Sunday Igboho supporters: Ki lo ṣokunfa ikọlu to n waye si ẹni to ba wọ aṣọ Sunday Igboho tabi Yoruba Nation n'Ibadan?

Oríṣun àwòrán, Sunday Igboho
Ọkan lara awọn ọmọlẹyin Oloye Sunday Adeyẹmọ ti ọpọ eeyan mọ si "Sunday Igboho", Ọmọọba Omiyale Ademọla ti ke gbajare sita.
O ni pe awọn eeyan kan ti fọn si igboro ilu Ibadan ti wọn si deede n ṣe ikọlu si ẹnikẹni ti wọn ba ri to wọn aṣọ ti o ba ni akọle 'Sunday Igboho' tabi ipe fun idasilẹ orilẹede Oodua, 'Yoruba Nation' lara.
Ninu ọrọ ti o ba BBC Yoruba sọrọ l'ọjọ Aje nile Sunday Igboho to n bẹ ni agbegbe Soka nilu Ibadan, Ademọla ni iṣẹlẹ naa ti n waye fun igba diẹ bayii.
O ni, "O ti maa n waye lati ọjọ bi i melo kan sẹyin.Àwọn jàndùkú agbébọn tún kọlu ilé Sunday Igboho, èèyàn kan dèrò ọ̀run
Ni eyi to jẹ wi pe ẹnikẹni ti o ba ti wọ aṣọ Oloye Sunday Igboho tabi to de fila Yoruba Nation, to ba jẹ pe ori okada ni wọn a jaa bọlẹ, wọn a ṣee leṣe, wọn a gun un yanayana.
- Àwọn jàndùkú agbébọn tún kọlu ilé Sunday Igboho, èèyàn kan dèrò ọ̀run
- Àjọ NDLEA ń wá ọ̀gá ọlọ́pàá Abba Kyari lórí ẹ̀sùn gbígbé òògùn olóró ''cocaine''
- Àgbáríjọpọ̀ èèyàn sẹkúpa ọkùnrin kan lórí ẹ̀sùn pé ó dáná sun Kurani
- Ará àdúgbò dáná sun afurasí méji tí wọ́n bá orí èèyàn lọ́wọ́ wọn ní àgọ́ ọlapàá ní Abeokuta
- Wọ́n ti rí òkú eèyàn mẹ́ta yọ kúrò lábẹ́ ilé tó dàwó ní Yaba
- Mubarak, tó bá ìṣẹ̀lẹ̀ ìdigunjalè Ibadan lọ ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ikú rẹ̀ - àwọn ọ̀rẹ́ kọrin arò lẹ́yìn rẹ̀
Awọn ẹri wa nibi, to jẹ ẹri maa jẹ mi niṣo".
Ademola ni pe: "Nigba ti awọn ọrọ yii bẹrẹ, Mọlete lo ti kọkọ bẹrẹ. Eeyan wa n jade lọ ibi iṣẹ rẹ, kodaa ọkada rẹ ṣi wa pẹlu wọn ti wọn ko ti i gbee silẹ titi di oni. Ki i ṣe ọlọkada, o n lọ ibi iṣẹ ẹni.
Wọn dẹ daa duro, wọn dẹ ṣaa yanayana".
Ademọla tẹsiwaju pe ikọlu to waye gbẹyin ni nnkan bi i aago mẹsan aabọ owurọ ọjọ Abamẹta ṣẹlẹ si arakunrin kan ti o maa n se asun fun awọn eeyan ninu ile Oloye Sunday Igboho, ti o si tun un ṣe iṣẹ afẹfẹ gaasi ẹro to n mu ile ati ọkọ tutu.
- "Ẹ̀yin obìnrin, ẹ fi òdòdó ṣe ẹ̀bùn ọjọ́ olólùfẹ́ fún ọkùnrin dípò kẹ gbà kó já òdòdó ara yín"
- Àjọ NDLEA ń wá ọ̀gá ọlọ́pàá Abba Kyari lórí ẹ̀sùn gbígbé òògùn olóró ''cocaine''
- Àgbáríjọpọ̀ èèyàn sẹkúpa ọkùnrin kan lórí ẹ̀sùn pé ó dáná sun Kurani
- Ẹgbẹ́ Olùkọ́ Fásitì ASUU bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì olóṣù kan lónìí
- Olùkọ́ lu akẹ́kọ̀ọ́ rẹ ọmọ ọdún kan àti oṣù méje pa ní ìpínlẹ̀ Delta, O bọ́ sí gbaga ọlọ́pàá
Arakunrin naa n lọ si ẹnu iṣẹ l'owurọ ọjọ Abamẹta. Nigba to de ibudoko to n bẹ ni agbegbe Soka ni awọn eeyan kan wọọ bọlẹ lori ọkada pe ọmọ Igboho ni.
Arakunrin naa beere ẹṣẹ ti oun ṣẹ, wọn ni, "Ẹyin lẹ ni ko ni si eto idibo lọdun 2023, ẹyin lẹ ni Yoruba kan ni. Ẹ pe ọga yin nisin, ṣebi o n bẹ ninu ẹwọn".

Lẹyin eyii ni wọn bẹrẹ sini na arakunrin naa titi ti wọn fi gun un ni nnkan ni agbọn, ti ẹjẹ si boo.
Ademọla fi kun ọrọ rẹ pe wọn gbe arakunrin naa lọ si agbegbe New Garrage lẹyin ti wọn luu tan.
O ni lẹyin eyii ni awọn dede n gburo awọn ọkọ kan ti o to tẹle ara wọn ti wọn si sare kọja niwaju ile Sunday Igboho.
Eruku awọn ọkọ naa ti wọn ri lo mu ki ọkan ninu awọn to n gbe ile Sunday Igboho ti wọn pe orukọ rẹ ni "Kokoro" pẹlu awọn akẹgbẹ rẹ ti wọn gbe ara wọn si ori okada ni meji meji, lẹpa awọn ọkọ naa lọ.

Ademọla ni bi awọn ọkọ naa ṣe jade si agbegbe Soka ni wọn mu ori le ọna Iwo Road ti wọn di doju ibọn kọ awọn to n lepa wọn lati ile Sunday Igboho.
Ninu iṣẹlẹ yii ni arakunrin ti wọn pe orukọ rẹ ni "kokoro" ti padanu ẹmi rẹ, ti awọn to ku si fi ara pa. Titi di asiko yii sini wọn n wa ibi ti oku arakunrin naa wa.
Bo tilẹ jẹ wi pe Ademọla ko da oruko ẹni kan ni pato, o ni oun mọ awọn to yin ibọn naa.
O kesi Gomina Ṣeyi Makinde lati gbe igbesẹ ti to tọ lori eto aabo n'ipinlẹ Ọyọ, nitori ipenija eto aabo ti dawọ duro n'ipinlẹ naa ki ijọba tuntun to gun ori aleefa.
















