2022 ASUU strike: Ẹgbẹ́ Olùkọ́ Fásitì ASUU bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì olóṣù kan lónìí

Oríṣun àwòrán, Others
Ẹgbẹ́ Olukọ awọn ile ẹkọ giga Fasiti Naijiria bẹrẹ iyanṣẹlodi oloṣu kan lonii ọjọ Aje, ọjọ kẹrinla, oṣu keji, ọdun 2022.
Ojogbon Musa Abdullahi tó jẹ akọwe iṣẹ iwadii ati eto gbogbo fun ẹgbẹ ASUU ṣalaye fun BBC pe iyanṣẹlodi naa jẹ ikilọ fun ijọba Naijiria lati mu adehun wọn ṣẹ.Ẹgbẹ́ Olùkọ Fásitì ASUU bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì olóṣù kan lónìí
Ki tun ni ASUU tun sọ lori iyanselodi naa?
Ojọgbọn Musa Abdullahi sọ pe ni ọrọ UTAS ti wọn jọ n fa lati 2009 ati adehun ti ijọba sọ ni wahala.
Egbẹ Olukọ naa ni pe ohun lo ṣokunfa ipade ọlọjọ meji ni ipinlẹ Eko ni eyi ti wọn ti wa fi ẹnu ko lori iyanṣẹlodi naa.
- Àjà ilé ọtí dàwó ní London, mẹ́tàlá nínú àwọn oníbàárà farapa
- Olùkọ́ lu akẹ́kọ̀ọ́ rẹ ọmọ ọdún kan àti oṣù méje pa ní ìpínlẹ̀ Delta, O bọ́ sí gbaga ọlọ́pàá
- Àwọn agbébọn ti yìnbọn pa ọlọ́pàá ní Enugu, kọlu àgọ ọlọ́pàá ní Anambra
- Wo ǹkan márùn ún tí ọ̀pọ̀ èèyàn kò fẹ́ ní 'Valentine' 2022
- Ará àdúgbò dáná sun afurasí méji tí wọ́n bá orí èèyàn lọ́wọ́ wọn ní àgọ́ ọlọ́pàá ní ọjà ọ̀dàn
- Ìdí tí mo fi ní ọ́jọ́ ikú ni ọ̀la ọjọ́ 'Valentine' fún àwọn kan- Mike Bamiloye
- Olubadan tuntun yóò di mímọ̀ lọ́jọ́ Ajé - Gómìnà Makinde

Oríṣun àwòrán, @ASUU
Ǹjẹ́ lóòótọ́ ni ASUU yóò bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì lónìí? ni ibeere ti ọpọ n beere kaakiri Naijiria bayii.
Ìgbìmọ̀ aláṣẹ ẹgbẹ́ àwọn olùkọ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga fásitì ilẹ̀ Nàìjíríà (ASUU) ti ní lónìí làwọn yóò forí ìkokò sọ̀ọ́dún lórí ìpinu wọn láti gùnlé ìyanṣẹ́lódì.
Láti ọjọ́ Àbámẹ́ta ni ẹgbẹ́ náà ti bẹ̀rẹ̀ ìpàdé ọlọ́jọ́ méjì láti fẹnukò lórí ìpinu wọn bóyá wọn yóò bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
Ó ṣeéṣe kí ẹgbẹ́ àwọn olùkọ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga fásitì, ASUU bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì láìpẹ́
- Àjà ilé ọtí dàwó ní London, mẹ́tàlá nínú àwọn oníbàárà farapa
- Wo ǹkan márùn ún tí ọ̀pọ̀ èèyàn kò fẹ́ ní 'Valentine' 2022
- Orílẹ̀-èdè méjìlá pàṣẹ̀ pé kí àwọn eèyàn wọn kúrò ní Ukraine nítorí ogun Russia tó súnmọ́ tòsí
- Ará àdúgbò dáná sun afurasí méji tí wọ́n bá orí èèyàn lọ́wọ́ wọn ní àgọ́ ọlọ́pàá ní ọjà ọ̀dàn
- Àwọn agbébọn ti yìnbọn pa ọlọ́pàá ní Enugu, kọlu àgọ ọlọ́pàá ní Anambra
- Ìdí tí mo fi ní ọ́jọ́ ikú ni ọ̀la ọjọ́ 'Valentine' fún àwọn kan- Mike Bamiloye
Kini ẹgbẹ ASUU n sọ bayii?
Ṣé lóòtọ́ ní ẹgbẹ́ Olùkọ́ Fásiti, ASUU ti bẹ̀rẹ̀ ìyanṣẹ́lódì?
Ní àṣálẹ́ ọjọ́ Àìkú ni Ààrẹ ẹgbẹ́ ASUU, ọ̀jọ̀gbọ́n Emmanuel Osodeke fi àtẹ̀jáde kan sórí ẹ̀rọ ayélujára Twitter rẹ̀ pé àwọn yóò gùnlé ìyanṣẹ́lódì ṣùgbọ́n ìfẹ́ àwọn ọmọ ẹgbẹ́ àwọn ṣe pàtàkì.
