Olubadan throne: Gómìnà Seyi Makinde ní ìgbìmọ̀ olóyè Ibadan ti fún òun lórúkọ Olubadan tuntun, ìkéde yóò wáyé lọ́jọ́ Ajé

Seyi Makinde n dọbalẹ fun Olubadan ana

Oríṣun àwòrán, Seyi makinde

Gomina ipinlẹ Ọyọ ti kede pe lọjọ Aje loun yoo kede Olubadan tuntun ti ilẹ Ibadan.

Ni ọjọ Satide ni gomina Ṣeyi Makinde sọrọ naa nibi eto igbalejo ayẹyẹ ogoji ọjọ isinku Olubadan to waja, Ọba Saliu Akanmu Adetunji.

Lara awọn eekan ilu Ibadan to wa nibi eto naa ni igbakeji gomina ipinlẹ Ọjọ, Onimọẹrọ Rauf Ọlaniyan, gomina ipinlẹ Ọyọ tẹlẹ, Sẹnetọ Rashidi Ladọja pẹlu Sẹnetọ Kola Balogun to n ṣoju ẹkun idibo guusu ipinlẹ Ọyọ nile aṣofin agba.

Kini Gomina Makinde tun sọ?

Gomina Makinde ni ọna ti la fun oun lati ṣe ikede Olubadan tuntun naa bayii lẹyin ti oun ti tẹwọ gba lẹta latọdọ igbimọ afọbajẹ ilẹ Ibadan lori ẹni ti ewe oye bọ le lori.

Gomina Makinde ṣalaye pe ọtọ laye ilu Ibadan, paapaa ti a ba n sọrọ oye jijẹ.

"Ibadan ko dabi awọn ilu miran nibi ti o ti n gba wọn to bii ọdun meje ki wọn to ri ọba jẹ lẹyin ti ọba kan ba gbesẹ."

Seyi Makinde nibi ayẹyẹ ogoji ọjọ Olubadan

Oríṣun àwòrán, Seyi makinde/ facebook

Saliu Akanmu Adetunji, ti a bi ni ọjọ kẹrindinlọgbọn oṣu kẹjọ ọdun 1928, waja ni ọjọ keji oṣu kini ọdun 2022.

Ẹni ọdun mẹtalelaadọrun ni nigba to ju awa silẹ nileewosan nla UCH.

Oun si ni olubadan kọkanlelogoji to jẹ.

Ọjọ kẹrin, oṣu kẹta, ọdun 2016 ni Ọba Adetunji gun apere Olubadan ti ilẹ Ibadan.

Àkọlé fídíò, Ìdíje ata tútù: Jẹ ata 50, ko gba góólù gírámù mẹ́ta

Ki lawọn ohun to ti ṣẹlẹ lẹyin iku Ọba Saliu Adetunji?

Gbogbo eeyan lo n reti ki wọn kede ẹni to kan lori ila oye jijẹ ni igbimọ agba oye ilẹ Ibadan gẹgẹ bii Olubadan tuntun bi wọn ṣe maa n sọ pe 'mọkanmọkan loye Ibadan.'

Amọṣa ọrọ ko ri bi ọpọ ṣe ro o nitori pe awuyewuye pe Oloye Lekan Balogun ti oye naa kan ko ni le e jẹ lo gbode.

Àkọlé fídíò, Damilọla pàdánù ọ̀rẹ́kùnrin rẹ̀ nítorí ilà kíkọ

Bawo ni ọrọ ipẹjọ Amofin Michael Lana ṣe bẹrẹ?

Eyi ko ṣẹyin bi amofin kan, Michael Lana, to jẹ ọmọbibi ilẹ Ibadan ṣe kọwe ifisun si gomina ipinlẹ Ọyọ.

O ni pe Lekan Balogun ko lee de ade meji lẹyin to ti gba lati de ade lasiko ti gomina ana, Sẹnetọ Abiọla Ajimọbi ti s awọn oloye ibadan, awọn Mgaji atawọn Baalẹ kan di ọba to n de ade.

