Yoruba-Fulani crisis: Ọlọrun má jẹ́ kí a jẹ́ gbèsè lókù báyìí tí a kò kó ọjá lọ sílẹ̀ Yorùbá mọ́- Hausa Oníṣòwò

Oríṣun àwòrán, others
Awọn ẹgbẹ olounjẹ ati ẹlẹran ọsin ni Naijiria lati ariwa ti amọ si AUFCDN n tẹsiwaju ninu iyanṣẹlodi wọn.
Egbe yii ti apeja orukọ wọn n jẹ: Amalgamated Union of Foodstuff and Cattle Dealers of Nigeria (AUFCDN) ni wọn kede pe ohun gbogbo ti gba ọpọ bayii nilẹ Hausa.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
Gbogbo awọn agbẹ ti ọrọ kan ni apa ariwa Naijiria ti wọn ti n ko ohun eelo ọbẹ bii ata, tomati, alubọsa, iresi ati bẹẹ bẹẹ lọ ti n pariwo gbese..A ò ní kó oúnjẹ lọ sílẹ̀ Yorùbá láì jẹ́ pé ààbò wà fáwọn Fulani níbẹ̀- Miyetti Allah
Wọn ni ọpọ ti ko ni ere rara ni awọn fi n ta nkan ọbẹ bayii ki wọn ma baa bajẹ mọ ori igba ati inu oko awọn.
Awọn miran ni ọrọ naa ko le tii aynju bayii laisi awọn igbesẹ kan;

Koda, ọpọ eeyan lo ti fidi ẹ mulẹ pe ọpọ ni apẹrẹ Tomati ati rodo bayii ni awọn ipinlẹ to wa ni ariwa ati ni Abuja to jẹ olu ilu Naijiria.
Eyi ko ṣẹyin bi awọn kan ṣe lọ di opopona ti wọn n gba ko nkan oko wọle wa si iwọ oorun guusu Naijiria lati ariwa
Ọpọ awọn eeyan lori ayelujara lo ṣalaye pe ohun to ṣokunfa gbese ọlọpọ yanturu ni ariwa yii ko ṣẹyin pe awọn ata ti pọ ju nibẹ nitori pe wọn ko ri wọn ko lọ si awọn ipinlẹ ilẹ Yoruba ati Igbo.
- Ẹni tó tẹ̀é mi lọ sílé ẹjọ́ ti ayé ń pariwo kìí ṣe Aláfọ̀ṣẹ rárá bíkòṣe...- Sowore
- Chimamanda Adichie pàdánù bàbá, ìyá láàrín ọdún kan, kíló ṣẹlẹ̀?
- Ẹ wo bí ìyàwó Pasitọ Adeboye ṣe sàpèjúwe rẹ̀
- Kí làwọn nǹkan tó lè rán ọkùnrin sí ọ̀run alákeji lásìkò ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin?
- Ẹ kó àwọn ọkọ̀ yín tó ti dẹnukọlẹ̀ kúrò lójú popo tàbí kí a gbẹ́sẹ̀lé wọn- FRSC sí àwọn awakọ̀
- Kí làwọn nǹkan tó lè rán ọkùnrin sí ọ̀run alákeji lásìkò ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin?
Bẹẹ awọn eeyan ti n sọrọ lori ayelujara:

Bawo ni ọmọ ṣe sọri lọja ilẹ Yoruba ati Igbo bayii?
Ni iṣọ ẹlẹran ìso ni ọja Alaba ni ipinlẹ Eko ni owo ẹran agbo ti di ilọpọ mẹta bayii.
Akọroyin BBC to lọ sibẹ ni koda, niṣẹ ni gbogbo ọja naa da waiwai ti ero ko si pọ rara.
O ni bẹẹ si ni gbogbo ẹran ọsin ati awọn nkan miran gbowo lori jọjọ.
Mallam Tanimu Bulama to jẹ Waziri alaba Rago ṣlaye fun BBC pe: Eran agbo ti wọn n ta ni N30, 000 tẹlẹ ti di N95,000 bayii nitori pe Niger ati ilẹ Sudan gba ilẹ Hausa ni awọn n gab ko ẹran wọle ju.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
Ero awọn Yoruba to n ra ọja ọwon naa yatọ bayii:

Mallam Umar to tun ba BBC sọrọ ṣalaye pe ironu ti ba ọpọ awon agbẹ ati Oniṣowo ni ariwa Naijiria nitori pe nkan ti n bajé si ori igba wọn.
O ni bayii awọn ti n ta tomati apẹrẹ ti wọn n ta ni N2,100 tẹlẹ ni N800 nitori pe wọn ti n bajẹ.

Oríṣun àwòrán, @Awal Ahmad
Se lootọ ni wọn n ko ọja pamọ?
Awọn miran ni awọn ọlọja nilẹ Yoruba n ko ọja pamọ nitori pe ọja mii ko de lati ilẹ Hausa.

Sugbọn Emir ọja Alaba, Alhaji Umaru Goggo ni irọ ni eyi.
O parọwa pe asiko ti to ki wọn fopin si aṣẹ ma ko ọja wọle lati ariwa yii.
- Ẹ wo èrò àwọn ènìyàn lórí bí Gòmìná Akeredolu ṣe fòfin de NURTW, RTEAN nípínlẹ̀ Ondo
- Owó Taxi ní ìpínlẹ̀ Ondo tí padà sí N50 látí N100 nítorí kò sí gbígba ''tíkẹ́ẹ̀tì'' NURTW mọ́
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Ijeoma ní òun kìí ṣe ọmọ Nàìjíríà mọ́, South Africa tó yàn dípò bá tún lé e jáde
- Àwọn ajínigbé fìyà jẹ́ wa lọ́nà igbó tí wọ́n kó wa lọ- Akẹ́kọ̀ọ́bìnrin GSS Zamfara
- Abẹ́rẹ́ àjẹsára, Covid 19 ti balẹ̀ bàgẹ̀ sí orílẹ̀èdè Naijiria
- Kí làwọn nǹkan tó lè rán ọkùnrin sí ọ̀run alákeji lásìkò ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin?
O ni o n ṣakoba fun ati Hausa ati Yoruba ati Igbo ni bayii.
Koda, Emir naa ke si aarẹ Naijiria lati wa ojutu si iṣoro yii ki nkan ma lọ bajẹ tan.















