Sunday Igboho: Igboho láṣẹ lábẹ́ òfin Nàìjíríà láti bọ ohun tó wù ú nígbà tó wù ú- Yinka Oyebode

IGBOHO

Oríṣun àwòrán, FACEBOOK

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 3

Ijọba ipinlẹ Ekiti ti ni awọn gbọ wi pe eekan ọm Yoruba, Sunday Igboho lọ si igbo Ire-Ekiti lati lọ bọ Ogun.

''Lọ́ọ̀tọ́ ní Sunday Igboho wá sí igbó Ire-Ekiti láti bọ Ogun lákáyé! ''

Akọwe eto iroyin fun gomina ipinlẹ Ekiti, Yinka Oyebode lo sọ bẹẹ fun BBC Yoruba lẹyin fidio to jade lori ayelujara,to safihan Sunday Igboho ninu igbo Ire-Ekiti.

Arakunrin Oyebode ni Igboho laṣẹ ni abẹ ofin lati lọ si ibikibi to ba wu u nitori ọmọ orilẹede Naijiria ni, to si le e ṣe ẹsin to ba wu u.

Akọwe Ekiti ni: 'Amọ agbegbe Ire-Ekiti fun ibi ti awọn eniyan gbagbọ nipa bibọ Ogun, nitori naa a gbọ wi pe oun nbọ nibẹ''

''Oun ti o lọ ṣe nipe o lọ darapọ mọ awọn ẹlẹsin ibilẹ lati lọ bọ Ogun gẹgẹ bi igbagbọ rẹ''

Àkọlé fídíò, Bone setting: Adimula Kehinde Akinfenwa ṣàlàyé nípa irúfẹ́ ẹranko tí wọ́n fi ń to eegun èy

Saaju ni fidio kan ti ja ranyin lori ayelujara nibi ti awọn eniyan ti tu yaya sita lati ki Sunday Igboho kaabọ ni agbegbe wọn.

Lẹyin naa ni wọn lọ si ojubọ Ogun lati lọ ṣe adura ati iṣẹṣe.

Sunday Igboho

Awọn ero lo pejọ naa wa ni ibi ojubọ Ogun naa lati oru titi di owurọ lati rubọ ati lati ṣe adura.

Awọn eniyan ti wọn n sọrọ ninu fidio naa sọ wi pe awọn ara agbegbe Ire-Ekiti gba ni alejo wa si agbegbe wọn.

Ti wọn si fun un ni ọpa aṣẹ ti Ogun lo nigba aye rẹ lati fi jagun.

Awọn ẹlẹsin ibilẹ gbagbọ wi pe ilu Ire-Ekiti ni Ogun wọlẹ si, ti wọn si ma n lọ si ojubọ rẹ lati bọ ọ ni orekoore.

Bakan naa ni wọn n yin ibọn kalukalu lati fi bọ Ogun gẹgẹ bi iṣe wọn lasiko ti wọn ba n bọ orisa naa.

Nǹkan dé, Igboho ní káwọn ọ̀dọ́ ilẹ̀ Yorùbá lọ múra ògùn jọ nítorí ohun tó ń bọ̀ lọ́nà

Eekan ọmọ Yoruba ni, Sunday Adeyẹmọ ti ọpọ mọ si Sunday Igboho ti ṣeleri ati da sẹria to ba yẹ fun awọn oloṣelu ọmọ ilẹ Yoruba to ba gbiyanju ati darapọ mọ idije ipo aarẹ Naijiria lọdun 2023.

Igboho

Oríṣun àwòrán, Others

Igboho to sọ eleyii nigba to n ba ọpọ ero kan sọrọ̀ nibi eto kan laipẹ yii.

O ṣalaye pe, dipo ki awọn oloṣelu ẹya Yoruba o maa gbaruku ti ipe fun ijijangbara ilẹ Yoruba, ipolongo lati dije fun ipo aarẹ ni wọn n le kaakiri."

O ni oun o ni gba kawọn oloṣelu ilẹ Yoruba kan laaye lati dije nitori oun ṣetan lati gbẹmi wọn ki idibo naa gan to waye.

Bakan naa lo tun rọ awọn agbagba ilẹ Yoruba lati dide fun ijijagbara ilẹ Yoruba.

Àkọlé fídíò, Olusegun Obasanjo: Ọmú ìyá mi ti mo fi ń mùkọ ni kekere ló jẹ ki ń lókun

Ninu ọrọ rẹ, o ni imọtara-ẹni-nikan lo n ba awọn oloṣelu ilẹ Yoruba ja ti wọn fi n polongo fun ilepa ara wọn lati di aarẹ.

O ni oun yoo ba wọn ja bi wọn ba gbero rẹ.

Àkọlé fídíò, NURTW Ondo: Ọ̀pọ̀ èrò ní Akure fi ayọ́ hàn bí Aketi ṣe ni kí NURTW lọ sinmi

Bakan naa ni Igboho tun ke sawọn ọdọ lati lọ ṣe oogun abẹnugọngọ lati lee fi gbeja ara wọn lasiko ipenija to n bọ lọna.

Àkọlé fídíò, Akomolede àti Aṣa: Olùkọ́ Olajide láti Ẹdẹ ló ṣàlàyé nípa Awẹ́ Gbólóhùn fún wa ní kíkún