Fulani Herdsmen Killing: Ẹran dídà káàkiri di ẹ̀ṣẹ̀ ní Oyo àti Ogun

Oríṣun àwòrán, @Muhammed Gumi
Ijọba ipinlẹ Oyo kede pe o ti di ofin bayii pe awọn darandaran ko gbọdọ da ẹran mọ kaakiri ipinlẹ naa.
Eyi ko sẹyin bi eto aabo ti dẹnukọlẹ ni ilẹ Yoruba pẹlu awọn darandaran ti wọn fẹsun ijinigbe ati ipaniyan kan kaakiri awọn ipinlẹ marun un ni ilẹ Kaarọ Oojire
Akowe iroyin fun Gomina Seyi Makinde, Taiwo Adisa lo sisọ loju ọrọ yii pẹlu afikun pe awọn darandaran ni anfaani lati ra ilẹ ti wọn yoo ti ma a da ẹran wọn kaakiri ipinlẹ Oyo.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Obasanjo ló yarí, Tinubu ni kò bá jẹ́ igbákejì Buhari - Oyinlola
- Kánífà Àdìrẹ gbé Odunlade re ìlú òyìnbó, Bobrisky rọ̀jò owó lé olólùfẹ́ lórí, Muka Ray pàdánù àbúrò
- Ta bá gba Seriki Fulani padà sí Igangan, a fi ọwọ́ ara wa, pa ara wa ni - Aráàlú
- Wo ọ̀dọ́mọdé olówó, tí àwọn ọkọ̀, fóònù, ọtí wáínì, ẹ̀ṣọ́ ilé rẹ̀ jẹ́ kìkìdá góòlù
- Ẹjọ́ ẹ̀ṣùn àjẹbánu márùn ún to milẹ titi ní Nàìjíríà lọdún 2020
- Buhari fọnmú bí Transparency International ṣe fi Nàíjíríà ṣípò kejì nínú ìwà àjẹbánu
- Ó wù mí kí ń padà sí Igangan, tí wọn bá fún mi láàyè - Seriki Fulani
- Èèyàn 75 di àwátì, 18 jáde láyé bí agbébọn ṣe gbàjọba yíka Nàíjíríà l‘Ọ́jọ́bọ
- Bí Sunday Igboho bá tàpá sófin, kí lẹ ṣe fáwọn ọ̀daràn Fulani tó ń pa èèyàn - Gani Adams
O ni awọn darandaran gbọdọ mọ wi pe, ọrọ aje tara wọn ni ọsin ati katakara ẹran jẹ, nitori naa, ko yẹ ki wọn fi da awọn ẹlomiran laamu.
"Ofin tuntun nipinlẹ Oyo fi idi rẹ mulẹ pe, idokowo ara ẹni ni isẹ darandaran, nitori naa, ijọba gba wọn laaye lati ra ilẹ lọwọ ijọba lati lo fun iṣẹ wọn''
''Amọ ofin naa ko fi aye gba dida ẹran kaakiri ni igboro kọja aala ti wọn fun wọn ni ori ilẹ tijọba yoo ya wọn lo fun ọdun mẹta, wọn yoo si pada wa ṣe iforukosilẹ miran fun ọdun mẹta mii''
''Ijọba ti kọ fun awọn ọmọde lati ma a da ẹran kaakiri ayafi ki agbalagba kan duro ti wọn.''
Bakan naa ni ijọba ipinlẹ Ogun ni awọn ti bẹrẹ igbesẹ lati sọ ọ di ofin pe ki awọn darandaran wa ma a fi orukọsilẹ, ki wọn to le ṣiṣẹ nipinlẹ naa.
Abẹnugan ile igbimọ Aṣofin nipinlẹ Ogun, Olakunle Oluomo naa ti ni o da oun loju pe awọn yoo buwọlu abadofin naa ni Oṣu Keji, ọdun 2021.
Olakunle Oluomo fikun wi pe gbogbo awọn ti ọrọ naa kan, gbọdọ fi ọwọ sowọpọ pẹlu ijọba, ki abadofin naa le kẹsẹ jari.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi Makinde
Ewu ń bẹ pẹ̀lú kíkó Amotekun lọ Oke Ogun-Ibarapa lórí ọ̀rọ̀ Fulani - Baajigan Ilaji Ile
Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe Baajigan Ilu Ilaji Ile, nijọba ibilẹ Iwajowa nipinle Oyo, Oba Lawal Oyeleye Oyedepo ti woye pe ewu n bẹ loko Longẹ pẹlu bi ijọba ipinlẹ Oyo ti pàṣẹ pe ki igba ẹṣọ eleto abo Amọtẹkun lọ si agbegbe Ibarapa.
