Wo ìlú tí wọ́n ti fòfin dé yíya àwòrán ṣaájú ìgbéyàwó ìyẹn "pre wedding picture" àti ètò ìgbéyàwó mìíràn

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Báyìí là ń ṣe nílé wa èèwọ̀ ilẹ̀ ibòmíràn.
Ìgbìmọ̀ tó ń rí sí ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn Islam ní ìjọba ìbílẹ̀ Mayo Belwa ní ìpínlẹ̀ Adamawa ní àwọn ti fòfin de ṣíṣe àwọn ayẹyẹ kan ṣaájú àti lẹ́yìn ìgbéyàwó kí ìbágbépọ̀ tọkọtaya lé rọrùn si.
Gẹ́gẹ́ bí àgbékalẹ̀ ìgbìmọ̀ yìí ṣíṣe ayẹyẹ patí "Cocktail", ọjọ́ abúlé (Village Day), Luncheon, àyájọ́ Fulani (Fulani day), àti Budar Kai ti di èèwọ̀ níbi ayẹyẹ ìgbéyàwó.
Láti àsìkò yìí lọ, tí òfin náà bá fi ẹsẹ̀ rinlẹ̀, ṣíṣe àmúlò orin níbi ètò ìgbẹyàwó yóò di ohun ìgbàgbé.
- Oríṣìíríṣìí aṣọ aláràǹbarà láwọn òṣèré tíátà fi ṣe àyájọ́ ọjọ́ olólùfẹ́
- Ẹgbẹ́ Olùkọ́ Fásitì ASUU bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì olóṣù kan lónìí
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá dárúkọ àwọn ọlọ́pàá mẹ́rin tó ń bá Abba Kyari ṣiṣẹ́ pẹ̀lú àwọn tó ń gbé oògùn olóró
- Ki lo ṣokunfa ikọlu to n waye si ẹni to ba wọ aṣọ Sunday Igboho tabi Yoruba Nation n'Ibadan?
- Ọmọ ọdún 18 dèrò àtìmọ́lé lórí ẹ̀sùn pẹ ó gún akẹgbẹ́ lọ́bẹ pa
- Barrister ló sọ mí di èèyàn ńlá - Ayinla Kollington
- Afurasí tọkọtaya ta ẹ̀yà ara ní ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́rin náírà- Ọlọ́pàá
Kini Igbimọ naa fi sita?
Abẹnugan ìgbìmọ̀ náà, Ahmadu Liman Aminu ní àwọn gbe ìgbésẹ̀ yìí láti mú kí ètò ìgbéyàwó rọrùn fún àwọn ọ̀dọ̀ tó ń gbèrò láti ṣe ìgbéyàwó.
Nígbà tó ń ṣàlàyé fún BBC Hausa ìdí tí àwọn fi gbé ìgbésẹ̀ náà, Ahmadu ní nítorí à ti mú àdínkù bá iye owó tí àwọn ènìyàn ń ná lórí ìgbéyàwó lásìkò yìí pẹ̀lú bí nǹkan kò ṣe fararọ ní orílẹ̀ èdè wa ló fà á tí àwọn fi ṣe òfin náà.
Bákan náà ló ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀dọ̀ ni kò fẹ́ ṣe ìgbéyàwó mọ́ nítorí owó gege tí wọ́n ń ná láti fi ṣe ìgbéyàwó à ti pé ọ̀pọ̀ àṣà àti ìṣe ni wọ́n ń tẹ̀ lójú mọ́lẹ̀, èyí tó fàá tí àwọn ọmọdé kò ní ẹ̀kọ́ tó bẹ́ẹ̀ mọ́.
- Àwọn tọ́ọ̀gì Aregbesola ló da wàhálà sílẹ̀ l'Osun - Ọlọ́pàá
- Wo ohun méjé tó yẹ kí o mọ̀ nípa Abba Kyari, ọ̀gá ọlọ́pàá tí wọ́n fẹ̀sùn ìwà ọ̀daràn kàn
- Ìjọba Canada ṣetán láti gbẹ́sẹ̀ lé àkáùntì àwọn tó ń ṣẹ ìwọ́de táko abẹ́rẹ́ covid-19
- Awakọ̀ dáná sun ara rẹ̀ lórí bí àwọn 'task force' ṣe mu l'Eko
- Olaleye Paul rí ẹ̀wọ̀n he ní àyájọ́ olólùfẹ́ ní Ilọrin
- Iléẹjọ́ tún sún ìgbẹ́jọ́ olórí ẹgbẹ́ IPOB Nnamdi Kanu síwájú
- Wo ọkùnrin kan tó fi N1.2m gbẹ́ ibojì rẹ̀ sílẹ̀ nígbà tó sì wà láàyè
Ọ̀nà wo ní wọ́n fẹ́ gbà láti fi fi òfin náà múlẹ̀?
Ahmadu ní pé ẹni tí ó bá kọtí ọ̀gbọin sí òfi tuntun yìí, àwọn yóò kọ̀ọ́ tì nínú ìlú, tí àwọn kò ní dá sí gbogbo ayẹyẹ tó bá ń ṣe ìbáà jẹ́ ìgbéyàwó tàbí ìkómọ.
Ó ní kódà bí ẹni náà bá kú, àwọn kò ní yọjú síbi ètò ìsìnkú ẹni náà.
Àwọn ìgbésẹ̀ mìíràn tí wọ́n tún gbé
Ìgbìmọ̀ náà tún ní àpótí tí àwọn ẹbí máa ń gbà lásìkò ayẹyẹ ìgbéyàwó kò gbọdọ̀ ju méjì lọ báyìí mọ́ tí àwọn nǹkan tí wọ́n yóò kó sínú rẹ̀ jẹ́ aṣọ ìró méje, bàtà mẹ́ta, gèlè mẹ́ta, hìjáàbù mẹ́ta, yẹtí mẹ́ta àti ẹ̀gbà ọwọ́ àti tọrùn mẹ́ta mẹ́ta.
Bákan náà ni wọ́n ó ti di èèwọ̀ láti máa gba owó lọ́wọ́ ọkọ tàbí ẹbí rẹ̀ yàtọ̀ sí owó orí.
Wọ́n tún ṣe àjọ tí yóò máa ṣe ìdánilẹ́kọ̀ọ́ fún àwọn tó bá fẹ́ ṣe ìgbéyàwó.
Kí ni èrò àwọn ará ìlú?
Nígbà tí akọ̀ròyìn BBC, Salihu Adamu bá àwọn tó ń gbèrò láti ṣègbéyàwó lópin ọ̀sẹ̀ yìí láti sọ ohun tí wọ́n rò lórí ìgbésẹ̀ ìgbìmọ̀ náà, wọ́n ní àwọn faramọ́.
Lára àwọn tó sọ̀rọ̀ ní pé nígbà tí èèyàn bá fẹ́ ṣe patí ṣùgbọ́n tí owó tí yóò fi pe eléré ti pọ̀jù láìsí ní owó lọ́wọ́ kìí ṣe ohun tó dára tó.
Wọ́n ní àwọn faramọ́ ìgbésẹ̀ yìí àti pé gbogbo àwọn àwòrán náà kò wúlò.



















