Opeyemi Ayeola: Gbàjúmọ̀ òṣèré tíátà sọ̀rọ̀ sókè lórí ìlera rẹ̀, ó ní Ọlọ́run ló kó òun yọ

Oríṣun àwòrán, opeyemi_aiyeola1
Awọn agba bọ wọn ni a kii ro kadun, ko sisi ẹni ti kii rẹ, se kẹnimani ara ko si, apọju rẹ ni ko sunwọn.
Gbajumọ oṣere tiata, Ọpẹyẹmi Ayeọla ti sọrọ sita lori ilera rẹ ati ipenija ti o n koju lori aisan to da a wolẹ ninu fidio kan to gbe soju opo ayelujara rẹ.
Ọpẹyẹmi Ayeọla ṣalaye loju opo Instagram rẹ pe, ọwọ rere ni ọdun 2022 fi bẹrẹ fun oun pẹlu oniruuru idokoowo to dantọ, ipe sawọn iṣẹ tiata loriṣiriṣi atawọn iṣẹ to mowo dani miran bẹẹ.
- Ikú tó fẹ́ pa Opeyemi Ayeola ṣí i ní fìlà, ló bá ń kọrin ẹ fọ̀rọ̀ mi kọ́gbọ́n
- Gbọ́yì-sọ̀yí àti ìròyìn èké láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ wa ló ṣáábà ma ń da ìgbéyàwó àwọn òṣèré rú- Ọpẹ Ayeola
- Àwọn Òṣèré fíìmù Yorùbá tẹ́ ò ro tó tí jápaa lọ ìlú Òyìnbó rèé
- Iyabo Ojo, Toyin Abraham, Mercy Aigbe, ta làwọn òṣèrébìnrin yìí gbè lẹ́yìn lórí ọ̀rọ̀ ìfipábánilòpọ̀?
- Egúngún bá òṣèrébìnrin lòpọ̀ nínú eré, àwọn Eléégún yarí
Amọṣa o ni oṣu keji n sun kẹrẹkẹrẹ wọle ni ipenija ilera de ba oun, ki Eleduwa to mu oun bori.
Ki lo se Opeyemi Ayeola to fi dubulẹ aisan:
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post
Nigba to n ohun to se to fi di ero ile iwosan, osere tiata naa ni lojiji ni esu gbe ise rẹ de, ti aisan naa si wọle wa.
Amọ o ni oun dupẹ lọwọ Ọlọrun to da si isẹlẹ naa, to si fun oun ni isẹgun ati idapada ilera oun.
O wa n kan saara si Oluwa ti o seun lori ilera rẹ naa, to si ni ko maa jọba lọ ninu aye oun nitori Ọlọrun ti kii se eniyan ni.

Oríṣun àwòrán, opeyemi_aiyeola1
Opeyemi Ayeola wa dupẹ lọwọ awọn ejika ti ko jẹ ki asọ bọ:
Ni kete ti ara le pada yii ni osere tiata naa n fi ẹmi imoore rẹ han si awọn eeyan to duro ti i, lasiko ti oju ogun le, ti aisan si da wolẹ.
Ko ṣai dupẹ lọwọ iya rẹ, ọkọ rẹ, awọn ọmọ atawọn mọlẹbi rẹ gbogbo, titi kan awọn akẹgbẹ rẹ lẹnu iṣẹ tiata fun aduroti wọn.
Bi ẹ ko ba ni gbagbe, ni nnkan bii oṣu kẹrin si ikarun ọdun 2021 ni iroyin kan pe, ara gbajumọ oṣere yii ko ya, o ṣi ogun lo fun ara rẹ ti o si daku rangbọdan.
- Small Mummy, aláwàdà ọmọ ọdún mẹwàá gba ẹ̀bùn ọkọ̀ olówó iyebíye
- Onímọ̀ ẹ̀yà ara míì kéde okùnfa ikú míràn tó pa Sylvester Oromoni
- Bí Sunday Igboho ṣe wà ní ẹ̀wọ̀n di àsìkò yìí fihàn pé ìjọba Benin kò bọ̀wọ̀ fún òfin - Gani Adams
- Ìjọba ti rí ibi tí àmúlùmálà epo gbà wọ Nàìjíríà - NNPC
- Àrídájú pé ìdájọ òdodo yóò wáyé ṣẹ̀ṣẹ̀ ń fojú hàn ni lórí ikú Adegoke - Agbẹjọ́rò ẹbí olóògbé
- Ìjọba àpapọ̀ yọwọ́ kúrò nínú ẹjọ́ tó ń bá Rahmon Adedoyin àtàwọn afurasí míì ṣe lórí ikú Adegoke
- Bí ìgbẹ́jọ́ ikú Timothy Adegoke ṣe ń wáyé lọ́wọ́ ní Abuja, Femi Falana ń bèèrè pé kí ọ̀gá ọlọ́pàá dá ẹjọ́ padà sí Osun
- Ìjọba le gbé ọ̀gá ọlọ́pàá Abba Kyari lọ Amẹ́ríkà láti lọ jẹ́jọ́ lórí ẹ̀sùn jìbìtì pẹ̀lú Hushpuppi - Malami
Ta ni Opeyemi Ayeola:
Opeyemi Aiyeola, tii se ẹni ọdun mẹrinlelogoji, jẹ gbajumọ osere tiata ni ede Yoruba, to si tun jẹ oludari ere pẹlu.
Ọdun 1998 lo darapọ mọ ere tiata, ọmọ bibi ilu Sagamu nipinlẹ Ogun nii se, amọ ilu Eko lo gbe dagba.
Ọmọ mẹta ni awọn obi Opeyemi bi, osu si ni ọmọ keji.
O se igbeyawo pẹlu ọkọ rẹ, Babatunde Olayiwola Owolomose, ti Ọba oke si fi ọmọkunrin meji ta wọn lọrẹ.
Gbajumọ osere tiata naa si ti gba ọpọ ami ẹyẹ nidi isẹ tiata, to si n gbe ni Amẹrika pẹlu ọkọ rẹ.

