Ikọ Amotekun naa nijọba ni yoo lọ dẹkun aawọ to n ṣẹlẹ laarin awọn eeyan agbegbe naa atawon Fulani darandaran.
Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, Baajigan ni ko sí apa ẹni to ka awọn ẹṣọ Amọtẹkun nitori wọn o sí labẹ ijọba ibilẹ.
- Bí Sunday Igboho bá tàpá sófin, kí lẹ ṣe fáwọn ọ̀daràn Fulani tó ń pa èèyàn - Gani Adams
- Sunday Igboho ṣọ́ra ṣe, jẹ́ kí Seyi Makinde ṣiṣẹ́ tí òfin gbé le lọ́wọ́ - Ooni Ife
- Ẹlẹ́nu méjì ni ìjọba Buhari, òun ló ń pín Nàíjíríà yẹ́lẹyẹ̀lẹ - Wole Soyinka
- Wo ìgbẹ̀yìn àwọn ọlọ̀tẹ̀ Yorùbá tó ran Fulani lọ́wọ́ láti kógun ja ìlú Osogbo
- Ẹ múra mi sílẹ̀ ẹ̀yin apààyàn Fulani ní Ogun, mò ń bọ̀ kánkán - Sunday Igboho
- Àwọn olóṣèlú ti ń fowó bẹ̀ mí kí n má bá Fulani jà torí ìbò 2023, àmọ́ o ti bọ́ - Sunday Igboho
- Sunday Igboho kò lẹ́tọ̀ọ́ láti lé Fulani nílùú, wọ́n sì le pè é lẹ́jọ́ - Femi Falana
- Wò ó bí Afọnja ṣe finú wénú pẹ̀lú Fulani ní Ilọrin títí tó fi jẹ iwọ
- Seyi Makinde lo ṣí ilé mi tó jóná pẹ̀lú ‘transformer 500kva’ - Sunday Igboho
Kabiyesi Oyedepo sọ pe, awọn ẹṣọ Amọtẹkun ko niru nidi lo jẹ ki ọpọ ninu wọn maa ṣiwa hu s'awọn to ju wọn lọ.
Baajigan ilu Ilaji Ile ṣalaye pe, ati ọga ati awọn ọmọṣẹ Amọtẹkun, iwa kan naa ni gbogbo wọn jọ n hu.

Oríṣun àwòrán, @Muhammed Gumi
"Alaga ijoba ibilẹ kankan ko lagbara lori ẹṣọ Amọtẹkun, awọn mii n ṣiṣẹ daadaa lara wọn ṣugbọn awọn to n huwa aitọ lo pọju ninu wọn," Baajigan ṣalaye.
Ọba Oyedepo ni "laipẹ yii ni a ṣe ìpàdé pọ pẹlu DPO ọga ọlọpaa at'awọn ọtẹlẹmuyẹ ni ijọba ibilẹ Iwajowa, awọn Amọtẹkun ko wa nitori wọn ko si labẹ ijọba ibilẹ."
Iwa ika tawọn Fulani darandaran n hu fun wa l‘Oke Ogun buru jai:
Ọba Oyedepo tilu Ilaji Ile tun ṣalaye fun BBC Yoruba bi awọn Fulani darandaran ti da maalu ba ire oko awọn agbẹ jẹ lagbegbe Oke Ogun.
"Oko agbado eeka mẹwaa ti emi gan an ti mo jẹ ọba da, gbogbo rẹ lawọn Fulani fi maalu jẹ tan.
Awọn Fulani yii tun maa n da maalu wọ aarin ilu, n ṣe lawọn maalu yii yoo fọn kaakiri ninu ilu, ohun ti wọn n ṣe fun wa buru jai," Ọba Oyedepo lo sọ bẹẹ.
Baajigan ilu Ilaji Ile wa rawọ ẹbẹ sí ijọba apapọ lati wa nnkan ṣe sí ọrọ eto abo to mẹhẹ lagbegbe Oke Ogun nipinlẹ Oyo.