Àkọlé fídíò, OLota

Amofin Lana ṣalaye pe ko si ninu iwe ofin oye jijẹ ilẹ Ibadan pe ọ̀ba alade le jẹ Olubadan, "Oloye lo n jẹ olubadan'

Amofin Lana to ti figba kan ri jẹ amofin agba ati kọmiṣọnna feto idajọ ni ipinlẹ Ọyọ ṣalaye pe oloye Kọla Balogun atawọn agbaoye kan nigbimọ olubadab ti gba ade gẹgẹ bi ọbalasiko iṣejọba Gomina Abila Ajimọbi

Eyi fa ọpọ awuyewuye ati ikayasoke lori ibi ti kangunkangun-kangun ọrọ naa yoo kangun si.

Seyi Makinde n ki Olubadan ana

Oríṣun àwòrán, Seyi makinde/ facebook

Bawo ni ilana ofin jijẹ Olubadan ṣe yẹ ko waye?

Ni ibamu pẹlu ilana oye jijẹ nilẹ Ibadan, asiko Oloye Lekan Balogun to jẹ Ọtun Olubadan lo kan lati jẹ ọba.

Amọṣa ekuru fẹ gbẹyin ni ifanfa fun un pẹlu bi oun atawọn agbaoye miran kan ṣe gba ki gomina ana sọ wọn di ọba alade eyi ti ọpọ alẹnulọrọ ati onwoye n sọ pe o tako ilana oye jijẹ nilẹ Ibadan.

Àkọlé fídíò, 'Ìgbà mẹẹ̀dógún ni mo ti ṣẹ́ oyún'

Oloye Lekan Balogun pẹlu awọn agba oye bii Oloye Owolabi Ọlakulẹhin, Balogun ilẹ Ibadan; Tajudeen Ajibọla, Ọtun Balogun ilẹ Ibadan; Oloye Eddy Adewọle, Aṣipa Olubadan; Oloye Abiọdun Kọla Daisi, Ẹẹkẹrin Olubadan ati Hamidu Ajibade, Ẹkarun un Olubadan ṣe faake kọri lati tako aṣẹ Olubadan to waja pe wọn ko gbọdọ tẹle ohun ti gomina ana fẹ fi wọn ṣe.

Àkọlé fídíò, Plights of Widows in Nigeria: Abosede Ilori ní N16,000 ni òun ń gbà fi tọ́jú ọmọ méjì

Ijiroro to waye laarin awọn eekan ọmọ bibi ilẹ Ibadan, awọn ololufẹ ilẹ Ibadan ati gomina pẹlu awọn oloye igbimọ olubadan ni wọn ti fẹnuko pe ki awọn agba oye naa o lọ pada si oye ti wọn wa tẹlẹ ki wọn si l gbe ade ti sẹgbẹ kan.

Bakan naa ni wọn tun fẹnu ko pe ki gbogbo awọn to gbe ẹjọ l si ile ẹjọ lọ wọgile ẹjọ bẹẹ ki wọn to lee mọ igbesẹ to kan.

Àkọlé fídíò, Bunmi Akinnanu: Ọlọ́run kìí fún èèyàn méjì ní orin ẹ̀mí kan ṣoṣo, ẹ jẹ́ ká ṣe sùúrù

Gbogbo eleyii ni awọn ti ọrọ kan ti ṣe ni ṣiṣẹ n tẹle.

Bi ọrọ ṣe ri bayii, ko tii si ẹni mọ boya Agba oye Lekan Balogun ni tabi oun kọ; o di igba ti gomina Makinde ba kede eyi ljọ Aje ki ẹnikẹni to lee mọ ẹni ti yoo jẹ Olubadan tuntun.

Àkọlé fídíò, Wo aburú àti ìpalára tí òògùn olóró Kush tuntun yí n ṣé ní Sierra Leone