -Sunday Igboho
- Ọkùnrin méjì dèrò àhámọ́ lẹ́yìn tí wọ́n fipá bá ọmọ ọdún 16 lòpọ̀


















