51595735Ọkùnrin kan rèé tó gé nǹkan ọmọkùnrin rẹ̀ lẹ́yìn tó fa igbó yó

Oríṣun àwòrán, Getty Images / BBC
Iroyin kan ti o jade lo ṣàfihàn pé ọkùnrin kan, ẹni ọdún mẹ́tàlélógún gé okó rẹ̀ lẹ́yìn tí igbó tó fà yí i lórí.
Iroyin naa tí Journal of Medical Case Report gbé jáde ní ọkùnrin ará Thailand náà tó ti n mu igbo fun ọdún méjì kó tó fi igbo mimu kalẹ̀ tó sì padà sídìí rẹ̀ lẹ́yìn oṣù mẹ́ta.
Wọ́n ní lẹ́yìn wákàtí méjì tó mu gírààmù méjì ni okó rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí ní le, tí nǹkan ọmọkùnrin rẹ̀ sì bẹ̀rẹ̀ sí ní dùn ún.
- 'Gbogbo ẹ̀yà ara Bamise Ayanwole ló pé nígbà tí mo rí òkú rẹ̀'
- A ti rí ilé ti à ń lọ lọ́ọ̀kán báyìí díẹ̀ ló kù - Ọ̀jọ̀gbọ́n Banji Akintoye lásíkò àjọyọ̀ ìtúsílẹ̀ Sunday Igboho
- Ademola Adeleke ní igun kíni PDP ní Osogbo fà kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọmọ oyè láti díje dupò gómìnà Osun
- Timothy Adegoke: Ìyàwó Timothy Adegoke jẹ́rìí nípa ọkọ rẹ̀ nílé ẹjọ́, gbọ́ nípa ìjà tó jà fún ọkọ̀ rẹ̀
- Ademola Adeleke ní igun kíni PDP ní Osogbo fà kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọmọ oyè láti díje dupò gómìnà Osun
Kini o wa selẹ̀ sii leyin naa?
Bákan náà ló ní ó jọ pé okó òun yàtọ̀ sí bó ṣe rí tẹ́lẹ̀, tó sì rò wí pé òun le mú àdínkù bá ìnira tó ń kó bá òun, ló bá fa abẹ yọ láti gé kúrú.
Ìjábọ̀ náà ní lẹ́yìn wákàtí méjì tí ẹ̀jẹ̀ kò dá ni ọkùnrin náà di èrò ilé ìwòsàn.
Àwọn Dókítà ní àwọn kòkòrò ti wọ èyí tó gé kúrò, tí èyí tó kù lára rẹ̀ kò sì ju sẹ̀ǹtímítà méjì lọ mọ́ tí ó sì ti ge kọjá àtúnṣe.
Bawo ni aago ara rẹ̀ se wa ri bayii?
Bákan náà ni wọ́n ní ara rẹ̀ ti ń balẹ̀ lẹ́yìn tó ti ń gba ìtọ́jú.
Onímọ̀ tó ṣaájú ìwádìí náà, Nantanan Jengsuebsant ní irú ohun tó ṣe ọkùnrin ọ̀hún kìí sábà wáyé lọ́pọ̀ ìgbà àti pé káàkìri ayé ni igbó ti jẹ́ ṣíṣe àmúlò.
Ìroyin náà tẹ́síwájú pé lára àwọn ohun tí igbó máa ń fà fún àgọ̀ ara náà ní orí yíyí.