Ẹwẹ, ọgagun ẹṣọ Amọtẹkun nipinlẹ Oyo kọ lati sọrọ nigba ti BBC Yoruba pè e lori ago.
O ni oun ni lati gba aṣẹ lọwọ ijọba, ki oun to le sọ ohunkohun nipa ọrọ naa.
Ìkórira ní kò jẹ́ kí alátakò rí aáyan mi lórí ààbò Oke Ogun àti Ibarapa - Seyi Makinde

Oríṣun àwòrán, Facebook/@OfficialSeyiMakinde
Gomina ipinlẹ Oyo, Onimọ ẹrọ Seyi Makinde ti fesi lori aayan rẹ lati mu ki eto aabo fẹsẹ rinlẹ lagbegbe Oke Ogun.
Makinde, ninu atẹjade kan ti amugbalẹgbẹ rẹ feto iroyin, Taiwo Adisa fisita salaye pe, lodi si ero awọn ẹgbẹ oselu alatako nipinlẹ naa, oun ti se isẹ takuntakun lẹka eto aabo.
Gomina Makinde ni oun ti ko dara ni bi ẹgbẹ oselu alatako se n tọwọ oselu bọ aifararọ eto aabo lagbegbe Oke Ogun ati Ibarapa, to fi mọ awọn agbegbe miran nipinlẹ Oyo.
- Seyi Makinde lo ṣí ilé mi tó jóná pẹ̀lú ‘transformer 500kva’ - Sunday Igboho
- Àwọn ọ̀tá kan ń lo ìwà akọni Sunday Igboho láti bà mí lórúkọ jẹ́ - Gani Adams
- Nkan márùn ùn nípa Ọgágun Attahiru, òkúta tí Burati kọ̀ sílẹ̀, tó padà di igun ilé
- N kò fẹ́ oyè ọ̀gá àgbà páta fún ikọ̀ Amotekun nílẹ̀ Yorùbá - Sunday Igboho yarí
- Sunday Igboho yarí lórí àwọn ‘ọ̀rọ̀ ìbajẹ́’ tí Babafemi Ojudu kọ nípa rẹ̀
- Àwọn jàǹdùkú yìnbọn sókè lọ́pọ̀ ìgbà kí wọn tó jó ilé Sunday Igboho - Ọlọ́pàá Oyo
- N kò le ṣàtìlẹyìn fún arúfin láti tán ìṣòro ètò ààbò - Seyi Makinde
- Àwọn ọ̀tá kan ń lo ìwà akọni Sunday Igboho láti bà mí lórúkọ jẹ́ - Gani Adams
- Ìkórira ní kò jẹ́ kí alátakò rí aáyan mi lórí ààbò Oke Ogun àti Ibarapa - Seyi Makinde
"Kedere ni aayan mi han fun araye nidi ipese eto aabo to peye si agbegbe Oke Ogun ati Ibarapa, koda, mo fi ikọ Operation Burst sọwọ sibẹ.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi makinde
Ogunlọgọ awọn ologun, ọlọpaa ati osisẹ aabo ara ẹni laabo ilu, Civil defence lo wa ninu ikọ alabo Operation Burst naa, ti wọn si kun awọn agbegbe mejeeji biba.
Bakan naa ni mo ti fi ikọ awọn ọlọpaa kogberegbe, Mopol sọwọ sibẹ, to si dabi ẹni pe ilu Agọ Are, ni Oke Ogun, gan ni ibujoko wọn wa bayii."
Makinde tun tẹ siwaju pe, ikọ Amotekun gan ti pọ bii esu lawọn agbegbe yii, ti isẹ akin ti wọn n se nibẹ si ti bẹrẹ si so eso rere.
O ni iwa tẹnbẹlẹkun, ikorira ati inunibini ni ko jẹ ki awọn alatako ri ọpọ aseyọri ijọba oun lẹka eto aabo naa, ti wọn si mọọmọ diju lati ri.
O wa mẹnuba awọn ọrọ to n tẹnu awọn eekan ninu ẹgbẹ oselu APC jade, to fi mọ Minisita feto ere idaraya, Sunday Dare, gẹgẹ bii eyi to ba ni ninujẹ.
