Lere Paimo: Eda Onile-ola ṣàlàyé bí fíìmù "Ogbori Elemosho" ṣe sọ ọ́ di ìlúmọ̀ọ́ká

Oríṣun àwòrán, Twitter/Nollywood Circle
Awọn agba bọ, wọn ni ori lo mọ iṣẹ aṣela. Ohun lo difa fun agbaọjẹ oṣere tiata Yoruba, Oloye Lere Paimo ti iṣẹ to yan laayo sọ ọ di ilumọọka.
Nigba to b'awọn akọroyin sọrọ laipẹ yii, gbajugbaja oṣere naa ti inagijẹ rẹ n jẹ Eda Onile-ola ṣalaye bi fiimu itan Ogbori Elemosho ṣe ṣọ ọ di olokiki ninu ere tiata.
Ninu esi rẹ si ọrọ t'awọn oṣere kan ṣọ pe awọn kii ṣaaba fẹ ṣe fiimu to da lori itan ilẹ Yoruba nitori kii lowo lori bi awọn fiimu agbelewo to wọpọ lasiko yii, Oloye Paimo ni irọ nla ni.
- Seyi Makinde pàṣẹ fún àwọn ọlọ́pàá láti wádìí Sunday Igboho lórí gbèǹdéke tó fún àwọn Fulani
- Ẹ wo ohun tí Seriki Fulani sọ fún gómìnà Makinde nípa Sunday Igboho
- Gbogbo ẹ̀yin Fulani darandaran tó wà ní ìgbó ìjọba ní Ondo, ọjọ méje lẹní láti pòórá - Gomina Akeredolu
- Àwọn agbébọn ti yìnbọn pa igbákejì akọ̀wé FUTA
- Àwọn agbébọn ti jí àwọn arìnrìnàjò gbé ní ìpínlẹ̀ Osun!
- Iyaafin Fọlakẹ Arẹmu, Orisabunmi ti wọ káà ílẹ̀ sún
Eda Onile-ola ṣọ pe fiimu Ogbori Elemosho ti oun ṣe ta, ati pe fiimu yii lo mu ki ijọba apapọ foun loye MFR pẹlu awọn ilumọọka ọlọrọ bíi Aliko Dangote ati Mike Adenuga niluu Abuja.
"Koda ajọ awọn akọṣẹ-mọṣẹ olokowo, Chartered Institute of Commerce ṣẹṣẹ fi oye Ọmọwe da mi lọla ni, nibayii, orukọ mi ti di Oloye Ọmọwe Lere Paimo," Eda Onile-ola ṣalaye.
O ni lati inu fiimu itan ilẹ Yoruba loun ti ri awọn oye yii gba, nibẹ naa loun tun ti ra ọkọ oriṣiiriṣii
Eda Onile-ola ni nibi iṣẹ tiata yii naa ni oun ti ran awọn ọmọ lọ sile iwe. "Ẹ sọ fun mi kinni eeyan tun n wa laye?"
Agbaọjẹ oṣere yii bu ẹnu atẹ lu bi awọn oṣere asiko yii kii ti fẹ gbe ere jade lori itan ilẹ Yoruba.
O ni ọpọ awọn oṣere yii kii le ronu jinlẹ lati kọ iru itan bẹẹ ni.
Eda Onile-ola ni oun atawon akẹgbẹ oun ṣe iwadii lọdọ awọn agbaagba ilẹ Yoruba ki awọn to gbe ere bi Ogbori Elemosho ati Saworo Ide jade.
"Ṣugbọn iwa ainirẹlẹ ko le jẹ k'awọn ọmọ iṣẹyii to n ṣere tiata lọ b'awọn agbaagba fun iwadii lori ere," Oloye Paimo lo sọ bẹẹ.
- Kí ló ma n fa Àkúfà nílẹ̀ Yorùbá, àti ọ̀nà àbáyọ?
