Couple death: Ó ṣe! tọkọtaya yìí papòdà láàrín oṣù mẹ́sàn-án síra wọn

Oríṣun àwòrán, @Odunukwe
Awayé kan kò sí, kò sí ẹni tí kò ní kú, kò sí ẹni tí ìta baba rẹ̀ kò ní dìgboro ṣùgbọ́n ọkàn ẹni a máa gbọgbẹ́ tí àwọn ọ̀dọ́ tàbí ẹni tó bá súnmọ́ ni bá fi ayé sílẹ̀.
Omijé gbojú àwọn mọ̀lẹ́bí tí ọkàn wọn sì gbọgbẹ́ bí àwọn tọkọtaya Chukwuemeka Odunukwe àti Chineye tó papòdà láàárín oṣù mẹ́sàn-án síra wọn ní ìpínlẹ̀ Anambra.
Àwọn tọkọtaya náà ló ti ṣe ìgbéyàwó ní ìlànà ìbílẹ̀, tí wọ́n sì ń palẹ̀mọ́ fún ìgbéyàwó ní ìlànà ìgbàlódé kí ọlọ́jọ́ tó dé.
- Wo àwòrán lóríṣìíríṣìí tó jádé níbí ètò ìsìnkú Adebayo Alao Akala
- Àwọn aláṣẹ UK ti ṣèkìlọ̀ kónílé gbélé fún àwọn ènìyàn nítorí ìjì líle
- Sunday Igboho kò le wà ní àhámọ́ kí èmi máa ṣe wẹ̀jẹ-wẹ̀mu - Ọ̀jọ̀gbọ́n Banji Akintoye, Olórí Ẹgbẹ̀ ìlànà ọmọ Oòduà
- Wo ìlú tí wọ́n ti fòfin dé yíya àwòrán ṣaájú ìgbéyàwó ìyẹn "pre wedding picture" àti ètò ìgbéyàwó mìíràn
- Gboyega Oyetola, Moshood Adeoti àti Lasun Yusuf ni yóò jọ ná an tán bí owó lónìí láti mọ ẹni ti yóò dupò gómìnà Osun
- Só lè jẹ búrẹ́dì tí wọ́n fi Aáyán se?
- Èèyàn mẹ́tàlá jáde láyé léyìn tí wọ́n já sínú kànga níbi ayẹyẹ ìgbéyàwó
Bawo ni ọrọ ṣe jẹ?
Ìṣẹ̀lẹ̀ yìí wáyé ní Nnobi, ìpínlẹ̀ Anambra tó jẹ́ ìlú àwọn méjéèjì.
Àwọn mọ̀lẹ́bí tí ń gbèrò láti ṣe ayẹyẹ ìkẹyìn fún àwọn méjéèjì papọ̀ báyìí.
Súfèsúfè ló pa ọmọ m- Iya Chukuemeka
Mary Odunukwe, ìyá Chukwuemeka nígbà tó ń bá BBC sọ̀rọ̀ ní ṣàdédé ni ọmọ òun bẹ̀rẹ̀ sí ní súfèsúfè lọ́jọ́ kan nígbà tó ń tajà lọ́wọ́, tí àwọn sì rò pé bóyá nítorí pé ọmọ òun kìí mu omi dada ló fàá.
Mary ní kìí ṣe pé àìsàn yìí dá ọmọ òun gúnlẹ̀ nígbà tó bẹ̀rẹ̀ nítorí kò dáa dúró láti ṣiṣẹ́ ṣùgbọ́n tó búrẹ́kẹ́ sí i lẹ́yìn tí ó ṣe ìgbéyàwó tán.
Ó ní nígbà tí àìsàn náà pọ̀ ju agbára lọ, kò sí ilé ìwòsàn tí àwọn kò gbé Chukwuemeka lọ ṣùgbọ́n kò sí ìyípadà kankan à fi ìgbà tí àwọn ti ẹsẹ̀ ilé bọ̀ọ́.
Ó fi kun orí àárẹ̀ náà ni ó kú sí ní oṣù kejì ọdún tó kọjá tí àwọn sì sín lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ nítorí ọ̀nà tó gbà kú àmọ́ àwọn kò ì tíì ṣe ẹ̀yẹ ìkẹyìn fún un.
Mary ṣàlàyé pé Chukwuemeka tó kú ní ẹni ọdún mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ni àkọ́bí òun, ọmọ mẹ́rin sìni òun bí.
Ọkàn Chinenye gbọgbé nígbà tí ọkọ rẹ̀ kú - ìyá Chukwuemeka
Ìyá Emeka ní nínú oṣù kẹjọ, ọdún 2020 ní Chinenye àti Chukwuemeka fẹ́ ara wọn ṣùgbọ́n tí ọmọ òun kú nínú ọṣù kéjì, ọdún 2021.
Ninu ọrọ iya rẹ: "Ikú Chukwuemeka dùn Chinenye púpọ̀ kódà ó dá àárẹ̀ si lára."
"Lẹ́yìn ọsù mẹ́sàn-án tí ọmọ mí kú náà ni Chinenye náà fò ṣánlẹ́ tó rọ̀run alákeji."
"Orí fífọ́ ló ń pariwo fún ọ̀sẹ̀ méjì kó tó jáde láyé."
Nínú oṣù keji ọdún 2022 ní wọ́n fẹ́ ṣẹ̀yẹ ìkẹyìn fún wọn
Mary ní láti ìgbà tí Chinenye ti kú lọ́dún tó kọjá, wọn ò tí ì sín ṣùgbọ́n àwọn ti sin Chukwuemeka.
Bákan náà ló ní nínú oṣù keji, ọdún 2022 ní wọ́n fẹ́ sin Chinenye tí àwọn yóò sì ṣẹ̀yẹ ìkẹyìn fún wọn papọ̀.
Ọmọ ọdún kan ló gbẹ̀yìn àwọn méjéèjì.
- Gómìnà Zulum ṣe ìkìlọ̀ lórí ìdúnkookò ikọ̀ agbéṣumọ̀mí ISWAP sí Nàìjíríà
- Amotekun Ondo gbẹ́sẹ̀lé ọkọ̀ àjàgbé tó ń kó àwọn ọ̀dọ́ 63 láti Gombe lọ sí Eko
- Kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn rẹ láti yé da àlááfíà ìlú láàmú- Ìjọba ìpínlẹ̀ Osun sí Aregbesola
- EFCC gbẹ́sẹ̀lé dúkìá ọ̀gá olọgun tí iye rẹ̀ tó ₦10.9b
- Algeria yóò bẹ̀rẹ̀ sí ní san N41,000 fáwọn ọ̀dọ́ tí kò rí iṣẹ́ ṣe lóṣù tó ń bọ̀
- Olaleye Paul rí ẹ̀wọ̀n he ní àyájọ́ olólùfẹ́ ní Ilọrin
- Awakọ̀ dáná sun ara rẹ̀ lórí bí àwọn 'task force' ṣe mu l'Eko
- Ẹ̀kún omi gbé èèyàn méjìdínlógójì lọ nílùú Petrópolis ní orílẹ́èdè Brazil



