" O se ni laanu pe iru eeyan to wa ninu igbimọ alakoso ijọba apapọ ti ko se aseyọri kankan lẹka eto aabo ilẹ Naijiria naa n sọrọ.
Amọ o se pataki ka jẹ ko mọ awọn aseyọri wa lẹka eto aabo, bo tilẹ jẹ pe a ko fẹ maa ba gba ọrọ bi ẹni gba igba ọti."
Makinde wa sọ fun awọn alatako rẹ pe, dipo ki wọn tọwọ oselu bọ ọrọ aabo yii, ko ba dara ki wọn kẹdun pẹlu awọn eeyan ipinlẹ Oyo nipa gbigbe ero gidi kalẹ lati mu agbega ba ipese eto aabo to pegede.
N kò le ṣàtìlẹyìn fún arúfin láti tán ìṣòro ètò ààbò - Seyi Makinde

Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi Makinde
Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe Gomina ipinlẹ Oyo, Enginia Seyi Makinde ti salaye pe ijọba oun ko le gbinyanju lati fopin si isoro aifararọ eto aabo nipa sise atilẹyin fawọn eeyan to n tẹ ofin loju.
Gomina Makinde, sisọ loju ọrọ naa lasiko to n sọrọ nibi ipade to waye nilu Akure laarin awọn gomina ilẹ Yoruba ati ẹgbẹ darandaran Miyetti Allah.
Makinde fikun pe isoro eto aabo ko le tan nilẹ tijọba ba se atilẹyin fun ẹni to ba n ru ofin lọwọ ara rẹ, to si n koro oro lai bọwọ fun ofin sawọn eeyan to gba pe wọn huwa aidaa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Mọ́tò mẹ́ta làwọn jàǹdùkú gbé wá sun ilé Sunday Igboho - Ará àdúgbò
- Àwọn ọ̀tá kan ń lo ìwà akọni Sunday Igboho láti bà mí lórúkọ jẹ́ - Gani Adams
- Kìí ṣe àgbẹ̀ nìkan ni ọ̀daràn darandaran n pa, wọ́n n pa àwa Fulani nàá - Ààrẹ Miyetti Allah
- Orí mi wú báwọn oríadé ṣe ní kò sí ààyè mọ́ láfi fi ọmọ Yorùbá ṣètùtù Nàìjíríà - Sunday Igboho
- Bukola Saraki sọ̀rọ̀ sókè lórí ìgbésẹ̀ Sunday Igboho
- Afurasí Fulani daran-daran fi ìbọn fọ́ ìka obìnrin kan lójú pópó
- Sunday Igboho sọ̀rọ̀ fún ìgbà àkọ́kọ́ lẹ́yìn àbẹ̀wò rẹ̀ sí Igangan
Makinde ni oun ko le se atilẹyin fun iru ẹni bẹẹ, to n huwa to le sọ orilẹede yii sinu ogun ẹlẹyamẹya , nitori o yẹ ka le mọ ohun ti yoo gbẹyin iru isẹlẹ bẹẹ.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi Makinde
O ni oun yoo yan lati se atilẹyin fun awọn agbofinro nipinlẹ oun ni, lati pese awọn eto iranwọ fun wọn, ti yoo jẹ ki wsn se isẹ wọn doju ami.
Gomina ipinlẹ Oyo tun sọ siwaju pe oun yoo se iranwọ fun ibagbepọ alaafia laarin awọn alamuleti oun nipa sise iwuri fun awsn eeyan ipinlẹ Oyo lati maa gbe pọ ni alaafia.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Seyi Makinde
O ni awsn yoo dijọ koju ọta awọn papọ ni, ti wsn jẹ ọdaran to wa ninu ẹya gbogbo, toun yoo si tun maa pese anfaani fawọn araalu, lọna ati mu ikayasoke ku laarin wọn.
Ẹ̀yin èèyàn ìpínlẹ̀ Oyo, mìmì kan kò lè mì yín lónìí- Makinde
Gomina ipinlẹ Oyo, Seyi Makinde sọ pe oun ti gbọ nipa awọn kan to n pin iwe fawọn Fulani lati kuro lori ilẹ wọn ni ipinlẹ Oyo.Ìjọba Oyo korò ojú sí ìròyìn tó ń jáde pé káwọn èèyàn Ibadan ó gbélé nítorí Igboho
Ti ẹ o ba gbagbe, ajafẹtọ Sunday Adeyemo ti ọpọ mọ si Sunday Igboho ti kọkọ fawọn Fulani to wa ni agbegbe Ibarapa nipinlẹ Oyo lati kuro lori ilẹ ti wọn wa lori ẹsun pe awọn lo wa nidi iṣẹlẹ ijinigbe ati iṣekupani to n ti waye kaakiri ipinlẹ naa.