- Ọjọ́ orí wo ló yẹ kí ikùn ẹ̀dá bẹ̀rẹ̀ sí tóbi?
- Opral Benson, ẹni ti oge ṣíṣe sọ di gbajúmọ̀ àti Yeye Oge ìlú Eko
- Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ ńlà lọ́sẹ̀ tó kọjá tó fi mọ́ bí Covid-19 ṣe gbẹ̀mí èèyàn 23 lọ́jọ́ kan ṣoṣo
- Àbámọ̀ ni yóò gbẹ̀yin ẹgbẹ́ ''Association of Stingy Men'' tí kò fẹ́ náwó f'óbìnrin- Akeugbagold
Eda Onile-ola fikun ọrọ rẹ pe oun at'awọn akẹgbẹ oun ko yaju s'awọn ọga awọn, bẹẹ ni awọn si bọwọ fawọn to ju awọn lọ lọjọ ori.
"Mo fẹ da ileewe ikẹkọọ ere tiata silẹ nibi ti mo ti maa kọ̀ awọn ọdọ nipa ere ṣiṣe, itan kikọ ati ijo jijo ninu ere," Eda Onile-ola lo ṣalaye bẹẹ.
O ni iru awọn ere toun fẹ maa kọ awọn ọdọ gbọdọ kọ awọn eeyan lẹkọọ.
Lere Paimo ni ohun to fi dabi ẹni pe awọn eeyan ko ṣaaba ri oun ninu ere mọ ni pe awọn olootu ere ni ko ṣaaba pe oun atawon akẹgbẹ oun sí ere mọ.
Eda Onile-ola ṣọ pe iwa ti ko boju mu ni ki wọn maa kun atike soju ọdọ lati ṣe bi arugbo ninu ere nigba t'awọn agba oṣere wa nilẹ.
Gbajugbaja osere yii tun koro oju si bi ọpọ oṣere ti n bo ara, ṣi ara wọn silẹ ti wọn si n lo awọn ede ti ko dun un gbọ leti ninu ere.
O ni iru awọn iwa bayii ko ba aṣa Yoruba mu, ati pe oun at'awọn akẹgbẹ oun ko dan iru rẹ wo nigba t'awọn bẹrẹ ere tiata.
Oloye Paimo ni awọn kilọ ni aimọye igba fawọn oṣere to n huwa bayii, amọ ọpọ ninu wọn lo kọ eti ikun.
Ninu awọn ti Eledumare fi ẹbun ijo jijo jinki, ọkan ni Eda Onile-ola jẹ.
Oloye Paimo ni Eduwa fi ijo jijo rọ oun debi pe ko si akẹgbẹ oun kan to le jo bi oun ṣe n jo.
"Ijo ti mo n jo lo mu ki awọn kan gbe mi lọ si orilẹ-ede Amẹrika lọdun 2017 fun ayẹyẹ ọjọ ibi mi," Eda Onile-ola lo wi bẹẹ.
O ni ọpọ lo yanu nigba ti oun f'ẹsẹ rajo ti wọn si sọ pe oun n jo bi gbajugbaja olorin Juju, King Sunny Ade.
- Iyaafin Fọlakẹ Arẹmu, Orisabunmi ti wọ káà ílẹ̀ sún
- Seyi Makinde pàṣẹ fún àwọn ọlọ́pàá láti wádìí Sunday Igboho lórí gbèǹdéke tó fún àwọn Fulani
- Ìjọba àpapọ̀ gbé ₦10b kalẹ̀ fún ìpèsè abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19 alábẹ́lé
- Ọkọ̀ agbépo bẹ́ntiról kankan kò gbọdọ̀ gun afárá nípínlẹ Ogun mọ́ - Gomina Dapo Abiodun
- Fulani kìí ṣe ajínigbé! Akeredolu kò ní ká pòórá nínú igbó ìjọba l'Ondo, ohun tí Gómìnà sọ rèé...- Miyetti Allah





