Osodeke ní ọjọ́ Ajé, ọjọ́ kẹrìnlá , oṣù kejì ni ìyanṣẹ́lódì náà yóò bẹ̀rẹ̀ títí di ìgbà tí ìjọba bá dáhùn gbogbo ohun tí àwọn ń bèèrè fùn ún.
Láti ìgbà pípẹ́ ni ASUU àti ìjọba àpapọ̀ ti ń ṣe ìfaǹfà láàárín ara wọn lórí àdéhùn tí ìjọba ṣe fún ẹgbẹ́ ASUU lọ́dún 2009.
Ní ọ̀sẹ̀ tó kọjá, ASUU ní kí àwọn ilé ẹ̀kọ́ gíga káàkiri orílẹ̀ èdè má wọ yàrá ìkẹ́kọ̀ọ́ láti fi ẹ̀hónú wọn hàn sí ìjọba lórí ìyanṣẹ́lódì tí wọ́n ń gbèrò.
Ilé ẹ̀kọ́ gíga Bayero, Kano ló kọ́kọ́ bẹ̀rẹ̀ èyí lọ́jọ́ Ajé, ọjọ́ keje, oṣù kejì tí àwọn ilé yòókù náà sì tẹ́wọ́ gbàá nínú ọ̀sẹ̀ kan náà.
Kí ló ti ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn?
Ní ọjọ́ kẹẹ̀dógún, oṣù kọkànlá, ọdún 2021, ASUU fún ìjọb àpapọ̀ ní gbèdéke ọ̀sẹ̀ mẹ́ta láti dáhùn gbogbo ìbéèrè àwọn ṣùgbọ́n tí ìjọba kùnà láti ṣe.
Kini ASUU sọ fun BBC ni pato?
Nígbà tó ń ikọ̀ ìròyìn BBC sọ̀rọ̀, ọ̀jọ̀gbọ́n Osodeke ní láti oṣù kìíní ọdún 2021 ní ìjọba àpapọ̀ ti ṣe àdéhùn fún àwọn ṣùgbọ́n tí wọn kò ṣe àmúṣẹ rẹ̀ títí inú oṣù kejìlá.
Ósodeke ní láti ìgbà náà ni ìjọba ti ń fi òní dá ọ̀la fún àwọn tí àwọn sì fọwọ́ lẹ́rán nítorí ìfẹ́ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àti àwọn òbí wọn.
Ó fi kun pé gbogbo ọ̀nà tí àwọn mọ̀ ní àwọn ti sà láti fi bá ìjọba sọ̀rọ̀ ṣùgbọ́n kò so èso rere, fún ìdí èyí ìyanṣẹ́lódì ló kù láti lò.
ASUU kò ṣẹ̀ṣẹ̀ máa lọ ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ pípẹ́
Ní ọdún 2020, oṣù mẹ́jọ ni ASUU fi yan iṣẹ́ lódì, ìyanṣẹ́lódì náà bẹ̀rẹ̀ nínú ọsù kẹta tó sì parí nínú oṣù kejìlá lẹ́yìn tí ìjọba àti ASUU tọwọ́bọ àdéhùn.
Lẹ́yìn èyí ni ìjọba kéde pé àwọn ti fún ASUU ní ọgbọ̀n bílíọ̀nù Náírà ṣùgbọ́n ASUU ní àwọn kò rí omira débi tí wọn yóò rí ẹ̀jẹ̀ títí di àsìkò yìí.
ASUU ní ìjọba kò ì tíì mú àdéhùn wọn ṣẹ.
- Kọmísánnà ọlọ́pàá ní London kọ̀wé fi ipò sílẹ̀ torí ìkéde a kò nígbẹkẹ̀lé nínú rẹ mọ́
- Small Mummy, aláwàdà ọmọ ọdún mẹwàá gba ẹ̀bùn ọkọ̀ olówó iyebíye
- NNPC di ẹ̀bí ayédèrú epo tó wọ Nàìjíríà ru iléeṣẹ́ mẹ́rin
- Wo orílẹ̀èdè míì l‘Áfíríkà tí ìfipá gbàjọba tún ti ń rúgbó bọ̀
- Ìjọba Oyo gba adé lórí àwọn baálẹ́ àti Mogaji tí Ajimọbi sọ di ọba ní Ibadan
- Àìsàn wo ló ń ṣe Opeyemi Ayeola tó tún fi dèrò ilé ìwòsàn?
- Mo ní ẹ̀ṣọ̀ ara tó lé ní ₦300m láyé àkọ́kọ́, ti mo ń gbé òògùn olóró




