Makinde ní ẹnikẹ́ni tó bá dúnkokò mọ́ Fulani láti kúró lórí ilẹ̀ Oyo yóò fojú winá òfin
Amọ, Makinde ni iwe ofin orilẹede Naijiria laa kalẹ pe awọn ọmọ Naijiria ni ẹtọ lati maa gbe lalaafia nibi kibi to ba wu wọn kaakiri orilẹede yii.
- Àwọn Ọba ló rànṣẹ́ pè mi pé ìyá ìjínigbé àti ìpànìyàn yì tó gẹ́- Sunday Igboho
- Ẹ wo ohun tí Seriki Fulani sọ fún gómìnà Makinde nípa Sunday Igboho
- Gbogbo ẹ̀yin Fulani darandaran tó wà ní ìgbó ìjọba ní Ondo, ọjọ méje lẹní láti pòórá - Gomina Akeredolu
- Ìgbìmọ̀ aláàṣẹ Nàìjíríà ti buwọ́lu ọjọ́ orí ìfẹ̀yìntì tuntun fún àwọn olùkọ́
- Ẹgbẹ́ Afenifere bu ẹnu ẹ̀tẹ́ lu Aárẹ Buhari lórí gbèńdéke tí Akeredolu fún àwọn darandaran Fulani
- Covid-19 ti ṣekúpa èèyàn 1,478 báyìí ní Nàìjíríà, 92,336 ti jàjàbọ́
Gomina ipinlẹ Oyo ni iwe ofin Naijiria yii ni oun bura pe oun ko ni tapa si gẹgẹ bi gomina.
''Ẹnikẹni to ba fi ipa mu ẹnikẹni lati kuro lori ilẹ ti wọn n gbe nipinlẹ Oyo yoo foju wina ofin,'' Makinde ṣalaye.
Gomina rọ ẹnikẹni to ba n gbero lati dunkoko mọ ẹnikẹni lati kuro nibi ti wọn n gbe wi pe ki wọn lọ ki ọwọ mọ bọ aṣọ.
Makinde ni ''Hausa tabi Fulani to n wa ibi ti yoo ti ko ẹran wọn jẹ oko kọ ni ọta wa nipinlẹ Oyo.'
Awọn ọta wa nipinlẹ Oyo kii ṣe awọn agbẹ to n dako lati jẹ ati lati ta fun araalu.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
''Ijọba wa n gbiyanju lati wa egbo egbo dẹkun fawọn janduku agbebọn atawọn ọdaran to n ṣọṣẹ ni ipinlẹ Oyo.
Bakan naa ni Makinde ke pe awọn lọbalọba lati maa gba ẹnikan kan laaye lati lo wọn da alaafia to wa ni ipinlẹ Oyo ru.
Makinde tun kepe awọn alaga ijọba ibilẹ kaakiri ipinlẹ Oyo lati ṣiṣẹ pọ pẹlu awọn lọbalọba atawọn agbofinro lati rii pe alaafia jọba.
- Kíní Kọmíṣọ́nnà Ọlọ́pàá, mẹ̀kòó ṣe tí wọ́n fi rí ẹ̀wọ̀n gbére he ní Ekiti?
- Bí ẹ bá tó bẹ́ẹ̀ ẹ pàdé mi l'Òjé- Makinde; Wọ́n ń tàn Ẹ́ bí àbẹ́là- APC
- Wo ǹkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa Joe Biden, aàrẹ tuntun ilẹ̀ America
- Lere Paimo ṣàlàyé bí fíìmù "Ogbori Elémosho" ṣe sọ ọ̀ di Olóyè MFR pẹ̀lú Dangote àti Adenuga
- "Adájọ́, ẹ má tú wa ká, mo sì nífẹ̀ẹ́ ọkọ mi bó tilẹ̀ jẹ́ pé alágbèrè pásítọ̀ ni"





















